< Jakuba 5 >
1 Nuż teraz, bogacze! płaczcie, narzekając nad nędzami waszemi, które przyjdą.
Ẹ wá nísinsin yìí, ẹ̀yin ọlọ́rọ̀, ẹ máa sọkún kí ẹ sì máa pohùnréré ẹkún nítorí òsì tí ó ń bọ̀ wá ta yín.
2 Bogactwo wasze zgniło, a szaty wasze mole zgryzły.
Ọrọ̀ yín díbàjẹ́, kòkòrò sì ti jẹ aṣọ yín.
3 Złoto wasze i srebro wasze pordzewiało, a rdza ich będzie na świadectwo przeciwko wam i pożre ciała wasze jako ogień; zgromadziliście skarb na ostatnie dni.
Wúrà òun fàdákà yín díbàjẹ́; ìbàjẹ́ wọn ni yóò sì ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, tí yóò sì jẹ ẹran-ara yín bí iná. Ẹ̀yin tí kó ìṣúra jọ de ọjọ́ ìkẹyìn.
4 Oto, zapłata robotników, którzy żęli krainy wasze, od was zatrzymana woła, a wołania żeńców weszły do uszów Pana zastępów.
Kíyèsi i, ọ̀yà àwọn alágbàṣe tí wọ́n ti ṣe ìkórè oko yín, èyí tí ẹ kò san, ń ké rara; àti igbe àwọn tí ó ṣe ìkórè sì ti wọ inú etí Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
5 Żyliście w rozkoszach na ziemi i bujaliście; wytuczyliście serca wasze jako na dzień zabijania ofiar.
Ẹ̀yin ti jẹ adùn ní ayé, ẹ̀yin sì ti fi ara yín fún ayé jíjẹ; ẹ̀yin ti mú ara yín sanra de ọjọ́ pípa.
6 Potępiliście, zamordowaliście sprawiedliwego, a nie sprzeciwia się wam.
Ẹ̀yin ti dá ẹ̀bi fún olódodo, ẹ sì ti pa á; ẹni tí kò kọ ojú ìjà sí yín.
7 Przetoż, bracia! bądźcie cierpliwymi aż do przyjścia Pańskiego. Oto, oracz oczekuje drogiego pożytku ziemi, cierpliwie go oczekując, ażby otrzymał deszcz ranny i wieczorny.
Nítorí náà ará, ẹ mú sùúrù títí di ìpadà wá Olúwa. Kíyèsi i, àgbẹ̀ a máa retí èso iyebíye ti ilẹ̀, a sì mú sùúrù dè é, títí di ìgbà àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò.
8 Bądźcież i wy cierpliwymi, a utwierdzajcie serca wasze; albowiem się przybliża przyjście Pańskie.
Ẹ̀yin pẹ̀lú, ẹ mú sùúrù; ẹ fi ọkàn yín balẹ̀, nítorí ìpadà wá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.
9 Nie wzdychajcie jedni przeciwko drugim, bracia! abyście nie byli osądzeni. Oto, sędzia już przede drzwiami stoi.
Ẹ má ṣe kùn sí ọmọnìkejì yín, ará, kí a má ba à dá a yín lẹ́bi: kíyèsi i, onídàájọ́ dúró ní ẹnu ìlẹ̀kùn.
10 Bierzcie za przykład, bracia moi! utrapienia i cierpliwości proroków, którzy mówili w imieniu Pańskiem.
Ará mi, ẹ fi àwọn wòlíì tí ó ti ń sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa ṣe àpẹẹrẹ ìyà jíjẹ, àti sùúrù.
11 Oto za błogosławionych mamy tych, którzy cierpieli. O cierpliwości Ijobowej słyszeliście i koniec Pański widzieliście, iż wielce miłosierny jest Pan i litościwy.
