< Jeremiasza 22 >

1 Tak mówi Pan: Zstąp do domu króla Judzkiego, a mów tam to słowo,
Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
2 I rzecz: Słuchaj słowa Pańskiego, królu Judzki! który siedzisz na stolicy Dawidowej, ty i słudzy twoi, i lud twój, którzy chodzicie bramami temi.
‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
3 Tak mówi Pan: Czyńcie sąd i sprawiedliwość, a wyzwalajcie uciśnionego z ręki gwałtownika, a przychdniowi, sierotce i wdowie nie czyńcie krzywdy, ani ich uciskajcie; ani krwi niewinnej nie wylewajcie na tem miejscu.
Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
4 Bo jeźli czyniąc uczynicie to słowo, tedy pewnie wnijdą bramami domu tego królowie, siedzący miasto Dawida na stolicy jego, jeżdżący na wozach i na koniach, sam król i słudzy jego, i lud jego.
Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
5 Lecz jeżli nie posłuchacie tych słów, sam na się przysięgam, mówi Pan, że ten dom pustynią będzie.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
6 Bo tak mówi Pan o domie króla Judzkiego: Tyś mi był jako Galaad i wierzch Libański; ale cię pewnie obrócę w pustenię, i miasta, w których nie mieszkają;
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
7 I zgotuję na cię burzycieli, każdego z orężem jego, którzy wyrąbią wyborne cedry twoje, i wrzucą je na ogień.
Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
8 A gdy pójdzie wiele narodów mimo to miasto, i rzecze jeden do drugiego: Dlaczegoż tak uczynił Pan temu miastu wielkimu?
“Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
9 Tedy odpowiedzą: Przeto, iż opuścili przymierze Pana, Boga swego, a kłaniali się bogom cudzym, i służyli im.
Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
10 Nie płaczcież umarłego, ani go żałujcie, ale ustawicznie płaczcie nad tym, który odchodzi; bo się więcej nie wróci, aby oglądał ziemię, w której się narodził.
Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
11 Bo tak mówi Pan o Sellumie, synu Jozyjasza, króla Judzkiego, który króluje miasto Jozyjasza, ojca swego: Gdy wyjdzie z miejsca tego, nie wróci się więcej,
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
12 Ale tam na onem miejscu, gdzie go przeniosą, umrze, a tak tej ziemi więcej nie ogląda.
Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
13 Biada temu, kto buduje dom swój z niesprawiedliwością, a pałace swoje z krzywdą, który bliźniego swego darmo zniewala, a zapłaty mu jego nie daje!
“Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
14 Który mówi: Zbuduję sobie dom wielki, i pałace przestworne; i wycina sobie okna, a obija drzewem cedrowem, i maluje cynobrem.
Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
15 Izali będziesz królował, że mieszkasz między cedrami? Ojciec twój izali nie jadał i nie pijał? kiedy czynił sąd i sprawiedliwość, tedy się miał dobrze;
“Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
16 Gdy sądził sprawę ubogiego, i nędznego, tedy się miał dobrze; izali to nie jest poznać mię? mówi Pan.
Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
17 Ale oczy twoje i serce twoje nie szuka jedno łakomstwa swego, i abyś krew niewinną wylewał, a gwałt i krzywdę czynił.
“Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
18 Przetoż tak mówi Pan o Joakimie, synu Jozyjasza, króla Judzkiego: Nie bądą go płakać ani mówić: Ach bracie mój! albo: Ach siostro! Nie będą go płakać ani mówić: Ach panie! albo: Ach! gdzież dostojność jego?
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
19 Pogrzebem oślim pogrzebiony bądzie; wywleczony i wyrzucony będzie za bramy Jeruzalemskie.
A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
20 Wstąp na Liban, a wołaj, i na górze Basan wydaj głos twój; wołaj i u brodów, gdyż starci będą wszyscy miłośnicy twoi.
“Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
21 Mawiałem z tobą w największem szczęściu twojem; aleś ty rzekła: Nie posłucham. Tać jest droga twoja od dzieciństwa twego, nie usłuchałeś zaiste głosu mego.
Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
22 Wszystkich pasterzy twoich wiatr spasie, a miłośnicy twoi w niewolę pójdą; tedy się zaiste zapałać i wstydzić będziesz dla wszelakiej złości twojej.
Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
23 O ty, która mieszkasz na Libanie, która sobie gniazdo czynisz na cedrach! jako wdzięczna będziesz, gdy cię ogarną boleści, a ucisk jako rodzącą.
Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
24 Jako żyję Ja, mówi Pan, iż choćby był Chonijasz, syn Joakima, króla Judzkiego, sygnetem na prawej ręce mojej, wszakże cię i stamtąd zerwę;
“Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
25 I podam cię w rękę tych, którzy szukaj duszy twojej, i w rękę tych, których się ty twarzy lękasz, to jest, w rękę Nabuchodonozora, króla Babilońskiego, i w rękę Chaldejczyków;
Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
26 A wyrzucę cię i matkę twoję, która cię urodziła, do ziemi cudzej, w którejście się nie rodzili, i tam pomrzecie.
Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
27 Ale do ziemi, do której tęsknić będziecie, abyście się tam wrócili, nie wrócicie się.
Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
28 Izali ten mąż Chonijasz będzie bałwanem nikczemnym, który podruzgotany bywa? Albo naczyniem, w którem niemasz żednej wdzięczności? Przeczżeby odrzuceni byli on i nasienie jego, a wyrzuceni do ziemi, której nie znają?
Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
29 O ziemio, ziemio, ziemio! słuchaj słowa Pańskiego.
Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
30 Tak mówi Pan: Zapiszcie to, że ten mąż będzie bez dzieci, a że mu się nie poszczęści za dni jego; owszem, nie poszczęści się i mężowi, któryby z nasienia jego siedział na stolicy Dawidowej, a panował jeszcze w Judzie.
Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”

< Jeremiasza 22 >