< Jeremiasza 34 >

1 Słowo, które się stało do Jeremijasza od Pana, (gdy Nabuchodonozor, król Babiloński, i wszystko wojsko jego, i wszystkie królestwa ziemi, które były pod władzą ręki jego, i wszystkie narody walczyły przeciwko Jeruzalemowi i przeciwko wszystkim miastom jego, ) mówiąc:
Nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ ọba tí ó jẹ ọba lé lórí ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yíká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
2 Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Idź, a mów Sedekijaszowi, królowi Judzkiemu, i powiedz mu: Tak mówi Pan: Oto Ja to miasto podam w rękę króla Babilońskiego, aby je ogniem spalił;
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ọmọ-ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekiah ọba Juda kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa ìlú yìí lé ọba Babeli lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
3 I ty nie ujdziesz ręki jego, ale zapewne będziesz pojmany, i w ręce jego podany, a oczy twoje oglądają oczy króla Babilońskiego, i usta jego z usty twemi mówić będą, a do Babilonu wnijdziesz.
Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí ọba Babeli pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Babeli.
4 A wszakże słuchaj słowa Pańskiego, Sedekijaszu, królu Judzki! Tak mówi Pan o tobie: Nie umrzesz od miecza:
“‘Síbẹ̀, gbọ́ ìlérí Olúwa, ìwọ Sedekiah ọba Juda. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí nípa rẹ; ìwọ kì yóò ti ipa idà kú;
5 W pokoju umrzesz; a jako wonne rzeczy palono ojcom twoim, królom przeszłym, którzy byli przed tobą, tak palić będą i tobie, a płakać cię będą, mówiąc: Ach, panie! Bom Ja to słowo rzekł, mówi Pan.
ìwọ yóò kú ní àlàáfíà. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń ṣe iná ìsìnkú ní ọlá fún àwọn baba rẹ, ọba tí ó jẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò ṣe iná ní ọlá rẹ, wọn ó sì pohùnréré pé, “Yé, olúwa!” Èmi fúnra mi ni ó ṣèlérí yìí ni Olúwa wí.’”
6 Tedy mówił Jeremijasz prorok do Sedekijasza, króla Judzkiego, wszystkie te słowa w Jeruzalemie.
Nígbà náà ni Jeremiah wòlíì sọ gbogbo nǹkan yìí fún Sedekiah ọba Juda ní Jerusalẹmu.
7 Gdy wojsko króla Babilońskiego walczyło przeciwko Jeruzalemowi, i przeciwko wszystkim miastom Judzkim pozostałym, przeciwko Lachys, i przeciw Asekowi; albowiem te były pozostały z miast Judzkich miasta obronne.
Nígbà tí ogun ọba Babeli ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní Juda, Lakiṣi, Aseka; àwọn nìkan ni ìlú olódi tí ó kù ní Juda.
8 Słowo, które się stało do Jeremijasza od Pana, gdy uczynił król Sedekijasz przymierze ze wszystkim ludem, co był w Jeruzalemie, wolność im ogłaszając;
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá lẹ́yìn ìgbà tí ọba Sedekiah ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu láti polongo ìtúsílẹ̀ fún àwọn ẹrú.
9 To jest, aby każdy wolno puścił sługę swego, i każdy służebnicę swoję, Żyda i Żydówkę, aby sobie nikt nie zniewalał Żyda, brata swego.
Kí oníkálùkù lè jẹ́ kí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin tí í ṣe Heberu lọ lọ́fẹ̀ẹ́, kí ẹnikẹ́ni kí ó má mú ará Juda arákùnrin rẹ̀ sìn.
10 A tak usłuchały wszyscy książęta, i wszystek lud, którzy byli weszli w przymierze, żeby każdy wolno puścił sługę swego, i każdy służebnicę swoję, aby ich więcej nie zniewalali; usłuchali, mówię, i puścili ich wolno.
Nítorí náà, gbogbo àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọwọ́ sí májẹ̀mú náà láti dá ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin sílẹ̀ kí wọ́n sì má ṣe fi wọ́n sínú ìgbèkùn mọ́. Wọ́n sì gbà, wọ́n sì jẹ́ kí wọn lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
11 Lecz potem rozmyśliwszy się, pobrali zaś sługi i służebnice, które byli puścili wolno, a zniewolili ich sobie za sługi i za służebnice.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, wọ́n yí ọkàn wọn padà; wọ́n sì mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀ padà láti tún máa sìn wọ́n.
