< Jeremiasza 39 >

1 Roku dziewiątego Sedekijasza, króla Judzkiego, miesiąca dziesiątego, przyciągnął Nabuchodonozor, król Babiloński, ze wszystkiem wojskiem swojem do Jeruzalemu, i oblegli je.
Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
2 A jedenastego roku Sedekijasza, miesiąca czwartego, dziewiątego dnia tegoż miesiąca, dobyto miasta.
Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
3 I wpadli do niego wszyscy książęta króla Babilońskiego, i usiedli w bramie średniej: Nergalscharezer, Samgarnebu, Sarsechym, Rabsarys, Nergalscharezer, Rabmag, i wszyscy inni książęta króla Babilońskiego.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
4 A gdy ich ujrzał Sedekijasz, król Judzki, i że wszyscy mężowie waleczni uciekli, i wyszli w nocy z miasta drogą ogrodu królewskiego, bramą między dwoma murami, uszedł też i król drogą ku puszczy.
Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
5 A wojsko Chaldejczyków goniło ich, i doścignęli Sedekijasza na równinach Jerycha, i wzięli go, i przywiedli go do Nabuchodonozora, króla Babilońskiegp, do Reble, do ziemi Emat, gdzie wydał przeciwko niemu dekret.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
6 Bo pomordował król Babiloński synów Sedekijaszowych w Rebli przed oczyma jego, i wszystkich najprzedniejszych z Judy pomordował król Babiloński.
Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
7 Ale oczy Sedekijaszowi wyłupił, a związawszy go łańcuchami miedzianemi prowadził go do Babilonu.
Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
8 Dom także królewski i dom onego ludu spalili Chaldejczycy ogniem, i mury Jeruzalemskie rozwalili.
Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
9 Ale ostatek ludu, który był został w mieście, i zbiegi, którzy byli pouciekali do niego, i inny lud pozostały zawiódł Nabuzardan, hetman żołnierski, do Babilonu.
Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
10 Tylko najpodlejszych z ludu, którzy nic nie mieli, zastawił Nabuzardan, hetman żołnierski, w ziemi Judzkiej, którym rozdał winnice i role dnia onego.
Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
11 A o Jeremijaszu przykazał Nabuchodonozor, król Babiloński, Nabuzardanowi, hetmanowi żołnierskiemu, mówiąc:
Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
12 Weźmij go, a pilnie go doglądaj, a nie czyń mu nic złego, ale jakoć rzekę, tak z nim postąp.
“Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
13 Przetoż posławszy Nabuzardan, hetman żołnierski, i Nebusasban, Rabsarys i Nergalscharezer, Rabmag, i wszyscy hetmani króla Babilońskiego;
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
14 Posławszy, mówię, wzięli Jeremijasza z sieni straży, i poruczyli go Godolijaszowi, synowi Ahikama, syna Safanowego, aby go dowiódł do domu. A tak mieszkał w pośród ludu.
ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 I stało się do Jeremijasza słowo Pańskie, gdy jeszcze był zamknięty w sieni straży, mówiąc:
Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
16 Idź, a powiedz Ebedmelechowi Murzynowi, mówiąc: Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Oto Ja przywiodę słowa moje na to miasto ku złemu a nie ku dobremu, i wypełnią się przed obliczem twojem dnia onego;
“Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
17 Ale ciebie wybawię onegoż dnia, mówi Pan, i nie będziesz podany w rękę mężów, których się ty oblicza boisz.
Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
18 Albowiem cię pewnie wyrwę, abyś od miecza nie upadł; ale będziesz miał duszę twoję za korzyść, przeto, żeś położył nadzieję we mnie, mówi Pan.
Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”

< Jeremiasza 39 >