< Izajasza 65 >

1 Objawiłem się tym, którzy się o mię nie pytali; znalezionym jest od tych, którzy mię nie szukali; do narodu, który się nie nazywał imieniem mojem. rzekłem: Otom Ja! otom Ja!
“Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi; àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi. Sí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò pe orúkọ mi, ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’
2 Rozciągnąłem ręce moje na każdy dzień do ludu upornego, który chodzi drogą nie dobrą za myślami swemi;
Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi síta sí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle, tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára, tí wọ́n sì gbára lé èrò ara wọn
3 Do ludu, który mię jawnie wzrusza do gniewu, ustawicznie ofiarując w ogrodach, a kadząc na cegłach;
àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbo lójú ara mi gan an, wọ́n ń rú ẹbọ nínú ọgbà wọ́n sì ń sun tùràrí lórí i pẹpẹ bíríkì;
4 Którzy siadają przy grobach, a przy bałwanach swoich nocują; którzy jedzą świnie mięso, i polewkę obrzydłą z naczynia swego.
wọ́n ń jókòó láàrín ibojì wọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀; tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀, tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;
5 Mówiąc: Odstąp precz, nie przystępuj do mnie; bom jest świętobliwszy niżeli ty. Cić są dymem w nozdrzach moich, i ogniem pałającym przez cały dzień.
tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’ Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú mi iná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.
6 Oto zapisano to przedemną: Nie zamilczę, ale oddam i odpłacę na łono ich.
“Kíyèsi i, a ti kọ ọ́ síwájú mi, Èmi kì yóò dákẹ́, ṣùgbọ́n èmi yóò san án padà lẹ́kùnrẹ́rẹ́; Èmi yóò san án padà sí àyà wọn
7 Nieprawości wasze, także i nieprawości ojców waszych, mówi Pan, którzy kadzili po górach, a na pagórkach hańbili mię; przetoż odmierzę sprawę ich pierwszą na łono ich.
àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,” ni Olúwa wí. “Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńlá wọ́n sì ṣe ẹ̀gbin sí mi ní òkè kékeré, Èmi yóò wọ́n ọ́n sí itan wọn ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”
8 Tak mówi Pan: Jako gdyby kto znalazł wino w gronie, i rzekłby: Nie psuj go, bo błogosławieństwo jest w niem; tak i Ja uczynię dla sług moich, że ich wszystkich nie wygubię.
Báyìí ni Olúwa wí: “Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí oje sì tún wà nínú àpólà àjàrà tí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘Má ṣe bà á jẹ́, nítorí ìbùkún ń bẹ nínú rẹ̀,’ bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi; Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.
9 Bo wywiodę z Jakóba nasienie, a z Judy dzierżawcę gór moich; i posiędą ją wybrani moi, a słudzy moi tam mieszkać będą.
Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jakọbu, àti láti Juda àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n-ọn-nì; àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn, ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.
10 A Saron będzie za pastwisko owcom, a dolina Achor za legowisko wołów ludu mojego, którzy mię szukali.
Ṣaroni yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran, àti àfonífojì Akori yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran, fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.
11 Ale was, którzyście opuścili Pana, którzy zapominacie na górę świętobliwości mojej, którzy gotujecie temu wojsku stół, a którzy oddawacie temu pocztowi mokre ofiary:
“Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé òkè ńlá mímọ́ mi, tí ó tẹ́ tábìlì fún Gadi tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,
12 Was, mówię policzę pod miecz, tak, że wy wszyscy do zabicia schylać się będziecie, przeto, żem wołał, a nie ozwaliście mi się, mówiłem, a nie słyszeliście, aleście czynili, co złego jest przed oczyma mojemi, a czegom Ja nie chciał, obieraliście.
Èmi yóò yà ọ́ sọ́tọ̀ fún idà, àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa; nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn. Mo sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tí sílẹ̀. Ẹ̀yin ṣe búburú ní ojú mi ẹ sì yan ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́.”