12 I stało się słowo Pańskie do Jeremijasza od Pana, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
13 Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Jam postanowił przymierze z ojcami waszymi w dzień, któregom ich wywiódł z ziemi Egipskiej, z domu niewoli, mówiąc:
“Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí pé: Mo dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín nígbà tí mo mú wọn kúrò ní Ejibiti; kúrò ní oko ẹrú. Mo wí pé,
14 Gdy się skończą siedm lat, niech wolno puści każdy brata swego Żyda, któryćby był sprzedany, a służyłciby przez sześć lat; wolno, mówię, puści go od siebie. Ale mię nie słuchali ojcowie wasi, ani nakłonili ucha swego.
‘Ní ọdún keje, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ tú àwọn Heberu tí wọ́n ti ta ara wọn fún un yín sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti sìn yín fún ọdún mẹ́fà. Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn kí ó lọ’; ṣùgbọ́n àwọn baba yín kò gbọ́; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí mi.
15 Wyścieć się zaiste dziś nawrócili, i uczyniliście to, co jest dobrego przed oczyma mojemi, żeście ogłosili wolność każdy bliźniemu swemu, i uczyniliście przymierze przed twarzą moją w domu tym, który jest nazwany od imienia mego.
Láìpẹ́ yìí ẹ ti ronúpìwàdà, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì ṣe ìtúsílẹ̀ fún àwọn ènìyàn. Ẹ sì tún bá mi dá májẹ̀mú ní àwọn ilé tí a ti ń pe orúkọ mi.
16 Aleście się zaś cofnęli, i splugawiliście imię moje, żeście zaś wzięli każdy sługę swego, i każdy służebnicę swoję, któreście byli wolno puścili według żądności ich, i zniewoliliście ich, aby byli sługami i służebnicami waszymi.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yípadà, ẹ sì sọ orúkọ mi di èérí, olúkúlùkù sì mú kí àwọn ẹni rẹ tí ó ti sọ di òmìnira bí ọkàn wọn ti fẹ́ padà; ẹ̀yin sì tún fi wọ́n ṣe ẹrú.
17 Dlategoż tak mówi Pan: Wyście mię nie słuchali, abyście ogłosili wolność każdy bratu swemu, i każdy bliźniemu swemu; otoż Ja przeciwko wam ogłaszam wolność, mówi Pan, miecza, moru, i głodu, a podam was na potłukanie po wszystkich królestwach ziemi.
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Ẹ̀yin kò fetí sí mi nípa ọ̀rọ̀ òmìnira láàrín ẹ̀gbọ́n sí àbúrò, láàrín ẹnìkan sí èkejì rẹ̀. Wò ó, èmi yóò kéde òmìnira fún un yín ni Olúwa wí. Sí idà, sí àjàkálẹ̀-ààrùn, àti sí ìyàn, èmi ó sì fi yín fún ìwọ̀sí ní gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé.
18 Podam zaiste tych ludzi, którzy przestąpili przymierze moje, którzy nie dotrzymali słów przymierza tego, które uczynili przed twarzą moją, gdy cielca na dwoje rozcięli, i przeszli między częściami jego;
Èmi ó ṣe àwọn ọkùnrin náà tí ó da májẹ̀mú mi, tí kò tẹ̀lé májẹ̀mú tí wọ́n ti dá níwájú mi bí ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì, tí ó sì kọjá láàrín ìpín méjì náà.
19 To jest książąt Judzkich, i książąt Jeruzalemskich, komorników i kapłanów, i wszystek lud tej ziemi, którzy przeszli między częściami tego cielca,
Àwọn ìjòyè Juda àti àwọn ti Jerusalẹmu, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrín àwọn ìpín méjèèjì ẹgbọrọ màlúù náà.
20 Podam ich mówię, w rękę nieprzyjaciół ich, i w rękę szukających duszy ich, i będą trupy ich żerem ptastwu niebieskiemu i bestyjom ziemskim.
Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko igbó.
21 Sedekijasza też, króla Judzkiego, i książąt jego podam w rękę nieprzyjaciół ich, i w rękę szukających duszy ich, w rękę, mówię, wojska króla Babilońskiego, które odstąpiło od was.
“Sedekiah ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Juda ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Babeli tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.
22 Oto Ja rozkażę, mówi Pan, i przywiodę ich zaś na to miasto, aby walczyli przeciwko niemu, a wziąwszy je spalili je ogniem; miasta też Judzkie obrócę w pustynię, tak iż będą bez obywatela.
Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì bá a jà, wọn ó sì kó o, wọn ó fi iná jó o. Èmi ó sì sọ ìlú Juda dí ahoro.”

< Jeremiasza 34 >