< Izajasza 5 >

1 Zaśpiewam teraz miłemu memu piosnkę miłego mego o winnicy jego. Winnicę ma miły mój na pagórku urodzajnym;
Èmi yóò kọrin fún ẹni tí mo fẹ́ràn orin kan nípa ọgbà àjàrà rẹ̀. Olùfẹ́ mi ní ọgbà àjàrà kan ní ẹ̀gbẹ́ òkè ẹlẹ́tù lójú.
2 Którą ogrodził, i wybrał z niej kamienie, a nasadził ją macicami wybornemi, i zbudował wieże w pośrodku niej, także i prasę postawił w niej, a czekał, aby wydała grona; ale ona zrodziła płonne wino.
Ó tu ilẹ̀ rẹ̀, ó ṣa òkúta ibẹ̀ kúrò ó sì gbin àyànfẹ́ àjàrà sí i. Ó kọ́ ilé ìṣọ́ sí inú rẹ̀ ó sì ṣe ìfúntí kan síbẹ̀ pẹ̀lú. Lẹ́yìn náà, ó ń retí èso àjàrà dáradára, ṣùgbọ́n èso búburú ni ó ti ibẹ̀ wá.
3 A tak, obywatele Jeruzalemscy i mężowie Judzcy! proszę, rozsądźcie teraz między mną i między winnicą moją.
“Ní ìsinsin yìí ẹ̀yin olùgbé Jerusalẹmu àti ẹ̀yin ènìyàn Juda ẹ ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ọgbà àjàrà mi.
4 Cóż dalej czynić było winnicy mojej, czegobym jej nie uczynił? Gdym rzekał, aby wydała grona, czemuż zrodziła płonne wino?
Kín ni ó kù tí n ò bá túnṣe sí ọgbà àjàrà mi. Ju èyí tí mo ti ṣe lọ? Nígbà tí mo ń wá èso dáradára, èéṣe tí ó fi so kíkan?
5 A przetoż oznajmię wam, co ja uczynię winnicy mojej: Rozbiorę płot jej, a będzie spustoszona; rozwalę ogrodzenie jej, a będzie podeptana.
Ní ìsinsin yìí, èmi yóò wí fún ọ ohun tí n ó ṣe sí ọgbà àjàrà mi. Èmi yóò gé igi inú rẹ̀ kúrò, a ó sì pa á run, Èmi yóò wó ògiri rẹ̀ lulẹ̀ yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
6 I uczynię ją pustą; nie będzie obrzezywana, ani okopywana, ale porośnie ostem i cierniem; obłokom też przykażę, aby na nią więcej dżdżu nie spuszczały.
Èmi yóò sì sọ ọ́ di ahoro láì kọ ọ́ láì ro ó, ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún ni yóò hù níbẹ̀. Èmi yóò sì pàṣẹ fún kurukuru láti má ṣe rọ̀jò sórí i rẹ̀.”
7 Winnica zaiste Pana zastępów jest dom Izraelski, a mąż Judzki szczepieniem jego rozkosznem. Oczekiwał sądu, a oto uciśnienie; oczekiwał sprawiedliwości, a oto krzyk.
Ọgbà àjàrà Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ilé Israẹli àwọn ọkùnrin Juda sì ni àyànfẹ́ ọgbà rẹ̀. Ó retí ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ṣùgbọ́n, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni ó rí. Òun ń retí òdodo ṣùgbọ́n ó gbọ́ ẹkún ìpayínkeke.
8 Biada wam, którzy przyłączacie dom do domu, a rolę do roli przyczyniacie, tak, że miejsca innym nie staje, jakobyście tylko sami mieszkać mieli na ziemi!
Ègbé ni fún àwọn tí ń kọ́lé mọ́lé tí ó sì ń ra ilẹ̀ mọ́lẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ààyè kò ṣẹ́kù tí ó sì nìkan gbé lórí ilẹ̀.
9 Pan zastępów rzekł w uszy moje: Zaiste wiele domów spustoszeje, a wielkie i piękne domy będą bez obywatela.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ ọ́ sí mi létí: “Ó dájú pé àwọn ilé ńlá ńlá yóò di ahoro, àwọn ilé dáradára yóò wà láìní olùgbé.
10 Do tego dziesięć stajan winnicy przyniosą jednę baryłę wina, a jeden chomer nasienia wyda efa.
Ọgbà àjàrà sáré oko mẹ́wàá yóò mú ìkòkò wáìnì kan wá, nígbà tí òsùwọ̀n homeri kan yóò mú agbọ̀n irúgbìn kan wá.”
