< Jeremiasza 15 >
1 Tedy rzekł Pan do mnie: Choćby stanął Mojżesz i Samuel przed obliczem mojem, nie miałbym serca do ludu tego; puść ich od oblicza mego, a niech precz idą.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
2 A jeźliby rzekli: Dokądże pójdziemy? Tedy im rzeczesz: Tak mówi Pan: Kto oddany na śmierć, na śmierć pójdzie; a kto pod miecz, pod miecz; a kto na głód, na głód; a kto w niewolę, w niewolę.
Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
3 Bo ich tą czworaką rzeczą nawiedzę, mówi Pan: Mieczem na zamordowanie, i psami na rozszarpanie, i ptastwem niebieskiem, i zwierzętami ziemskiemi na pożarcie i na wygubienie.
“Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
4 I podam ich na potłukanie się po wszystkich królestwach ziemi dla Manasesa, syna Ezechijasza, króla Judzkiego, za to, co uczynił w Jeruzalemie.
N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
5 Bo któżby się zmiłował nad tobą? Jeruzalemie! albo ktoby się użalił nad tobą? albo ktoby przyszedł, aby się pytał, jakoć się powodzi?
“Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
6 Tyś mię opuściło, mówi Pan, poszłoś nazad. Przetoż wyciągnę rękę moję na cię, abym cię wytracił; ustałem od żalu.
O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
7 Przetoż ich rozwieję wiejaczką po bramach tej ziemi, osierocę i wygubię ich; bo się od dróg swoich nie nawracali.
Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
8 Więcej się namnoży wdów jego, niż piasku morskiego; przywiodę na nich, na matki, na młodzieńców burzyciela i w południe; sprawię, że przypadną nagle na to miasto; i będą przestraszeni.
Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
9 Zemdleje i ta, która rodziła po siedmiorgu, wypuści duszę swoję, zajdzie jej słońce jeszcze za dnia, zapłonie i wstydzić się będzie; a ostatek ich dam pod miecz przed obliczem nieprzyjaciół ich, mówi Pan.
Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
10 Biada mnie, matko moja! żeś mię urodziła męża swaru, i męża sporu po wszystkiej ziemi; nie dawałem im na lichwę, ani mnie oni na lichwę dawali, a wżdy mi każdy złorzeczy.
Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
11 I rzekł Pan: Izali tobie, który pozostaniesz, nie będzie dobrze? Izali się nie zastawię o cię nieprzyjacielowi czasu utrapienia i czasu ucisku?
Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
12 Izali żelazo proste pokruszy żelazo północne i stal?
“Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
13 Majętność twoję, o Judo! i skarby twoje dam w rozszarpanie darmo po wszystkich granicach twoich, a to dla wszystkich grzechów twoich;
“Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
14 A sprawię to, że pójdziesz z nieprzyjaciółmi twymi do ziemi, którejś nie znał; albowiem ogień rozniecony w zapalczywości mojej na was pałać będzie.
Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
15 Ty mię znasz, Panie! wspomnijże na mię, a nawiedź mię, i pomścij się za mię nad tymi, co docierają na mię; odwłaczając zapalczywości twojej przeciwko nim, nie porywaj mię; wiedz, że podejmuję dla ciebie pohańbienie.
Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
16 Gdy się znalazły mowy twoje, zjadłem ich, a było mi słowo twoje weselem i radością serca mego, ponieważ się nazywam od imienia twego, Panie, Boże zastępów!
Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
17 Nie siadam w radzie naśmiewców, ani się z nimi raduję; ale dla surowości ręki twojej samotny siadam; bo zapalczywością napełniłeś mię.
Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
18 Przeczże ma być żal mój wieczny? a rana moja śmiertelna, która się uleczyć nie da? Przeczże mi tak masz być jako omylny, jako wody niepewne?
Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
19 Przetoż tak mówi Pan: Jeźli się nawrócisz, tedy cię nawrócę, abyś stał przed obliczem mojem; a jeźli odłączysz rzecz kosztowną od nikczemnej, będziesz jako usta moje; oni niech się obrócą do ciebie, ale się ty nie obracaj do nich.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
20 Bom cię postawił przeciw ludowi temu jako mur miedziany i obronny; i będą walczyć przeciwko tobie, ale cię nie przemogą; bom Ja z tobą, abym cię wybawiał i wyrywał, mówi Pan.
Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
21 Wyrwę cię zaiste z rąk ludzi złych, i odkupię cię z rąk okrutników.
“Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”