< Jeremiasza 46 >

1 Słowo Pańskie, które się stało do Jeremijasza proroka przeciwko tym narodom.
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa àwọn Orílẹ̀-èdè.
2 Przeciwko Egiptowi. Przeciwko wojsku Faraona Necha, króla Egipskiego, (które było nad rzeką Eufrates u Karchemis, które poraził Nabuchodonozor, król Babiloński) roku czwartego Joakima, syna Jozyjaszowego, króla Judzkiego;
Nípa Ejibiti. Èyí ni ọ̀rọ̀ nípa àwọn ọmọ-ogun Farao Neko ọba Ejibiti ẹni tí a borí rẹ̀ ní Karkemiṣi, ní odò Eufurate láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:
3 Gotujcie tarcz i pawężę, a wychodźcie na wojnę;
“Ẹ múra àpáta, èyí tí ó tóbi, àti èyí tí ó kéré, kí ẹ sì súnmọ́ ojú ìjà!
4 Zaprzęgajcie konie, a wsiadajcie jezdni, stańcie w hełmach, wycierajcie oszczepy, obleczcie się w pancerze.
Ẹ di ẹṣin ní gàárì, kí ẹ sì gùn ún. Ẹ dúró lẹ́sẹẹsẹ pẹ̀lú àṣíborí yín! Ẹ dán ọ̀kọ̀ yín, kí ẹ sì wọ ẹ̀wù irin.
5 Czemuż tych widzę zatrwożonych, tył podawających, a mocarzy ich startych i prędko uciekających, tak, że się ani oglądają? Strach jest zewsząd, mówi Pan,
Kí ni nǹkan tí mo tún rí? Wọ́n bẹ̀rù, wọ́n sì ń padà sẹ́yìn, wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn jagunjagun. Wọ́n sá, wọn kò sì bojú wẹ̀yìn, ìbẹ̀rù sì wà níbi gbogbo,” ni Olúwa wí.
6 Aby nie uciekł prędki, a nie uszedł mocarz; aby się na północy o brzeg rzeki Eufrates otrącili i upadli.
“Ẹni tí ó yára kì yóò le sálọ, tàbí alágbára kò ní lè sá àsálà. Ní àríwá ní ibi odò Eufurate wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
7 Któż to jest, który jako rzeka wzbiera? Którego się wody wzruszają jako rzeki?
“Ta ni èyí tí ó gòkè wá bí odò Ejibiti, tí omi rẹ̀ ń ru gẹ́gẹ́ bí odò wọ̀n-ọn-nì?
8 Egipt jako rzeka wzbiera, a jego wody wzruszają się jako rzeki, i mówi: Pociągnę, okryję ziemię, wygubię miasto, i tych, co w niem mieszkają.
Ejibiti dìde bí odò náà, bí omi odò tí ń ru. Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò dìde, n ó sì bo gbogbo ilẹ̀ ayé.’ Èmi yóò pa ìlú àti àwọn ènìyàn rẹ̀ run.
9 Poskoczcie konie, a zagrzmijcie wozy, a niech się ruszą i mocarze, Murzynowie, i Putejczycy noszący tarcz, i Ludymczycy, którzy noszą i ciągną łuk,
Ẹ gòkè wá ẹ̀yin ẹṣin, ẹ sì sáré kíkankíkan ẹ̀yin kẹ̀kẹ́. Kí àwọn alágbára túbọ̀ tẹ̀síwájú, àwọn ará Kuṣi àti àwọn ará Puti tí ń di asà mú; àti àwọn ará Lidia tí ń fa ọrun.
10 Bo ten dzień panującego Pana zastępów będzie dzień pomsty, aby się pomścił nad nieprzyjaciołmi swymi, których miecz pożre, a nasyci się, i opije się krwią ich; bo ofiara panującego Pana zastępów będzie w ziemi północnej u rzeki Eufrates.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà jẹ́ ti Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọjọ́ ìgbẹ̀san, ìgbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Idà yóò sì jẹ́ títí yóò fi ní ìtẹ́lọ́rùn, títí yóò fi pa òǹgbẹ rẹ̀ rẹ́ pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀. Nítorí pé Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò rú ẹbọ ní ilẹ̀ gúúsù ní odò Eufurate.
