< Jeremiasza 49 >
1 Przeciwko synom Amonowym. Tak mówi Pan: Izali Izrael nie ma synów? Izali żadnego dziedzica nie ma? czemuż król ich dziedzicznie opanował Gad, a lud jego czemu mieszka w miastach jego?
Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Przetoż oto dni idą, mówi Pan, sprawię, że usłyszą trąbienie wojenne przeciwko Rabbie synów Amonowych, i będzie obrócona w kupę rumu, a inne miasta jego ogniem spalone będą, i posiędzie Izrael dzierżawców swoich, mówi Pan.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
3 Rozrzewnij się, Hesebonie! bo Haj spustoszone będzie; krzyczcie, o córki Rabby! przepaszcie się worami, narzekajcie, a tułajcie się około płotów; bo król wasz do więzienia pójdzie, także kapłani jego, i książęta jego społem.
“Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Cóż się przechwalasz dolinami? Spłynęła dolina twoja, o córko uporna! która ufasz w skarbach twoich, mówiąc: Któż przyciągnie przeciwko mnie?
Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
5 Oto Ja przywiodę na cię strach, mówi Pan, Pan zastępów od wszystkich, którzy są około ciebie, przez który rozegnani będziecie jeden od drugiego, a nie będzie, ktoby zebrał tułających się.
Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 Wszakże potem przywiodę zaś więźniów synów Amonowych, mówi Pan.
“Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
7 Przeciwko Edomczykom. Tak mówi Pan zastępów: Izali niemasz więcej mądrości w Teman? Izali zginęła rada od roztropnych, a wniwecz się obróciła mądrość ich?
Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8 Uciekajcie, obróćcie się, zstąpcie w głębokość na mieszkanie, obywatele Dedan! bo przywiodę zatracenie na Ezawa czasu nawiedzenia jego.
Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9 Gdyby ci, którzy zbierają wino, przyszli na cię, izaliby nie zostawili jakich gron? gdyby się wkradli złodzieje w nocy, azażby szkodzili więcej nad potrzebę swoję?
Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 Lecz Ja obnażę Ezawa, odkryję skrytości jego, tak, iż się ukryć nie będzie mógł: zniszczone będzie nasienie jego, i bracia jego, i sąsiedzi jego, tak, że zgoła nie będzie, ktoby rzekł:
Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Zaniechaj sierotek twoich, ja je żywić będę, a wdowy twoje we mnie ufać będą.
Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12 Tak zaiste mówi Pan: Oto ci, którym nie przysądzono pić z kubka tego, przecie piją z niego, a tybyś miał zgoła tego ujść?
Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
13 Nie ujdziesz, ale koniecznie pić będziesz; bo przez się przysięgam, mówi Pan, iż na spustoszenie, na pohańbienie, na zburzenie, i na przeklęstwo Bocra przyjdzie, i wszystkie miasta jego będą pustemi na wieki.
Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
14 Słyszałem wieść od Pana, że do narodów posłany jest poseł mówiący: Zgromadźcie się, a ciągnijcie, przeciwko niemu, wstańcież do bitwy.
Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
15 Bo oto sprawię, abyś był najlichszym między narodami, i wzgardzonym miedzy ludźmi.
“Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Hardość twoja zdradzi cię, i pycha serca twego, ty, który mieszkasz w rozsiadlinach skalnych, który się trzymasz wysokich pogórków; byś też wywyższył jako orzeł gniazdo swoje, i stamtąd cię stargnę, mówi Pan.
Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
17 I będzie ziemia Edomska pustynią, i ktokolwiek pójdzie przez nię, zdumieje się, i świstać będzie nad wszystkiemi plagami jej.
“Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
18 Jako podwrócona jest Sodoma i Gomora z przyległościami swojemi, mówi Pan, tak się tam nikt nie osadzi, ani w niej syn człowieczy mieszkać będzie.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
19 Oto aczkolwiek jako lew występuje, i bardziej niż nadęcie Jordanu się podnosi przeciwko przybytkowi Mocnego: wszakże go nagle wypędzę z tej ziemi, a tego, który jest obrany, przełożę nad nią: bo któż mnie jest podobny? i kto mi da rok; a kto jest tym pasterzem, któryby się postawił przeciwko mnie?
“Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
20 Przetoż słuchajcie rady Pańskiej, którą uradził przeciwko Edomczykom; i zamysłów jego, które umyślił przeciwko obywatelom Temańskim; zaiste żeć ich wywleką najmniejsi z tej trzody, zaiste pobudzą ich, i przybytki ich.
Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Od grzmotu upadku ich wzruszy się ziemia; głos i krzyk ich słyszeć będą na morzu Czerwonem.
Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
22 Oto jako orzeł przypadnie i przyleci, a rozciągnie skrzydła swe nad Bocrą, i stanie się serce mocarzów z Edom dnia onego, jako serce niewiasty bolejącej.
Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
23 Przeciwko Damaszkowi. Zawstydzi się Emat i Arfad; bo wieść złą usłyszą, i zatrwożą się, tak że się i morze wzruszy, a nie będzie się mogło uspokoić.
Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Osłabieje Damaszek, uda się do uciekania, a strach go ogarnie; uciski i boleści ogarną go, jako rodzącą.
Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Ale rzeką: Jakożby się nie miało ostać miasto sławne, miasto wesela mego?
Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
26 Przetoż upadną młodzieńcy jego na ulicach jego, a wszyscy mężowie waleczni dnia onego wytraceni będą, mówi Pan zastępów.
Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 I rozniecę ogień w murze Damaszku, który strawi pałace Benadadowe.
“Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
28 Przeciwko Kiedar, i przeciwko królestwom Hasor, które wytracić ma Nabuchodonozor, król Babiloński; tak mówi Pan: Wstańcie, ciągnijcie przeciwko Kiedar, a zburzcie narody wschodnie.
Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
29 Namioty ich i trzody ich zabiorą; opony ich ze wszystkiem naczyniem ich i wielbłądy ich wezmą ze sobą, i zawołają na nich: Strach zewsząd.
Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
30 Uciekajcie, rozpierzchnijcie się prędko, zstąpcie w głębokości na mieszkanie, obywatele Hasor! mówi Pan; bo zawarł radę przeciwko wam Nabuchodonozor, król Babiloński, i umyślił przeciwko wam zdradę.
“Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
31 Wstańcie, ciągnijcie przeciwko narodowi spokojnemu, mieszkającemu bezpiecznie, mówi Pan: nie ma ani wrót, ani zawór, samotni mieszkają.
“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
32 Będą zaiste wielbłądy ich podane na łup, a mnóstwo dobytku ich na korzyść; i rozproszę na wszystkie wiatry tych, którzy i w najostateczniejszych kątach mieszkają, i ze wszystkich stron złe na nich przywiodę, mówi Pan.
Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
33 I stanie się Hasor mieszkaniem smoków, pustynią aż na wieki; nie osadzi się tam nikt, ani mieszkać będzie w nim syn człowieczy.
“Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
34 Słowo Pańskie, które się stało do Jeremijasza proroka przeciwko Elamczykom na początku królowania Sedekijasza, króla Judzkiego, mówiąc:
Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
35 Tak mówi Pan zastępów: Oto ja złamię łuk Elamczyków, największą siłę ich;
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36 A przywiodę przeciwko Elamczykom cztery wiatry ze czterech stron świata, i rozproszę ich na wszystkie one wiatry, tak, iż nie będzie narodu, do któregoby się nie dostali wygnańcy z Elam;
Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
37 I zatrwożę Elamczyków przed obliczem nieprzyjaciół ich, i przed obliczem tych, którzy szukają duszy ich; przywiodę, mówię, na nich złe, gniew popędliwości mojej, mówi Pan, a posyłać za nimi będę miecz, dokąd ich nie wyniszczę;
Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
38 I postawię stolicę moję między Elamczykami, a wytracę stamtąd króla i książąt, mówi Pan.
Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
39 Wszakże stanie się, że w ostateczne dni przywrócę zaś więźniów Elam, mówi Pan.
“Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.