Sá à wò ó, àwa a máa ka àwọn tí ó fi ara dà ìyà sí ẹni ìbùkún. Ẹ̀yin ti gbọ́ ti sùúrù Jobu, ẹ̀yin sì rí ìgbẹ̀yìn tí Olúwa ṣe; pé Olúwa kún fún ìyọ́nú, ó sì ní àánú.
12 A przed wszystkiemi rzeczami, bracia moi! nie przysięgajcie ani przez niebo, ani przez ziemię, ani żadną inszą przysięgą; ale niech będzie mowa wasza: Tak, tak; i Nie, nie; abyście w obłudę nie wpadli.
Ṣùgbọ́n ju ohun gbogbo lọ, ará mi, ẹ má ṣe ìbúra, ìbá à ṣe fífi ọ̀run búra, tàbí ilẹ̀, tàbí ìbúra-kíbúra mìíràn. Ṣùgbọ́n jẹ́ kí “Bẹ́ẹ̀ ni” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni; àti “Bẹ́ẹ̀ kọ́” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ kọ́; kí ẹ má ba à bọ́ sínú ẹ̀bi.
13 Jest kto utrapiony między wami, niechże się modli; jest kto dobrej myśli, niechajże śpiewa.
Inú ẹnikẹ́ni ha bàjẹ́ nínú yín bí? Jẹ́ kí ó gbàdúrà. Inú ẹnikẹ́ni ha dùn? Jẹ́ kí ó kọrin mímọ́.
14 Choruje kto między wami, niechże zawoła starszych zborowych, a niech się modlą za nim, pomazując go olejkiem w imieniu Pańskiem;
Ẹnikẹ́ni ha ṣe àìsàn nínú yín bí? Kí ó pe àwọn àgbà ìjọ, kí wọ́n sì gbàdúrà sórí rẹ̀, kí wọn fi òróró kùn ún ní orúkọ Olúwa.
15 A modlitwa wiary uzdrowi chorego i podniesie go Pan; a jeźliby się grzechu dopuścił, będzie mu odpuszczone.
Àdúrà ìgbàgbọ́ yóò sì gba aláìsàn náà là, Olúwa yóò sì gbé e dìde; bí ó bá sì ṣe pé ó ti dẹ́ṣẹ̀, a ó dáríjì í.
16 Wyznawajcie jedni przed drugimi upadki, a módlcie się za drugimi; abyście byli uzdrowieni. Wiele może uprzejma modlitwa sprawiedliwego.
Ẹ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín fún ara yín, kí ẹ sì máa gbàdúrà fún ara yín, kí a lè mú yín láradá. Iṣẹ́ tí àdúrà olódodo ń ṣe ní agbára púpọ̀.
17 Elijasz był człowiek tymże biedom poddany jako i my, a modlitwą modlił się, żeby deszcz nie padał; i nie padał deszcz na ziemię trzy lata i sześć miesięcy,
Ènìyàn bí àwa ni Elijah, ó gbàdúrà gidigidi pé kí òjò kí ó má ṣe rọ̀, òjò kò sì rọ̀ sórí ilẹ̀ fún ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà.
18 I zaś się modlił, a wydało niebo deszcz i ziemia zrodziła owoce swoje.
Ó sì tún gbàdúrà, ọ̀run sì tún rọ̀jò, ilẹ̀ sì so èso rẹ̀ jáde.
19 Bracia! jeźliby się kto z was obłądził od prawdy, a nawróciłby go kto,
Ará, bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá ṣìnà kúrò nínú òtítọ́, tí ẹni kan sì yí i padà;
20 Niechże wie, że kto by odwrócił grzesznika od błędnej drogi jego, zachowa duszę od śmierci i zakryje mnóstwo grzechów.
jẹ́ kí ó mọ̀ pé, ẹni tí ó bá yí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan padà kúrò nínú ìṣìnà rẹ̀, yóò gba ọkàn kan là kúrò lọ́wọ́ ikú, yóò sì bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.