11 Wstąp do Galaad, a nabierz soku balsamowego, panno, córko Egipska! Aleć próżno używasz wiele lekarstw; bo nie będziesz uleczona.
“Gòkè lọ sí Gileadi, kí o sì mú ìkunra, ìwọ wúńdíá ọmọbìnrin Ejibiti. Ṣùgbọ́n ní asán ni ìwọ ń lo oògùn, kì yóò sí ìwòsàn fún ọ.
12 Narody usłyszą o sromocie twojej, a narzekanie twoje napełniło ziemię; bo mocarz na mocarza natarł, tak, że społem oba upadają.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ nípa ìtìjú rẹ, igbe rẹ yóò kún gbogbo ayé. Jagunjagun yóò máa ṣubú lu ara wọn lórí rẹ, àwọn méjèèjì yóò sì jọ ṣubú papọ̀.”
13 Słowo, które mówił Pan do Jeremijasza, proroka, o tem, że ma przyjść Nabuchodonozor, król Babiloński, a porazić ziemię Egipską.
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó bá Jeremiah wòlíì nì sọ nípa wíwá Nebukadnessari ọba Babeli láti lọ dojú ìjà kọ Ejibiti:
14 Oznajmijcie w Egipcie, a rozgłoście w Migdolu; opowiadajcie także w Nof, i w Tachpanches; rzeczcie: Postuj a nagotuj się; wszakże miecz pożre to, co jest około ciebie.
“Kéde èyí ní Ejibiti, sì sọ ọ́ ní Migdoli, sọ ọ́ ní Memfisi àti Tafanesi: ‘Dúró sí ààyè rẹ kí o sì múra sílẹ̀, nítorí pé idà náà ń pa àwọn tí ó yí ọ ká.’
15 Przecz porażony jest każdy z mocarzów twoich? Nie może się ostać, przeto, że Pan natarł nań.
Èéṣe tí àwọn akọni rẹ fi ṣubú? Wọn kò ní le dìde dúró, nítorí Olúwa yóò tì wọ́n ṣubú.
16 Wieleć będzie tych, którzy poszwankują a padną jeden na drugiego, i rzeką: Wstań, a wróćmy się do ludu naszego, i do ziemi urodzenia naszego przed ostrzem miecza pustoszącego.
Wọn yóò máa ṣubú léraléra wọn yóò máa ṣubú lu ara wọn. Wọn yóò sọ wí pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wa àti ilẹ̀ ìbí wa, kúrò níbi idà àwọn aninilára.’
17 Tam będą wołać: Farao, król Egipski, jest tylko próżny trzask, już mu pominął czas postanowiony,
Níbẹ̀ ni wọn ó kígbe pé, ‘Ariwo lásán ni Farao ọba Ejibiti pa, ó ti sọ àǹfààní rẹ̀ nù.’
18 Jakom żywy Ja, mówi król, Pan zastępów imię jego; że jako Tabor między górami, i jako Karmel przy morzu, tak to przyjdzie.
“Bí èmi ti wà láààyè,” ni ọba, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Nítòótọ́ gẹ́gẹ́ bí Tabori láàrín àwọn òkè àti gẹ́gẹ́ bi Karmeli lẹ́bàá Òkun bẹ́ẹ̀ ni òun yóò dé.
19 Spraw sobie naczynie przeprowadzenia, obywatelko, córko Egipska! bo Nof pustynią będzie i spustoszeje, i będzie bez obywatela.
Ìwọ, ọmọbìnrin ti ń gbé Ejibiti pèsè ohun èlò ìrìnàjò fún ara rẹ nítorí Memfisi yóò di ahoro a ó sì fi jóná, láìní olùgbé.
20 Egipt jest jako piękna jałowica; ale zabicie jej od północy idzie, idzie.
“Ẹgbọrọ abo màlúù tó lẹ́wà ní Ejibiti ṣùgbọ́n eṣinṣin ìparun dé, ó dé láti àríwá.
