< Jeremiasza 37 >

1 Potem królował król Sedekijasz, syn Jozyjaszowy, miasto Chonijasza, syna Joakimowego, którego Nabuchodonozor, król Babiloński, w ziemi Judzkiej królem postanowił.
Sedekiah ọmọ Josiah sì jẹ ọba ní ipò Jehoiakini ọmọ Jehoiakimu ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Juda.
2 Lecz nie był posłuszny on, i słudzy jego, i lud onej ziemi słowom Pańskim, które mówił przez Jeremijasza proroka.
Ṣùgbọ́n àti òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kò fetísí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípa wòlíì Jeremiah.
3 Ale jednak król Sedekijasz posłał Jechuchala, syna Selemijaszowego, i Sofonijasza, syna Maazejaszowego, kapłana, do Jeremijasza proroka, aby mówili: Módl się proszę za nami Panu, Bogu naszemu.
Sedekiah ọba sì rán Jehukali ọmọ Ṣelemiah àti Sefaniah ọmọ Maaseiah sí Jeremiah wòlíì wí pé, “Jọ̀wọ́ gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
4 Bo Jeremijasz jeszcze wolno chodził między ludem, i jeszcze go było nie wsadzono do więzienia.
Nígbà yìí Jeremiah sì ń wọlé, ó sì ń jáde láàrín àwọn ènìyàn nítorí wọ́n ti fi sínú túbú.
5 A wojsko Faraonowe wyciągnęło było z Egiptu; (a usłyszawszy Chaldejczycy, którzy byli oblegli Jeruzalem, wieść o tem, odciągnęli od Jeruzalemu.)
Àwọn ọmọ-ogun Farao ti jáde kúrò nílẹ̀ Ejibiti àti nígbà tí àwọn ará Babeli tó ń ṣàtìpó ní Jerusalẹmu gbọ́ ìròyìn nípa wọn, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.
6 I stało się słowo Pańskie do Jeremijasza proroka, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì Ọlọ́run wá:
7 To mówi Pan, Bóg Izraelski: Tak powiedzcie królowi Judzkiemu, który was posłał do mnie, abyście się mnie radzili: Oto wojsko Faraonowe, które wam przyciągnęło na pomoc, wróci się do ziemi swojej do Egiptu.
“Èyí ni, ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ fún ọba àwọn Juda tó rán ọ láti wádìí nípa mi. ‘Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáde láti kún ọ lọ́wọ́ yóò padà sílẹ̀ wọn sí Ejibiti.
8 I wrócą się zasię Chaldejczycy, i będą walczyli przeciwko temu miastu, i wezmą je, i spalą je ogniem.
Nígbà náà ni àwọn ará Babeli yóò padà láti gbógun ti ìlú. Wọn yóò mú wọn nígbèkùn, wọn yóò sì fi iná jó ìlú náà kanlẹ̀.’
9 Tak mówi Pan: Nie zwodźcie dusz waszych, mówiąc: Zapewne odciągną od nas Chaldejczycy; boć nie odciągną.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Babeli yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú.’ Wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀.
10 Owszem, choćbyście porazili wszystko wojsko Chaldejczyków, którzy walczą z wami, a zostaliby z nich tylko zranieni, ci z namiotów swoich powstaną, a to miasto ogniem spalą.
Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ-ogun Babeli tí ń gbóguntì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”
11 Gdy tedy odciągnęło wojsko Chaldejczyków od Jeruzalemu przed wojskiem Faraonowem,
Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ-ogun Babeli ti kúrò ní Jerusalẹmu nítorí àwọn ọmọ-ogun Farao.
12 Wychodził Jeremijasz z Jeruzalemu, aby szedł do ziemi Benjaminowej, aby tak uszedł z pośrodku ludu.
Jeremiah múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Benjamini láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrín àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀.
13 A gdy już był w bramie Benjaminowej, był tam przełożony nad strażą, imieniem Jeryjasz, syn Selemijasza, syna Chananijaszowego, który pojmał Jeremijasza proroka, mówiąc: Do Chaldejczyków ty uciekasz.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ẹnu ibodè Benjamini, olórí àwọn olùṣọ́ tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Irijah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Hananiah mú un, ó wí pé, “Ìwọ ń fi ara mọ́ àwọn ará Babeli.”
14 A Jeremijasz odpowiedział: Nieprawda, nie uciekam do Chaldejczyków; ale go nie chciał słuchać, owszem, pojmał Jeryjasz Jeremijasza, i przywiódł go do książąt.
Jeremiah sọ wí pé, “Èyí kì í ṣe òtítọ́! Èmi kò yapa sí àwọn ará Babeli.” Ṣùgbọ́n Irijah ko gbọ́ tirẹ̀, dípò èyí a mú Jeremiah, ó sì mú un lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè.
15 Tedy rozgniewawszy się książęta na Jeremijasza, ubili go, i podali go do więzienia, do domu Jonatana pisarza; bo z niego byli uczynili dom więzienia.
Nítorí náà ni àwọn ìjòyè ṣe bínú sí Jeremiah, wọ́n jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n tún fi sí túbú nílé Jonatani akọ̀wé nítorí wọ́n ti fi èyí ṣe ilé túbú.
16 A gdy wszedł Jeremijasz do onego domu a do tarasu ich, i siedział tam Jeremijasz przez wiele dni;
Wọ́n fi Jeremiah sínú túbú tí ó ṣókùnkùn biribiri; níbi tí ó wà fún ìgbà pípẹ́.
17 Tedy posławszy król Sedekijasz, wziął go, i pytał go król w domu swoim potajemnie, mówiąc: Jestże jakie słowo od Pana? I odpowiedział Jeremijasz: Jest; przytem rzekł: W rękę króla Babilońskiego podany będziesz.
Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ sí i, tí ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú wá sí ààfin níbi tí ó ti bi í ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kan wà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?” Jeremiah fèsì pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, wọn ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Babeli.”
18 Nadto rzekł Jeremijasz do króla Sedekijasza: Cóżem zgrzeszył przeciwko tobie, i sługom twoim, i ludowi twemu, żeście mię podali do tego domu więzienia?
Nígbà náà, Jeremiah sọ fún ọba Sedekiah pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú?
19 I gdzież są prorocy wasi, którzy wam prorokują, mówiąc: Nie przyjdzie król Babiloński na was, ani na tę ziemię?
Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín wí pé ọba Babeli kò ní gbóguntì yín wá?
20 Słuchajże teraz, proszę, królu, panie mój! niech będzie, proszę, ważna prośba moja przed tobą: Nie odsyłajże mię do domu Jonatana pisarza, abym tam nie umarł.
Ṣùgbọ́n ní báyìí, olúwa mi ọba, èmí bẹ̀ ọ. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jonatani akọ̀wé, àfi kí n kú síbẹ̀.”
21 A tak rozkazał król Sedekijasz, aby wsadzony był Jeremijasz do sieni straży, a iżby mu dawano bochenek chleba na dzień z ulicy piekarskiej, pókiby nie był strawiony wszystek chleb w mieście. A tak siedział Jeremijasz w sieni straży.
Ọba Sedekiah wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremiah sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà tó wà ní ìlú yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremiah wà nínú àgbàlá náà.

< Jeremiasza 37 >