< Izajasza 39 >
1 Onego czasu posłał Merodach Baladan, syn Baladanowy, król Babiloński, list i dary do Ezechyjasza; bo zasłyszał, że zachorowawszy zaś ozdrowiał.
Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli fi ìwé àti ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí Hesekiah, nítorí ó gbọ́ pé ó ṣàìsàn ó sì gbádùn.
2 I weselił się z tego Ezechyjasz, i ukazał im skarbnicę klejnotów swoich srebra i złota, i rzeczy wonnych, i olejki najwyborniejsze, także i dom rynsztunków swoich, i cokolwiek się znajdowało w skarbach jego: nie było nic, czegoby im nie ukazał Ezechyjasz w domu swym, i we wszystkiem państwie swojem.
Hesekiah gba àwọn ikọ̀ yìí tayọ̀tayọ̀, ó sì fi àwọn nǹkan tí ó wà nínú yàrá ìkẹ́rù sí mọ́ hàn wọ́n—fàdákà, wúrà, ohun olóòórùn dídùn, òróró dídára, gbogbo nǹkan ogun rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìṣúra rẹ̀ kò sí ohunkóhun tí ó wà nínú ààfin rẹ̀ tàbí ní ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò fihàn wọ́n.
3 Wtem przyszedł Izajasz prorok do króla Ezechyjasza, i rzekł mu: Coć powiedzieli ci mężowie, i skąd przyszli do ciebie? I odpowiedział Ezechyjasz: Z ziemi dalekiej przyszli do mnie, z Babilonu.
Lẹ́yìn náà wòlíì Isaiah lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah ọba ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí, níbo ni wọ́n sì ti wá?” “Láti ilẹ̀ jíjìnnà,” ni èsì Hesekiah. “Wọ́n wá sọ́dọ̀ mi láti Babeli.”
4 Nadto rzekł: Cóż widzieli w domu twoim? Odpowiedział Ezechyjasz: Wszystko, co jest w domu moim, widzieli; niemasz nic, czegobym im nie ukazał w skarbach moich.
Wòlíì náà sì béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí nínú ààfin rẹ?” Hesekiah si dáhùn pe, “Wọ́n rí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin mi. Kò sí ohun kankan nínú ìṣúra mi tí èmi kò fihàn wọ́n.”
5 Tedy rzekł Izajasz do Ezechyjasza: Słuchaj słowa Pana zastępów:
Lẹ́yìn náà ni Isaiah sọ fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
6 Oto przyjdą te dni, w które zabiorą wszystko do Babilonu, cokolwiek jest w domu twoim, i cokolwiek zachowali ojcowie twoi aż do dnia tego; nie zostanie nic, mówi Pan;
Àsìkò ń bọ̀ nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin rẹ, àti ohun gbogbo tí àwọn baba rẹ ti kójọ títí di ọjọ́ òní yóò di kíkó lọ sí Babeli. Ohun kankan kò ní ṣẹ́kù ni Olúwa wí.
7 Ale i synów twoich, którzy wyjdą z ciebie, których spłodzisz, pobiorą, i będą komornikami na dworze króla Babilińskiego.
Àti díẹ̀ nínú àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ, àwọn ẹ̀jẹ̀ àti ẹran-ara rẹ tí a ó bí fún ọ ni a ó kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà nínú ààfin ọba Babeli.”
8 Tedy rzekł Ezechyjasz do Izajasza: Dobre jest słowo Pańskie, któreś mówił; (i dołożył: Dobre, ) przeto, że pokój i prawda będzie za dni moich.
Hesekiah wí fún Isaiah pé, “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Àlàáfíà àti ààbò yóò wà ní ìgbà ayé tèmi.”