21 Więc i najemnicy jego w pośrodku niego są jako ciele utuczone, ale i oni także obróciwszy się uciekną społem, nie ostoją się; bo dzień porażki ich przyszedł na nich, czas nawiedzenia ich.
Àwọn jagunjagun rẹ̀ dàbí àbọ́pa akọ màlúù. Àwọn pẹ̀lú yóò yípadà, wọn ó sì jùmọ̀ sá, wọn kò ní le dúró, nítorí tí ọjọ́ ibi ń bọ̀ lórí wọn àsìkò láti jẹ wọ́n ní ìyà.
22 Głos jego wynijdzie jako wężowy; bo z wojskiem idą, a z siekierami przyjdą nań, jako ci, co wyrąbują drzewo.
Ejibiti yóò pòṣé bí ejò tí ń sá bí ọmọ-ogun ṣe ń tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú agbára. Wọn ó tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú àáké, gẹ́gẹ́ bí i ti agégi.
23 Wyrąbią las jego, mówi Pan, choć policzony być nie może; bo się nad szarańczę rozmnożyli, i niemasz im liczby.
Wọn o gé igbó rẹ̀ lulẹ̀,” ni Olúwa wí, “nítorí ti a kò le rídìí rẹ̀. Nítorí pé wọ́n pọ̀ ju ẹlẹ́ǹgà lọ, wọ́n sì jẹ́ àìníye.
24 Zawstydzi się córka Egipska; podana będzie w rękę ludu północnego.
A ó dójútì ọmọbìnrin Ejibiti, a ó fà á lé ọwọ́ àwọn ènìyàn àríwá.”
25 Pan zastępów, Bóg Izraelski, mówi: Oto Ja nawiedzę ludne miasto No, także Faraona i Egipt, i bogów jego, i królów jego, Faraona mówię, i tych, którzy w nim ufają:
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí pé: “Èmi yóò rọ̀jò ìyà mi sórí Amoni òrìṣà Tebesi, sórí Farao, sórí Ejibiti àti àwọn òrìṣà rẹ̀ àti sórí àwọn ọba rẹ̀ àti sórí àwọn tó gbẹ́kẹ̀lé Farao.
26 I podam ich w rękę tych, którzy szukają duszy ich, to jest w rękę Nabuchodonozora, króla Babilońskiego, i ręką sług jego; lecz potem mieszkać w nim będą, jako za dawnych dni, mówi Pan.
Èmi ó sì fi wọ́n lé àwọn tó wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́, lé Nebukadnessari ọba Babeli, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Ejibiti yóò sì di gbígbé bí i ti àtijọ́,” ni Olúwa wí.
27 Ale się ty nie bój, sługo mój Jakóbie! a nie lękaj się, o Izraelu! Bo oto Ja ciebie wybawię z daleka, i nasienie twoje z ziemi pojmania ich; i wróci się Jakób, aby odpoczywał i aby miał pokój, a nie będzie, ktoby go postraszył;
“Má bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má fòyà, ìwọ Israẹli. Dájúdájú èmi ó gbà ọ́ láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ ọmọ rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn. Jakọbu yóò tún ní àlàáfíà àti ààbò, kò sì ṣí ẹni tí yóò dẹ́rùbà á.
28 Ty, mówię, Jakóbie, sługo mój! nie bój się, mówi Pan; bom Ja z tobą. Uczynię zaiste koniec wszystkim narodom, do których cię wypędzę; lecz tobie nie uczynię końca, ale cię miernie karać będę, a cale cię bez karania nie zostawię.
Má bẹ̀rù, Jakọbu ìránṣẹ́ mi, nítorí pé mo wà pẹ̀lú rẹ,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, láàrín àwọn tí mo fọ́n yín ká sí. Èmi kò ní run yín tán. Èmi yóò jẹ ọ́ ní ìyà lórí òdodo, èmi kí yóò jọ̀wọ́ rẹ lọ́wọ́ lọ láìjẹ ọ́ ní yà.”

< Jeremiasza 46 >