11 Biada tym, którzy rano wstawając chodzą za pijaństwem, a trwają na niem do wieczora, aż ich wino rozpali!
Ègbé ni fún àwọn tí wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti lépa ọtí líle, tí wọ́n sì mu ún títí alẹ́ fi lẹ́ títí wọ́n fi gbinájẹ pẹ̀lú wáìnì.
12 A cytra, i lutnia, bęben i piszczałka, i wino bywa na biesiadach ich; ale na sprawy Pańskie nie patrzą, a na uczynki rąk jego nie oglądają się.
Wọ́n ní dùùrù àti ohun èlò orin olókùn níbi àsè wọn, ṣaworo òun fèrè àti wáìnì, ṣùgbọ́n wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí, wọn kò sí bọ̀wọ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
13 Przetoż w niewolę pójdzie lud mój, iż nie ma umiejętności; a zacni jego będą głodnymi, i pospólstwo jego wyschnie od pragnienia.
Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò lọ sí ìgbèkùn nítorí òye kò sí fún wọn, ebi ni yóò pa àwọn ọlọ́lá wọn kú; ẹgbàágbèje wọn ni òǹgbẹ yóò sì gbẹ.
14 Dlatego rozszerzyło piekło gardło swoje, a rozdarło nad miarę paszczękę swoję, i zstąpią do niego szlachta i pospólstwo jego, i zgiełk jego, i ci, którzy się weselą w niem. (Sheol h7585)
Nítorí náà isà òkú ti ń dátọ́mì gidigidi, ó sì ti ya ẹnu rẹ̀ sílẹ̀ gbagada, nínú rẹ̀ ni àwọn gbajúmọ̀ àti mẹ̀kúnnù yóò sọ̀kalẹ̀ sí pẹ̀lú ọlá àti ògo wọn. (Sheol h7585)
15 A tak będzie nachylony człowiek, a zacny mąż poniżony będzie, i oczy wyniosłych zniżone będą.
Báyìí, ènìyàn yóò di ìrẹ̀sílẹ̀ àti ọmọ ènìyàn ni a sọ di onírẹ̀lẹ̀ ojú agbéraga ni a sì rẹ̀ sílẹ̀.
16 Ale Pan zastępów wywyższony będzie w sądzie, a Bóg święty ukaże się świętym w sprawiedliwości.
Ṣùgbọ́n Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni a ó gbéga nípa ẹ̀tọ́ rẹ̀, Ọlọ́run ẹni mímọ́ yóò sì fi ara rẹ̀ hàn ní mímọ́ nípa òdodo rẹ̀.
17 I będą się paść baranki według zwyczaju swego, a przychodniowie pustyń bogaczów pożywać będą.
Nígbà náà ni àwọn àgùntàn yóò máa jẹ́ ko ní ibùgbé e wọn, àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yóò máa jẹ nínú ahoro àwọn ọlọ́rọ̀.
18 Biada tym, którzy ciągną nieprawość powrozami marności, a grzech jako powrozem wozowym!
Ègbé ni fún àwọn tí ń fi ohun asán fa ẹ̀ṣẹ̀, àti àwọn tí o dàbí ẹni pé wọ́n ń fi okùn kẹ̀kẹ́ ẹ̀sìn fa ẹsẹ̀,
19 Którzy mówią: Niech się pospieszy, a niechaj nie omieszkuje sprawa jego, abyśmy ją widzieli; niech się przybliży i przyjdzie rada świętego Izraelskiego, żebyśmy się dowiedzieli.
sí àwọn tí ó sọ pé, “Jẹ́ kí Ọlọ́run ṣe kíákíá, jẹ́ kí ó yára ṣiṣẹ́ rẹ̀ kí a lè rí i, jẹ́ kí ó súnmọ́ bí jẹ́ kí ètò ẹni mímọ́ Israẹli kí ó dé, kí àwa kí ó le mọ̀ ọ́n.”
20 Biada tym, którzy nazywają złe dobrem a dobre złem; którzy pokładają ciemność za świetłość, a światłość za ciemność; którzy pokładają gorzkość za słodkość, a słodkość za gorzkość!
Ègbé ni fún àwọn tí ń pe ibi ní rere, àti rere ní ibi, tí ń fi òkùnkùn ṣe ìmọ́lẹ̀ àti ìmọ́lẹ̀ ṣe òkùnkùn, tí ń fi ìkorò ṣe adùn àti adùn ṣe ìkorò.
21 Biada tym, którzy się sobie zdadzą być mądrymi, a sami u siebie roztropnymi!
Ègbé ni fún àwọn tí ó gbọ́n lójú ara wọn tí wọ́n jáfáfá lójú ara wọn.
