< Jeremiasza 41 >

1 I stało się miesiąca siódmego, że przyszedł Izmael, syn Natanijasza, syna Elisamowego, z nasienia królewskiego, i hetmani królewscy, to jest, dziesięć mężów z nim, do Godolijasza, syna Ahikamowego, do Masfy, i jedli tam społu chleb w Masfie.
Ní oṣù keje Iṣmaeli, ọmọ Netaniah ọmọ Eliṣama, nínú irú-ọmọ ọba, àti àwọn ìjòyè ọba, àti àwọn ọkùnrin mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu wá ní Mispa; níbẹ̀ ni wọ́n jùmọ̀ jẹun ní Mispa.
2 Potem wstawszy Izmael, syn Natanijaszowy, i dziesięć mężów, którzy z nim byli, zabili Godolijasza, syna Ahikama, syna Safanowego, mieczem; zabili mówię tego, którego był przełożył król Babiloński nad oną ziemią.
Iṣmaeli ọmọ Netaniah àti àwọn ọkùnrin mẹ́wàá tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀, sì dìde wọ́n kọlu Gedaliah ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani pẹ̀lú idà. Wọ́n sì pa á, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ilẹ̀ náà.
3 Wszystkich także Żydów, którzy byli z nim, z Godolijaszem w Masfie, i onych Chaldejczyków, których tam znalazł, mężów walecznych, pobił Izmael.
Iṣmaeli sì tún pa gbogbo àwọn Júù tí wọ́n wà pẹ̀lú Gedaliah ní Mispa, àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun Babeli tí wọ́n wà níbẹ̀ bákan náà.
4 A dnia wtórego, gdy zabił Godolijasza, (o czem nikt nie zwiedział.)
Ní ọjọ́ kejì tí wọ́n pa Gedaliah kí ó tó di wí pé ẹnikẹ́ni mọ̀,
5 Przyszli niektórzy z Sychem, z Sylo, i z Samaryi, mężów ośmdziesiąt, ogoliwszy brody, i rozdarłszy szaty, i podrapawszy się, którzy ofiarę śniedną, i kadzidło w rękach swych mieli, aby je odnieśli do domu Pańskiego.
àwọn ọgọ́rin ọkùnrin wá láti Ṣekemu, Ṣilo àti Samaria, wọ́n fa irùngbọ̀n wọn, wọ́n ya aṣọ wọn, wọ́n ṣá ara wọn lọ́gbẹ́, wọ́n mú ẹbọ ọpẹ́ àti tùràrí wá sí ilé Olúwa.
6 Tedy Izmael, syn Natanijaszowy, wyszedł przeciwko nim z Masfy, a idąc szedł i płakał; a gdy się spotkał z nimi, rzekł do nich: Pójdźcie do Godolijasza, syna Ahikamowego.
Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah jáde kúrò láti Mispa láti lọ pàdé wọn. Ó sì ń sọkún bí ó ti ṣe ń lọ, nígbà tí ó pàdé wọn, ó wí pé, “Ẹ wá sọ́dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu.”
7 Ale gdy przyszli w pośród miasta, pobił ich Izmael, syn Natanijaszowy, i wrzucił ich w dół, sam i mężowie, którzy z nim byli.
Nígbà tí wọ́n dé ìlú náà; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa wọ́n, wọ́n sì sọ òkú wọn sínú ihò kan.
8 Lecz się dziesięć mężów znalazło między nimi, którzy rzekli do Izmaela: Nie zabijaj nas, bo mamy skarby skryte w polu, pszenicy i jęczmienia, i oliwy, i miodu. I pohamował się; a nie zabił ich między braćmi ich.
Ṣùgbọ́n mẹ́wàá nínú wọn sọ fún Iṣmaeli pé, “Má ṣe pa wá! Àwa ní ọkà àti barle, òróró àti oyin ní ìpamọ́ nínú oko.” Nítorí náà, ó fi wọ́n sílẹ̀: kò sì pa wọ́n pẹ̀lú àwọn yòókù.
9 A dół, do którego Izmael wrzucił do Godolijasza wszystkie trupy onych mężów, których pobił, ten jest, który uczynił król Aza, bojąc się Baazy, króla Izraelskiego, który napełnił Izmael syn Natanijaszowy pobitymi.
Nísinsin yìí, ihò náà tí ó kó gbogbo ara àwọn ọkùnrin tí ó ti pa pẹ̀lú Gedaliah sí ni ọba Asa ń lò gẹ́gẹ́ bí i ààbò nítorí ọba Baaṣa ti Israẹli. Iṣmaeli ọmọ Netaniah sì ti kó òkú kún inú rẹ̀.
