< Jeremiasza 44 >

1 Słowo, które się stało do Jeremijasza o wszystkich Żydach, którzy mieszkali w ziemi Egipskiej, którzy mieszkali w Migdolu, i w Tachpanches, i w Nof, i w ziemi Patros, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
2 Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Wyście widzieli wszystko ono złe, którem przywiódł na Jeruzalem, i na wszystkie miasta Judzkie, że oto puste są po dziś dzień, niemasz w nich obywatela.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
3 Dla złości ich, którą czynili, aby mię do gniewu pobudzali, chodząc kadzić i służyć Bogom cudzym, których nie znali sami, wy i ojcowie wasi;
Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
4 Chociażem posyłał do was wszystkich sług moich, proroków, rano wstawając i posyłając a mówiąc: Nie czyńcie proszę tej obrzydliwości, której nienawidzę.
Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
5 Ale nie usłuchali ani nakłonili ucha swego, aby się odwrócili od złości swojej, a nie kadzili bogom cudzym.
Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
6 Przetoż wylany jest gniew mój, a zapalczywość moja zapaliła się w miastach Judzkich, i w ulicach Jeruzalemskich, i obróciły się w pustynie, i wzburzenie, jako się to dziś pokazuje.
Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
7 Teraz tedy tak mówi Pan, Bóg zastępów, Bóg Izraelski: Czemu wy czynicie tę złość wielką przeciwko duszom waszym, aby z was był wykorzeniony mąż i niewiasta, dziecię i ssący z pośrodku Judy, tak, żeby z was nic nie zostało,
“Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
8 Draźniąc mię sprawami rąk waszych, kadząc bogom cudzym w ziemi Egipskiej, do którejście weszli, abyście tam pielgrzymowali, iżbyście byli wykorzenieni, a byli na przeklęstwo i na hańbę u wszystkich narodów na ziemi?
Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
9 Azaście zapamiętali na złość ojców waszych, i na złość królów Judzkich, i na złość żon ich, i na złości wasze, i na złości żon waszych, których się dopuściły w ziemi Judzkiej i po ulicach Jeruzalemskich?
Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
10 Nie upokorzyli się aż do dnia tego, i nie bali się, ani chodzili w zakonie moim i w ustawach moich, które podaję wam i ojcom waszym.
Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
11 Przetoż tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Oto Ja obrócę oblicze moje przeciwko wam na złe, aby wykorzenił wszystkiego Judę.
“Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
12 Wygubię zaiste ostatki Judzkie, którzy upornie weszli do ziemi Egipskiej, aby tam pielgrzymowali, tak, że zniszczeją wszyscy w ziemi Egipskiej, polegną od miecza, od głodu zniszczeją od najmniejszego aż do największego, od miecza i od głodu pomrą; nadto będą na przeklinanie, i na zdumienie, i na złoszczenie, i na hańbę.
Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
13 Bo nawiedzę tych, którzy mieszkają w ziemi Egipskiej, jakom nawiedził Jeruzalem mieczem, głodem i morem.
Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
14 I nie będzie ktoby uszedł i został z ostatków Judzkich, którzy weszli do ziemi Egipskiej, aby tam pielgrzymowali, aby się zaś wrócić mieli do ziemi Judzkiej, do której się oni pragną wrócić, i mieszkać tam; ale się nie wrócą, tylko ci, którzy ujdą.
Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
15 Tedy odpowiedzieli Jeremijaszowi wszyscy mężowie, którzy wiedzieli, iż kadzały żony ich bogom cudzym, one wszystkie niewiasty, których stało mnóstwo wielkie, i wszystek lud, który mieszkał w ziemi Egipskiej w Patros, mówiąc:
Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
16 W słowie, któreś mówił do nas imieniem Pańskiem, nie usłuchały cię;
“Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
17 Ale dosyć czynimy każdemu słowu, które wynijdzie z ust naszych, kadząc królowej niebieskiej, i sprawując jej ofiary mokre, jakośmy czynili, my i ojcowie nasi, królowie nasi, i książęta nasi w miastach Judzkich i po ulicach Jeruzalemskich, a najad aliśmy się chleba, i dobrze nam było, a nic złegośmy nie widzieli.
Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
18 Ale odtąd jakośmy przestali kadzić królowej niebieskiej, i sprawować jej ofiary mokre, na wszystkiem nam schodzi, a od miecza i od głodu niszczejemy.
Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
19 A gdy kadzimy królowej niebieskiej, i sprawujemy jej ofiary mokre, izali jej bez mężów naszych placki czynimy, kształtując ją, i sprawując jej ofiary mokre?
Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
20 Tedy rzekł Jeremijasz do wszystkiego ludu, do mężów i do niewiast, i do wszystkiego pospólstwa, którzy mu tak odpowiedzieli, mówiąc:
Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
21 Izali na kadzenie, któremeście kadzili w miastach Judzkich i w ulicach Jeruzalemskich, wy i ojcowie wasi, królowie wasi, i książęta wasi, i lud ziemi, nie wspomniał Pan, i nie wstąpiło to na serce jego?
“Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
22 Tak, że nie mógł Pan dalej znosić złości spraw waszych, i obrzydliwości, któreście broili; dlatego się stała ziemia wasza spustoszeniem i zdumieniem, i przeklęstwem, tak, że niemasz w niej obywatela, jako się to dziś pokazuje,
Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
23 Dlatego, żeście kadziili bałwanom, i żeście grzeszyli przeciw Panu, a nie słuchaliście głosu Pańskiego, a tak w zakonie jego, i w ustawach jego, ani w świadectwach jego nie chodziliście, dlatego przyszło na was to złe, jako się to dziś pokazuje.
Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
24 Nadto rzekł Jeremijasz do wszystkiego ludu, i do wszystkich niewiast: Słuchajcie słowa Pańskiego wszyscy ludzie Judzcy, którzyście z ziemi Egipskiej.
Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
25 Tak rzekł Pan zastępów, Bóg Izraelski, mówiąc: Wy i żony wasze mówiliście usty swemi, i wypełniliście rękami swemi, mówiąc: Uczynimy dosyć ślubom naszym, któreśmy poślubili, abyśmy kadzili królowej niebieskiej, i sprawowali jej ofiary mokre, a tak wszystką siłą wypełniacie śluby wasze, i samym skutkiem wykonywacie śluby wasze.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
26 Przetoż słuchajcie słowa Pańskiego wszyscy ludzie Judzcy, którzy mieszkacie w ziemi Egipskiej: Oto Ja przysięgam przez imię moje wielkie, mówi Pan, że nie będzie więcej imię moje wzywane usty żadnego męża Judzkiego po wszystkiej ziemi Egipskiej, któryby rzekł: Jako żyje panujący Pan!
Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
27 Oto Ja będę czuł nad nimi na złe, a nie na dobre; i niszczeć będą wszyscy mężowie Judzcy, którzy są w ziemi Egipskiej, mieczem i głodem, aż do szczętu wyginą;
Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
28 A którzy ujdą miecza, wrócą się z ziemi Egipskiej do ziemi Judzkiej, ludu mały poczet; i pozna wszystek ostatek Judzki, którzy weszli do ziemi Egipskiej, aby tam pielgrzymowali, czyje się słowo ostoi, mojeli, czyli ich?
Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
29 A to miejcie za znak, mówi Pan, że Ja was nawiedzę na tem miejscu, abyście wiedzieli, iż się prawdziwie spełnią słowa moje nad wami ku złemu.
“‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
30 Tak mówi Pan: Oto Ja podam Faraona Chofra, króla Egipskiego, w rękę nieprzyjaciół jego, i w rękę szukających duszy jego, jakom podał Sedekijasza, króla Judzkiego, w rękę Nabuchodonozora, króla Babilońskiego, nieprzyjaciela jego, który szukał duszy jego.
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”

< Jeremiasza 44 >