22 Biada tym, którzy są mocni na picie wina, a mężom dużym ku nalewaniu napoju mocnego!
Ègbé ni fún àwọn akọni nínú wáìnì mímu àti àwọn akíkanjú nínú àdàlú ọtí,
23 Którzy usprawiedliwiają niezbożnego za podarki, a sprawiedliwość sprawiedliwych odejmują od nich!
tí wọ́n dá ẹlẹ́bi sílẹ̀ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí wọn sì du aláre ní ẹ̀tọ́.
24 Przetoż jako płomień ogniowy pożera parzdzieże, i jako płomień plewy trawi: tak korzeń ich będzie jako zgnilizna, a kwiat ich jako proch ku górze pójdzie; albowiem odrzucili zakon Pana zastępów, a wyrokiem świętego Izraelskiego pogardzili.
Nítorí náà, gẹ́gẹ́ bí ahọ́n iná ṣe ń jó àgékù koríko run àti bí koríko ṣe rẹlẹ̀ wẹ̀sì nínú iná, bẹ́ẹ̀ ni egbò wọn yóò jẹrà tí òdodo wọn yóò sì fẹ́ lọ bí eruku: nítorí pé wọ́n ti kọ òfin Olúwa àwọn ọmọ-ogun sílẹ̀ wọ́n sì gan ọ̀rọ̀ Ẹni mímọ́ Israẹli.
25 Dlatego się zapaliła popędliwość Pańska przeciw ludowi swemu, a wyciągnąwszy nań rękę swą poraził go, tak że się zatrząsnęły góry, i były trupy ich jako gnój po ulicach. W tem jednak wszystkiem nie odwróciła się zapalczywość jego, ale jeszcze ręk a jego jest wyciągniona.
Nítorí náà, ìbínú Olúwa gbóná si àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó sì lù wọ́n bolẹ̀. Àwọn òkè sì wárìrì, òkú wọn sì dàbí ààtàn ní àárín ìgboro. Pẹ̀lú gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò, ṣùgbọ́n ọ̀wọ́ rẹ̀ sì ná jáde síbẹ̀.
26 Bo podniesie chorągiew do narodu dalekiego, a zaświśnie nań od kończyn ziemi, a oto rychło i prędko przyjdzie.
Yóò sì gbé ọ̀págun sókè sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó jìnnà, yóò sì kọ sí wọn tí ó wà ní ìpẹ̀kun ilẹ̀. Sì kíyèsi, wọ́n yóò yára wá kánkán.
27 Żadnego spracowanego i upadającego nie będzie między nimi; nie będzie drzemiącego ani śpiącego, ani się rozepnie pas na biodrach jego, ani się rozerwie rzemyk u trzewików jego.
Kò sí ẹni tí yóò rẹ̀ nínú wọn, tàbí tí yóò kọsẹ̀, kò sí ẹni tí yóò tòògbé tàbí tí yóò sùn; bẹ́ẹ̀ ni àmùrè ẹ̀gbẹ́ wọn kì yóò tú, bẹ́ẹ̀ ni okùn sálúbàtà wọn kì yóò ja.
28 Strzały jego ostre, i wszystkie łuki jego naciągnione; kopyta koni jego jako krzemień poczytane będą, a koła jego jako burza.
Àwọn ọfà wọn múná, gbogbo ọrun wọn sì le; pátákò àwọn ẹṣin wọn le bí òkúta akọ, àwọn àgbá kẹ̀kẹ́ wọn sì dàbí ìjì líle.
29 Ryk jego jako lwi; będzie ryczał jako szczenięta lwie; będzie zgrzytał, i porwie łup, i uciecze z nim, a nie będzie ktoby go wydarł.
Bíbú wọn dàbí tí kìnnìún, wọ́n bú bí ẹgbọrọ kìnnìún, wọ́n ń kọ bí wọ́n ti di ẹran ọdẹ wọn mú tí wọn sì gbé e lọ láìsí ẹni tí yóò gbà á là.
30 I zaszumi nad nim dnia onego jako szum morski. Tedy spojrzymy na ziemię, a oto ciemność i ucisk; bo i światło zaćmi się przy wytraceniu jego.
Ní ọjọ́ náà, wọn yóò hó lé e lórí gẹ́gẹ́ bí i rírú omi Òkun. Bí ènìyàn bá sì wo ilẹ̀, yóò rí òkùnkùn àti ìbànújẹ́; pẹ̀lúpẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn pẹ̀lú kurukuru rẹ̀.

< Izajasza 5 >