10 I pobrał w niewolę Izmael wszystkie ostatki ludu, które były w Masfie, córki królewskie, i wszystek lud, który był został w Masfie, które był poruczył Nabuzardan, hetman żołnierski, Godolijaszowi, synowi Ahikamowemu, i wziął je w pojmanie Izmael, syn Natanijaszowy, i poszedł uchodząc do synów Ammonowych.
Iṣmaeli sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní Mispa nígbèkùn, ọmọbìnrin ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn tókù síbẹ̀ lórí àwọn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti fi yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ṣe olórí. Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah kó wọn ní ìgbèkùn, ó sì jáde rékọjá sí ọ̀dọ̀ àwọn Ammoni.
11 Wtem usłyszał Johanan, syn Kareaszowy, i wszyscy hetmani owych wojsk, którzy byli z nim, o tem wszystkiem złem, które uczynił Izmael, syn Natanijaszowy;
Nígbà tí Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ gbọ́ nípa gbogbo ìpànìyàn náà tí Iṣmaeli ọmọ Netaniah ti ṣe.
12 I wzięli wszystek swój lud, i ciągnęli, aby zwiedli bitwę z Izmaelem, synem Natanijaszowym, którego znaleźli u wód wielkich, które są w Gabaon.
Wọ́n kó gbogbo àwọn ọkùnrin wọn, wọ́n sì, lọ bá Iṣmaeli ọmọ Netaniah jà. Wọ́n pàdé rẹ̀ ní odò kan lẹ́bàá Gibeoni.
13 A gdy ujrzał wszystek lud, który był z Izmaelem, Johanana, syna Kareaszowego, i wszystkich książąt wojsk, którzy z nim byli, uradowali się;
Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn Iṣmaeli tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ rí Johanani ọmọkùnrin Karea àti àwọn olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì yọ̀.
14 A obróciwszy się wszystek on lud, który był wziął w niewolę Izmael z Masfy, wrócił się zasię, a przyszedł do Johanana, syna Kareaszowego.
Gbogbo àwọn ènìyàn tí Iṣmaeli ti kó ní ìgbèkùn ní Mispa yípadà, wọ́n sì lọ sọ́dọ̀ Johanani ọmọ Karea.
15 Ale Izmael, syn Natanijaszowy, uszedł z ośmioma mężami przed Johananem, i przyszedł do synów Ammonowych.
Ṣùgbọ́n Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah àti àwọn mẹ́jọ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀ bọ́ lọ́wọ́ Johanani, wọ́n sì sálọ sí Ammoni.
16 Przetoż wziął Johanan, syn Kareaszowy, i wszyscy książęta wojsk, którzy z nim byli, wszystek ostatek ludu, który zaś przywiódł od Izmaela, syna Natanijaszowego, z Masfy, gdy zabił Godolijasza, syna Ahikamowego, mężów walecznych, i niewiasty, i dziatki, i komorników, których zaś przywiódł z Gabaonu.
Lẹ́yìn náà Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí wọn wà pẹ̀lú rẹ̀ sì kó gbogbo àwọn tí ó kù ní Mispa; àwọn tí ó ti rí gbà lọ́wọ́ Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah; lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa Gedaliah ọmọ Ahikamu. Àwọn ọmọ-ogun, àwọn obìnrin, àwọn ọmọdé àti àwọn olórí ilé ẹjọ́ tí ó ti kó wa láti Gibeoni.
17 A odszedłszy pomieszkali w gospodzie Chimchamowej, która jest u Betlehemu, aby idąc uszli do Egiptu przed Chaldejczykami;
Wọ́n sì kúrò níbẹ̀, wọ́n dúró ní Geruti Kimhamu ní ẹ̀bá Bẹtilẹhẹmu ní ọ́nà ìrìnàjò wọn sí Ejibiti.
18 Bo się ich bali, przeto, że był zabił Izmael, syn Natanijaszowy, Godolijasza, syna Ahikamowego, którego był przełożył król Babiloński nad oną ziemią.
Láti gba àwọn Babeli sílẹ̀. Wọ́n bẹ̀rù wọn nítorí wí pé, “Iṣmaeli ọmọ Netaniah ti pa Gedaliah ọmọ Ahikamu èyí tí ọba Babeli ti yàn gẹ́gẹ́ bí i gómìnà lórí ilẹ̀ náà.”

< Jeremiasza 41 >