13 Przetoż tak mówi panujący Pan: Oto słudzy moi jeść będą, a wy łaknąć będziecie; oto słudzy moi pić będą, a wy pragnąć będziecie; oto słudzy moi weselić się będą, a wy zawstydzeni będziecie.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun; ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin, àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu, ṣùgbọ́n òǹgbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin; àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀, ṣùgbọ́n a ó dójútì yin.
14 Oto słudzy moi wykrzykać będą od radości serdecznej, a wy będziecie wołać od boleści serca, i od skruszenia ducha wyć będziecie.
Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrin láti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókè láti inú ìrora ọkàn yín àti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.
15 I zostawicie imię wasze na przeklinanie wybranym moim, gdy was pomorduje panujący Pan, a sługi swe nazwie innem imieniem.
Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀ fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún; Olúwa Olódùmarè yóò sì pa yín, ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òun yóò fún ní orúkọ mìíràn.
16 Ten, który sobie będzie błogosławił na ziemi, będzie sobie błogosławił w Bogu prawdziwym; a kto będzie przysięgał na ziemi, będzie przysięgał przez Boga prawdziwego; w zapomnienie zaiste przyjdą te uciski pierwsze, a będą zakryte od oczów moich.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náà yóò ṣe é nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́; Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náà yóò búra nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́. Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbé yóò sì fi ara sin kúrò lójú mi.
17 Albowiem oto Ja tworzę niebiosa nowe, i ziemię nową, a nie będą wspominane rzeczy pierwsze, ani wstąpią na serce.
“Kíyèsi i, Èmi yóò dá àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun. A kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́, tàbí kí wọn wá sí ọkàn.
18 Owszem weselcie się, a radujcie się na wieki wieków z tego, co Ja stworzę; bo oto Ja stworzę Jeruzalem na radość, a lud jego na wesele.
Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láé nínú ohun tí èmi yóò dá, nítorí èmi yóò dá Jerusalẹmu láti jẹ́ ohun ìdùnnú àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.
19 I rozraduję się w Jeruzalemie, a weselić się będę w ludu moim; a nie będzie słychać w nim głosu płaczu i głosu narzekania.
Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jerusalẹmu n ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi; ariwo ẹkún àti igbe ni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́.
20 Nie będzie tam więcej nikogo w wieku dziecinnym, ani starca, któryby nie dopełnił dni swoich; bo dziecię we stu latach umrze; ale grzesznik, choćby miał i sto lat, przeklęty będzie.
“Títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀, tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán; ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún ni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé; ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kan ni a ó pè ní ẹni ìfibú.
21 Pobudują też domy, a będą w nich mieszkali; nasadzą też winnic, a będą jeść owoce ich.
Wọn yó ò kọ́ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọn wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èso wọn.
22 Nie będą budować tak, aby tam inszy mieszkał; nie będą szczepić, aby inny jadł; bo dni ludu mojego będą jako dni drzewa, a dzieła rąk swoich do zwietszenia używać będą wybrani moi.
Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmíràn láti gbé, tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmíràn láti jẹ. Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan, bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí; àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́ wọn fún ìgbà pípẹ́.
23 Nie będą robić próżno, ani płodzić będą na postrach; bo będą nasieniem błogosławionych od Pana, oni i potomkowie ich z nimi.
Wọn kì yóò ṣe iṣẹ́ lásán, wọn kí yóò bímọ fún wàhálà; nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún, àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.
24 Nadto stanie się, że pierwej niż zawołają, Ja się ozwę; jeszcze mówić będą, a Ja wysłucham.
Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn; nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.
25 Wilk z barankiem paść się będą społem; lew jako wół plewy jeść będzie, a wężowi proch będzie chlebem jego; nie będą szkodzić ani zatracać na wszystkiej górze świętej mojej, mówi Pan.
Ìkookò àti ọ̀dọ́-àgùntàn yóò jẹun pọ̀, kìnnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù, ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò. Wọn kì yóò pa ni lára tàbí pa ni run ní gbogbo òkè mímọ́ mi,” ni Olúwa wí.

< Izajasza 65 >