< Izajasza 55 >

1 Nuż wszyscy pragnący pójdźcie do wód, i wy, co niemacie pieniędzy, pójdźcie, kupujcie a jedzcie; pójdźcie, mówię, kupujcie bez pieniędzy i bez zapłaty, wino i mleko.
“Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òǹgbẹ ń gbẹ, ẹ wá sí ibi omi; àti ẹ̀yin tí kò ní owó; ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ! Ẹ wá ra wáìnì àti wàrà láìsí owó àti láìdíyelé.
2 Przecz wynakładacie pieniądze nie za chleb, a pracę swą na to, co nie nasyca? Słuchając słuchajcie mię, a jedzcie to, co jest dobrego, i niech się rozkocha w tłustości dusza wasza.
Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrà àti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn? Tẹ́tí sílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.
3 Nakłońcie ucha swego, a pójdźcie do mnie; słuchajcie, a będzie żyła dusza wasza. I postanowię z wami przymierze wieczne, miłosierdzie Dawidowe pewne wyleję na was.
Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ mi; gbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láààyè. Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú rẹ, ìfẹ́ òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dafidi.
4 Oto dałem go za świadka narodom, za wodza i za nauczyciela narodom.
Kíyèsi i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn, olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.
5 Oto naród, któregoś nie znał, powołasz, a narody, które cię nie znały, zbieżą się do ciebie dla Pana, Boga twego, i Świętego Izraelskiego; bo cię uwielbi.
Lóòtítọ́ ìwọ yóò ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ ni yóò sáré tọ̀ ọ́ wá, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ Ẹni Mímọ́ Israẹli nítorí pé ó ti fi ohun dídára dá ọ lọ́lá.”
6 Szukajcie Pana, póki może być znaleziony; wzywajcie go, póki blisko jest.
Ẹ wá Olúwa nígbà tí ẹ lè rí i; ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
7 Niech opuści niepobożny drogę swoję, a człowiek nieprawy myśli swoje i niech się nawróci do Pana, a zmiłuje się; i do Boga naszego, gdyż jest hojnym w odpuszczaniu.
Jẹ́ kí ìkà kí ó kọ ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀ àti ènìyàn búburú èrò rẹ̀. Jẹ́ kí ó yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì ṣàánú fún un, àti sí Ọlọ́run wa, nítorí Òun yóò sì dáríjì.
8 Boć zaiste myśli moje nie są jako myśli wasze, ani drogi wasze jako drogi moje, mówi Pan;
“Nítorí èrò mi kì í ṣe èrò yín, tàbí ọ̀nà yín a ha máa ṣe ọ̀nà mi,” ni Olúwa wí.
9 Ale jako wyższe są niebiosa niż ziemia, tak przewyższają drogi moje drogi wasze, a myśli moje myśli wasze.
“Gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti ga ju ayé lọ, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín lọ àti èrò mi ju èrò yín lọ.
10 Bo jako zstępuje deszcz i śnieg z nieba, a tam się więcej nie wraca, ale napawa ziemię, a czyni ją płodną, czyni ją też urodzajną, tak że wydaje nasienie siejącemu, a chleb jedzącemu:
Gẹ́gẹ́ bí òjò àti yìnyín ti wálẹ̀ láti ọ̀run tí kì í sì padà sí ibẹ̀ láì bomirin ilẹ̀ kí ó sì mú kí ó tanná kí ó sì rudi, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi mú irúgbìn fún afúnrúgbìn àti àkàrà fún ọ̀jẹun,
11 Takci będzie słowo moje, które wynijdzie z ust moich; nie wróci się do mnie próżno, ale uczyni to, co mi się podoba, i poszczęści mu się w tem, na co je poślę.
bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ mi tí ó jáde láti ẹnu mi wá; kì yóò padà sọ́dọ̀ mi lọ́wọ́ òfo, ṣùgbọ́n yóò ṣe ohun tí mo fẹ́, yóò sì mú ète mi tí mo fi rán an wá sí ìmúṣẹ.
12 Przetoż w weselu wynijdziecie, a w pokoju doprowadzeni będziecie. Góry i pagórki chwałę przed wami głośno zaśpiewają, a wszystkie drzewa polne rękami klaskać będą.
Ẹ̀yin yóò jáde lọ ní ayọ̀ a ó sì darí i yín lọ ní àlàáfíà; òkè ńlá ńlá àti kéékèèké yóò bú sí orin níwájú yín àti gbogbo igi inú pápá yóò máa pàtẹ́wọ́.
13 Miasto ciernia wyrośnie jedlina, a miasto pokrzywy wyrośnie mirt; a to będzie Panu ku sławie, na znak wieczny, który nigdy nie będzie wygładzony.
Dípò igi ẹ̀gún ni igi junifa yóò máa dàgbà, àti dípò ẹ̀wọ̀n, maritili ni yóò yọ. Èyí yóò wà fún òkìkí Olúwa, fún àmì ayérayé, tí a kì yóò lè parun.”

< Izajasza 55 >