< Jeremiasza 20 >
1 Tedy usłyszawszy Fassur, syn Immerowy, kapłan, który był postanowiony przedniejszym w domu Pańskim, Jeremijasza prorokującego o tem;
Ní ìgbà tí àlùfáà Paṣuri ọmọkùnrin Immeri olórí àwọn ìjòyè tẹmpili Olúwa gbọ́ tí Jeremiah ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nǹkan wọ̀nyí.
2 Ubił Fassur Jeremijasza proroka, i dał go do więzienia, które było najwyższe w bramie Benjaminowej, a ta była przy domu Pańskim.
Ó mú kí wọ́n lù wòlíì Jeremiah, kí wọ́n sì fi sínú túbú tí ó wà ní òkè ẹnu-ọ̀nà ti Benjamini ní tẹmpili Olúwa.
3 A nazajutrz, gdy wywiódł Fassur Jeremijasza z więzienia, rzekł do niego Jeremijasz: Nie nazwał cię Pan Fassurem, ale Magor Missabib.
Ní ọjọ́ kejì tí Paṣuri tú u sílẹ̀ nínú túbú, Jeremiah sì sọ fún un wí pé, “Orúkọ Olúwa fun ọ kì í ṣe Paṣuri bí kò ṣe ìpayà.
4 Bo tak mówi Pan: Oto Ja puszczę na cię strach, na cię i na wszystkich przyjaciół twoich, którzy upadną od miecza nieprzyjaciół swych, na co oczy twoje patrzyć będą; a wszystkiego Judę podam w ręce króla Babilońskiego, który ich zaprowadzi do Babil onu, i pozabija ich mieczem.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ. Èmi yóò mú ọ di ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ sí ara rẹ àti sí gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Ní ojú ara rẹ, ìwọ yóò sì rí tí wọ́n ṣubú nípa idà ọ̀tá wọn. Èmi yóò fi gbogbo àwọn ọ̀tá Juda lé ọba Babeli lọ́wọ́, òun yóò sì kó wọn lọ sí Babeli tàbí kí ó pa wọ́n.
5 Dam też wszystkę majętność miasta tego, i wszstkę pracę jego, i wszystkie kosztowne rzeczy jego, i wszstkie skarby królów Judzkich dam w ręce nieprzyjaciół ich; i rozchwycą je, i zabiorą je, i zaprowadzą je do Babilonu.
Èmi yóò jọ̀wọ́ gbogbo ọrọ̀ inú ìlú yìí fún ọ̀tá wọn. Gbogbo ìní wọ́n gbogbo ọlá ọba Juda. Wọn yóò sì ru ìkógun lọ sí Babeli.
6 Ale ty, Fassurze! i wszyscy, którzy mieszkają w domu twym, pójdziecie w pojmanie, i do Babilonu przyjdziesz, i tam umrzesz, i tam pogrzebiony będziesz; ty i wszyscy miłujący cię, którymeś kłamliwie prorokował.
Àti ìwọ Paṣuri, gbogbo ènìyàn inú ilé rẹ yóò sì lọ ṣe àtìpó ní Babeli. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí, tí wọn yóò sì sin ọ́ síbẹ̀, ìwọ àti gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí ìwọ ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún.”
7 Namówiłeś mię, Panie! a dałem się namówić; mocniejszyś był niż ja, i przemogłeś; jestem na pośmiech każdy dzień, każdy się ze mnie naśmiewa.
Olúwa, o tàn mí jẹ́, o sì ṣẹ́gun. Mo di ẹni ẹ̀gàn ní gbogbo ọjọ́, gbogbo ènìyàn fi mí ṣẹlẹ́yà.
8 Bo jakom począł mówić, wołam, dla gwałtu i spustoszenia krzyczę; bo mi słowo Pańskie jest ku pohańbieniu i na pośmiech każdy dzień.
Nígbàkígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, èmi sì kígbe síta èmi á sọ nípa ipá àti ìparun. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ Olúwa ti mú àbùkù àti ẹ̀gàn bá mi ni gbogbo ìgbà.
9 I rzekłem: Nie będę go wspominał, ani będę więcej mówił w imieniu jego; ale słowo Boże jest w sercu mojem, jako ogień pałający, zamkniony w kościach moich, którym usiłował zatrzymać, alem nie mógł.
