< Izajasza 46 >
1 Pochylił się Bel, upadł Nebo; bałwany ich włożone są na bestyje, i na bydlęta; tem zaiste, co wy nosicie, będą bardzo obciążone aż do ustania.
Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀; àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù. Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di àjàgà sí wọn lọ́rùn, ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.
2 Pochyliły się, i upadły społem, i Babilończycy nie będą mogli ratować brzemion; owszem, i dusza ich w niewolę pójdzie.
Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀; wọn kò lè gba ẹrù náà, àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.
3 Słuchajcie mię, domie Jakóbowy, i wszystkie ostatki domu Izraelskiego! które noszę zaraz z żywota, które piastuję zaraz od narodzenia;
“Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu, gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli, ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún, tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.
4 Ja sam aż do starości, i owszem aż do sędziwości was nosić będę. Jam was uczynił, Ja też nosić będę; Ja mówię nosić was będę, i wybawię.
Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín, Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró. Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ; Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.
5 Komuż mię przypodobacie, i przyrównacie, albo podobnym uczynicie, żebym mu był podobny?
“Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba? Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?
6 Ci, którzy marnie wydawają złoto z worka, a srebro na szalach ważą, najmują za zapłatę złotnika, aby uczynił z niego boga, przed którym padają i kłaniają się.
Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn wọ́n sì wọn fàdákà lórí òsùwọ̀n; wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà, wọn sì tẹríba láti sìn ín.
7 Noszą go na ramieniu, dźwigają go, i stawiają go na miejscu jego. I stoi, a z miejsca swego się nie ruszy; jeźli kto zawoła do niego, nie ozywa się, ani go z utrapienia jego wybawia.
Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n, wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí. Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà. Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn; òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.
8 Pamiętajcież na to, a wstydźcie się; przypuśćcie to do serca, o przestępnicy!
“Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ, fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.
9 Wspomnijcie sobie na rzeczy pierwsze, które się działy od wieku; bom Ja Bóg, a niemasz żadnego Boga więcej, i niemasz mnie podobnego;
Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́; Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn; Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.
10 Który opowiadam od początku rzeczy ostatnie, i zdawna to, co się jeszcze nie stało; rzekęli co, rada moja ostoi się, i wszystkę wolę moję uczynię.
Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá. Mo wí pé, Ète mi yóò dúró, àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.
11 Który zawołam od wschodu słońca ptaka, z ziemi dalekiej tego, któryby wykonał radę moję. Rzekłem, a dowiodę tego; umyśliłem, a uczynię to.
Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá; láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ. Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ; èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.
12 Słuchajcie mię, wy upornego serca, którzy jesteście dalekimi od sprawiedliwości.
Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn, ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.
13 Sprawię, że się przybliży sprawiedliwość moja, nie pójdzie w długą, a zbawienie moje nie omieszka; bo położę w Syonie zbawienie, a w Izraelu sławę moję.
Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí, kò tilẹ̀ jìnnà rárá; àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró. Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà ògo mi fún Israẹli.