< Izajasza 60 >

1 Powstań, objaśnij się! ponieważ przyszła światłość twoja, a chwała Pańska weszła nad tobą.
“Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé, ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.
2 Bo oto ciemności okryją ziemię, a zaćmienie narody; ale nad tobą wejdzie Pan, a chwała jego nad tobą widziana będzie.
Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́ ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.
3 I będą chodzić narody w światłości twojej, a królowie w jasności, która wejdzie nad tobą.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ, àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.
4 Podnieś w około oczy twe, a spojrzyj; ci wszyscy, którzy się zgromadzili, pójdą do ciebie; synowie twoi z daleka przyjdą, a córki twoje przy boku twoim chowane będą.
“Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò. Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ; àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.
5 Tedy oglądasz to, a rozweselisz się; tedy się zdumieje i rozszerzy serce twoje, gdy się obróci ku tobie zgraja morska, a moc narodów przyjdzie do ciebie.
Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán, ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀; ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ, sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.
6 Obfitość wielbłądów okryje cię, także dromedarze z Madyjan i z Efy. Wszyscy ci przyjdą z Saby, złoto i kadzidło przyniosą, a chwały Pańskie opowiadać będą.
Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani. Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá, wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́ tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.
7 Wszystkie stada z Kedar zgromadzą się do ciebie; barany z Nebajotu służyć ci będą, a ofiarowane będąc na ołtarzu moim, przyjemne będą; a tak dom majestatu mego ozdobię.
Gbogbo agbo ẹran ìlú Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ, àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́; wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi, bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.
8 I rzeczesz: Którzyż to są, co się jako obłoki zlatują, i jako gołębie do okien swoich?
“Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru, gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?
9 Na mięć zaiste wyspy oczekują, i okręty morskie zdawna, aby przywiedli synów twoich z daleka, także srebro swoje z sobą, i złoto swoje imieniowi Pana, Boga twego, i Świętego Izraelskiego; bo cię uwielbi.
Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí; ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn, pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn, fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli, nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.
10 I pobudują cudzoziemcy mury twoje, a królowie ich służyć ci będą, gdyż w rozgniewaniu mojem uderzę cię, a w upodobaniu mojem zlituję się nad tobą.
“Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́, ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.
11 I będą otworzone bramy twoje ustawicznie; we dnie i w nocy nie będą zatkane, aby przywiedziono do ciebie moc pogan, i królowie ich aby byli przywiedzieni.
Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀, a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru, tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.
12 Naród ten i królestwo, którećby nie służyło, zginie; narody takie, mówię, do szczętu spustoszone będą.
Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun; pátápátá ni yóò sì dahoro.
13 Sława Libanu do ciebie przyjdzie, jedlina, sosna, także bukszpan, dla ozdoby miejsca świątnicy mojej, abym miejsce nóg moich uwielbił.
“Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀, láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi; àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.
14 Przyjdą także do ciebie w pokorze synowie tych, którzy cię trapili, i będą się kłaniać stopom nóg twoich, którzykolwiek pogardzili tobą, i nazwią cię miastem Pańskiem, Syonem Świętego Izraelskiego.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò wá foríbalẹ̀ fún ọ; gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa, Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.
15 Miasto tego, coś opuszczona i w nienawiści była, tak, że nie było, ktoby przez cię chodził, wystawię cię za dostojność wieczną, i wesele od narodu do narodu.
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá, Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé àti ayọ̀ àtìrandíran.
16 Bo ssać będziesz mleko narodów, i piersiami królów karmiona będziesz; i poznasz, iżem Ja Pan, zbawieciel twój i odkupiciel twój, mocarz Jakóbowy;
Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.
17 Miasto miedzi naniosę złota, a miasto żelaza naniosę srebra, a miasto drew miedzi, a miasto kamienia żelaza; i postawię nad tobą dozorców spokojnych, i urzędników sprawiedliwych.
Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ, dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ, àti irin dípò òkúta. Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.
18 Nie będzie więcej słychać o drapiestwie w ziemi twojej, o zburzeniu i spustoszeniu na granicach twoich; ale ogłaszać będziesz zbawienie na murach twoich, a chwałę w bramach twoich.
A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́, tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.
19 Nie będziesz miał więcej słońca za światłość dzienną, a jasność miesiąca nie oświeci cię, ale Pan będzie światłością twoją wieczną, a Bóg twój sławą twoją.
Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́, tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́, nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé, àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.
20 Nie zajdzie więcej słońce twoje, a miesiąc twój nie skryje się; bo Pan będzie wieczną światłością twoją; a tak dokonają się dni smutku twego.
Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́, àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́; Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ, àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.
21 Lud także twój, którzybykolwiek byli sprawiedliwi, na wieki odziedziczą ziemię; będą latoroślą szczepienia mego, dziełem rąk moich, abym w niem był uwielbiony.
Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé. Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn, iṣẹ́ ọwọ́ mi, láti fi ọláńlá mi hàn.
22 Najmniejszy rozmnoży się na tysiące, a maluczki poczet w naród niezliczony. Ja Pan czasu swego prędko to uczynię.
Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan, èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá. Èmi ni Olúwa; ní àkókò rẹ̀, Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”

< Izajasza 60 >