< Jeremiasza 26 >
1 Na początku królowania Joakima, syna Jozyjasza, króla Judzkiego, stało się to słowo od Pana, mówiąc:
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
2 Tak mówi Pan: Stań w sieni domu Pańskiego, a mów do wszystkich miast Judzkich, do przychodzących kłaniać się w domu Pańskim, wszystkie słowa, któreć rozkazuję mówić do nich; nie ujmuj i słowa.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa, sọ fún gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà.
3 Owa snać usłuchają, a nawrócą się każdy od złej drogi swej, abym pożałował złego, którem im umyślił uczynić dla złości spraw ich.
Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n.
4 I rzecz do nich: Tak mówi Pan: Jeźli mię nie usłuchacie, żebyście chodzili w zakonie moim, którym wam przedłożył.
Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín,
5 Słuchając słów sług moich proroków, których Ja posyłam do was, jakoście, gdym ich rano wstawając posyłał, nie usłuchali:
àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́),
6 Tedy uczynię temu domowi jako Sylo, a to miasto dam na przeklęstwo wszystkim narodom ziemi.
nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’”
7 A kapłani i prorocy i wszystek lud słyszeli Jeremijasza mówiącego te słowa w domu Pańskim.
Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa.
8 A skoro przestał Jeremijasz mówić wszystko, co mu był rozkazał Pan mówić wszystkiemu ludowi, pojmali go oni kapłani i prorocy, i wszystek on lud mówiąc: Śmiercią umrzesz.
Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú!
9 Czemuś prorokował w imię Pańskie, mówiąc: Stanie się temu domowi jako Sylo, a to miasto tak spustoszeje, że w niem nie będzie obywatela? I zgromadzał się wszystek lud przeciwko Jeremijaszowi do domu Pańskiego.
Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.
10 Tedy usłyszawszy te rzeczy książęta Judzcy, przyszli z domu królewskiego do domu Pańskiego, i usiedli w wejściu nowej bramy Pańskiej.
Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa.
11 I rzekli kapłani i prorocy do onych książąt, i do wszystkiego ludu, mówiąc: Ten mąż godzien jest śmierci; bo prorokował przeciwko miastu temu, jakoście to słyszeli w uszy swoje.
Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”
12 Tedy rzekł Jeremijasz do wszystkich książąt, i do wszystkiego ludu, mówiąc: Pan mię posłał, abym prorokował o tym domu i o tem mieście wszystko to, coście słyszeli.
Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́.
13 Przetoż teraz poprawcie drogi swoje i sprawy swe, a usłuchajcie głosu Pana, Boga swego, a pożałuje Pan tego złego, które wyrzekł przeciwko wam.
Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín.
14 A ja otom jest w rękach waszych; czyńcie zemną, co dobrego i sprawiedliwego jest w oczach waszych.
Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi.
15 A wszakże zapewne wiedzcie, jeźliż mię zabijecie, że krew niewinną zwalicie na się i na to miasto, i na obywateli jego; bo mię zaprawdę Pan do was posłał, abym mówił te wszystkie słowa w uszy wasze.
Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”
16 I rzekli książęta i wszystek lud do kapłanów i do onych proroków: Niema być żadnym sposobem ten mąż osądzony na śmierć, ponieważ w imieniu Pana, Boga naszego, mówił do nas.
Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”
17 Tedy powstali niektórzy z starszych onej ziemi, i uczynili rzecz do wszystkiego zgromadzenia ludu, mówiąc:
Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé,
18 Micheasz Morastytczyk prorokował za dni Ezechijasza, króla Judzkiego, i rzekł do wszystkiego ludu Judzkiego, mówiąc: Tak mówi Pan zastępów: Syon jako pole poorany będzie, a Jeruzalem jako gromady rumu będzie, a góra domu tego jako wysokie lasy.
“Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘A ó sì fa Sioni tu bí oko Jerusalẹmu yóò di òkìtì àlàpà àti òkè ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ibi gíga igbó.’
19 Izali go zaraz dlatego zabili Ezechijasz, król Judzki, i wszystek Juda? izali się nie ulękł Pana, a nie modlił się Panu? I żałował Pan onego złego, które był wyrzekł przeciwko nim: przetoż my złą rzecz czynimy przeciwko duszom naszym.
Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”
20 Także też był mąż prorokujący w imieniu Pańskiem, Uryjasz, syn Semejaszowy, z Karyjatyjarym, który prorokował o tem mieście i o tej ziemi według wszystkich słów Jeremijaszowych.
(Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe.
21 A gdy usłyszał król Joakim, i wszystko rycerstwo jego, i wszyscy książęta słowa jego, zaraz go chciał król zabić, co usłyszawszy Uryjasz uląkł się, a uciekłszy przyszedł do Egiptu.
Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti.
22 Ale król Joakim posłał niektórych do Egiptu, Elnatana, syna Achborowego, i innych z nim do Egiptu;
Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn.
23 Którzy wywiódłszy Uryjasza z Egiptu, przywiedli go do króla Joakima; i zabił go mieczem, i wrzucił trupa jego do grobów ludu pospolitego.
Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)
24 Wszakże ręka Achikama, syna Safanowego, była przy Jeremijaszu, aby nie był wydan w ręce ludu, i nie był zabity.
Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.