< Jeremiasza 24 >

1 Ukazał mi Pan, a oto dwa kosze fig postawione były przed kościołem Pańskim, gdy był w niewolę zabrał Nabuchodonozor, król Babiloński, Jechonijasza, syna Joakima, króla Judzkiego, i książąt Judzkich, i cieśli, i kowali z Jeruzalemu, a zawiódł ich do Babilonu.
Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
2 Kosz jeden miał figi bardzo dobre, jako bywają figi dojrzałe; a kosz drugi miał figi bardzo złe, których jeść nie można, przeto, iż były złe.
Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
3 I rzekł Pan do mnie: Cóż widzisz? Jeremijaszu! I rzekłem: Figi. Figi dobre są bardzo dobre, a złe są bardzo złe, których jeść nie mogą, przeto, iż są złe.
Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
4 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
5 Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Jako te figi są dobre, tak mi przyjemni będą w niewolę zaprowadzeni z Judy, którychem wysłał z miejsca tego do ziemi Chaldejskiej ku dobremu.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
6 I obrócę oko moje na nich ku dobremu, i przywiodę ich do tej ziemi, gdzie ich pobuduję, a nie skażę, i wszczepię ich, a nie wykorzenię.
Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
7 Albowiem dam im serce, aby mię poznali, żem Ja Pan; i będą mi ludem moim, a Ja będę Bogiem ich, gdy się nawrócą do mnie całem sercem swojem.
Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
8 A jako figi złe, których nie jadają, przeto, że są złe, tak zarzucę (toć zaiste mówi Pan, ) Sedekijasza, króla Judzkiego, i książąt jego, i ostatki z Jeruzalemu, które pozostały w tej ziemi, i tych, którzy mieszkają w ziemi Egipskiej.
“‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
9 Podam ich, mówię, na utrapienie, i na ucisk po wszystkich królestwach ziemi, na pohańbienie i na przypowieść, na przysłowie i na przeklęstwo po wszystkich miejscach, do których ich zapędzę;
Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
10 I będę posyłał na nich miecz, głód i mór, aż do końca wytraceni będą z ziemi, którąm był dał im, i ojcom ich.
Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”

< Jeremiasza 24 >