Ṣùgbọ́n bí mo bá sọ pé, “Èmi kì yóò dárúkọ rẹ tàbí sọ nípa orúkọ rẹ̀ mọ́, ọ̀rọ̀ rẹ̀ ń bẹ bi iná tí ń jó nínú mi nínú egungun mi, agara dá mi ní inú mi nítòótọ́ èmi kò lè ṣe é.
10 Chociaż słyszę urąganie od wielu i od Magor Missabiba, mówiących: Powiedzcie co nań, a oznajmiemy to królowi. Wszyscy przyjaciele moi czyhają na upadek mój, mówiąc: Aza snać zwiedziony będzie, i przemożemy go, a pomścimy się nad nim.
Mo gbọ́ sísọ ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ìbẹ̀rù ni ibi gbogbo. Fi í sùn! Jẹ́ kí a fi sùn! Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń dúró kí èmi ṣubú, wọ́n sì ń sọ pé, bóyá yóò jẹ́ di títàn, nígbà náà ni àwa yóò borí rẹ̀, àwa yóò sì gba ẹ̀san wa lára rẹ̀.”
11 Aleć Pan jest ze mną, jako mocarz straszny; przetoż ci, którzy mię prześladują, upadną, a nie przemogą; bardzo będą pohańbieni, że sobie niemądrze poczęli, hańba ich wieczna nie będzie zapamiętana.
Ṣùgbọ́n Olúwa ń bẹ pẹ̀lú mi gẹ́gẹ́ bí akọni ẹlẹ́rù. Nítorí náà, àwọn tí ó ń lépa mi yóò kọsẹ̀, wọn kì yóò sì borí. Wọn yóò kùnà, wọn yóò sì gba ìtìjú púpọ̀. Àbùkù wọn kì yóò sì di ohun ìgbàgbé.
12 Przetoż, o Panie zastępów! który doświadczasz sprawiedliwego, który wypatrujesz nerki i serce, niech widzę pomstę twoję nad nimi; tobiem zaiste odkrył sprawę moję.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìwọ tí ó ń dán olódodo wò tí o sì ń ṣe àyẹ̀wò ọkàn àti ẹ̀mí fínní fínní, jẹ́ kí èmi kí ó rí ìgbẹ̀san rẹ lórí wọn, nítorí ìwọ ni mo gbé ara mi lé.
13 Śpiewajcież Panu, chwalcie Pana, że wybawił duszę ubogiego z ręki złośników.
Kọrin sí Olúwa! Fi ìyìn fún Olúwa! Ó gba ẹ̀mí àwọn aláìní lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.
14 Przeklęty dzień, w którym się urodził; dzień, którego mię porodziła matka moja, niech nie będzie błogosławiony.
Ègbé ni fún ọjọ́ tí a bí mi! Kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má ṣe di ti ìbùkún.
15 Przeklęty mąż, który oznajmił ojcu memu, mówiąc: Urodziłoć się dziecię płci męskiej, aby go bardzo uweselił.
Ègbé ni fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún baba mi, tí ó mú kí ó yọ̀, tí ó sì sọ wí pé, “A bí ọmọ kan fún ọ—ọmọkùnrin!”
16 Niechże będzie on mąż jako miasta, które Pan podwrócił, a nie żałował tego; niech słyszy krzyk z poranku, i narzekanie czasu południa.
Kí ọkùnrin náà dàbí ìlú tí Olúwa gbàkóso lọ́wọ́ rẹ̀ láìkáàánú Kí o sì gbọ́ ariwo ọ̀fọ̀ ní àárọ̀, ariwo ogun ní ọ̀sán.
17 O że mię nie zabił zaraz z żywota! Oby mi była matka moja grobem moim, a żywot jej wiecznie brzemiennym!
Nítorí kò pa mí nínú, kí ìyá mi sì dàbí títóbi ibojì mi, kí ikùn rẹ̀ sì di títí láé.
18 Przeczżem wyszedł z żywota, abym doznał pracy i smutku, a żeby dni moje w hańbie strawione były?
Èéṣe tí mo jáde nínú ikùn, láti rí wàhálà àti ọ̀fọ̀ àti láti parí ayé mi nínú ìtìjú?