< Jeremiasza 27 >

1 Na początku królowania Joakima, syna Jozyjasza, króla Judzkiego, stało się to słowo do Jeremijasza od Pana, mówiąc:
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
2 Tak mówi Pan do mnie: Uczyń sobie okowy i jarzma, a włóż je na szyję swoję:
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
3 Potem je poślij do króla Edomskiego, i do króla Moabskiego, i do króla synów Ammonowych, i do króla Tyrskiego, i do króla Sydońskiego, przez rękę posłów, którzy przyjdą do Jeruzalemu do Sedekijasza, króla Judzkiego;
Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
4 A rozkaż im, aby panom swym powiedzieli: Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski, tak powiecie panom waszym:
Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
5 Jam uczynił ziemię, także człowieka i bydlęta, którekolwiek są na obliczu ziemi, mocą swoją wielką i ramieniem swojem wyciągnionem: przeto ja daję temu, który się podoba oczom moim.
Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
6 A teraz dałem te wszystkie ziemie w rękę Nabuchodonozora, króla Babilońskiego, sługi mego; nadto i zwierzęta polne dałem mu, aby mu służyły.
Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
7 Przetoż będą mu służyły te wszystkie narody, i synowi jego i synowi syna jego, dokądby nie przyszedł czas ziemi jego i jego samego, gdy go też zaś sobie w niewolę podbiją narody zacne, i królowie wielcy.
Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
8 A ten naród i to królestwo, któreby mu nie służyło, to jest Nabuchodonozorowi, królowi Babilońskiemu, i któryby nie poddał szyi swojej pod jarzmo króla Babilońskiego, mieczem, i głodem, i morem nawiedzę ten naród, mówi Pan, dokądbym ich do końca nie wytracił ręką jego.
“‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
9 Przetoż wy nie słuchajcie proroków swoich, i wieszczków swoich, ani snów swoich, ani wróżków swoich, i czarowników swoich, którzy wam powiadają, mówiąc: Nie będziecie służyli królowi Babilońskiemu;
Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
10 Bo wam oni kłamstwo prorokują, abym was oddalił od ziemi waszej, a wygnał was, abyście poginęli.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
11 A naród, który poddał szyję swą pod jarzmo króla Babilońskiego, a któryby mu służył, ten zaiste zostawię w ziemi jego, (mówi Pan, ) aby ją sprawował, i mieszkał w niej.
Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
12 A do Sedekijasza, króla Judzkiego, rzekłem według tych wszystkich słów, mówiąc: Poddajcie szyje wasze pod jarzmo króla Babilońskiego, a służcie mu i ludowi jego, a żyć będziecie.
Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
13 Przeczże macie zginąć, ty i lud twój, od miecza, od głodu i od powietrza, jako mówił Pan o narodzie, któryby nie służył królowi Babilońskiemu?
Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
14 Nie słuchajcież tedy słów tych proroków, którzy mówiąc do was powiadają: Nie będziecie służyli królowi Babilońskiemu; albowiem wam oni kłamstwo prorokują.
Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
15 Nie posłałem ich zaiste, mówi Pan; wszakże oni prorokują w imię moje kłamliwie, abym was zapędził, gdziebyście zginęli, wy i ci prorocy, którzy wam prorokują.
‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
16 Do kapłanów też, i do tego wszystkiego ludu rzekłem, mówiąc: Tak mówi Pan: Nie słuchajcie słów proroków swoich, którzy wam prorokują, mówiąc: Oto naczynia domu Pańskiego teraz w rychle przywrócone będą z Babilonu; bo wam oni kłamstwo prorokują.
Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
17 Nie słuchajcież ich; służcie królowi Babilońskiemu, a żyć będziecie; przeczżeby to miasto miało być pustynią?
Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
18 A jeźliż oni są prorokami, i jeźli jest słowo Pańskie w nich, proszę, niech zabieżą Panu zastępów, aby te naczynia, które pozostały w domu Pańskim; i w domu króla Judzkiego, i w Jeruzalemie, nie dostały się do Babilonu.
Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
19 Bo tak mówi Pan zastępów o tych słupach, i o tem morzu, i o tych podstawkach, i o ostatku naczynia, które pozostało w tem mieście;
Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
20 Którego nie zabrał Nabuchodonozor, król Babiloński, gdy w niewolę prowadził Jechonijasza, syna Joakimowego, króla Judzkiego, z Jeruzalemu do Babilonu, i wszystkich przedniejszych, z Judy i z Jeruzalemu:
Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
21 Tak zaiste mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski, o tych naczyniach, które pozostały w domu Pańskim, i w domu króla Judzkiego, i w Jeruzalemie:
Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
22 Do Babilonu zawiezione będą, a będą tam aż do dnia, którego je nawiedzę, mówi Pan, i każę je przywieźć i przywrócić na to miejsce.
‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”

< Jeremiasza 27 >