< Izajasza 37 >

1 A gdy to usłyszał król Ezechyjasz, rozdarł szaty swoje, a oblókłszy się w wór, wszedł do domu Pańskiego.
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
2 I posłał Elijakima, sprawcę domu swego, i Sobnę pisarza, i starszych z kapłanów obleczonych w wory, do Izajasza proroka, syna Amosowego.
Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 Którzy rzekli do niego: Tak mówi Ezechyjasz: Dzień ten jest dzień utrapienia, i łajania, i bluźnienia; albowiem synowie przyszli aż do porodzenia, ale siły niemasz ku rodzeniu.
Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
4 Oby usłyszał Pan, Bóg twój, słowa Rabsacesowe, którego posłał król Assyryjski, pan jego, aby urągał Bogu żyjącemu, i pomścił się Pan Bóg twój, tych słów, które słyszał! Przetoż uczyń modlitwę za te ostatki ludu, które się znajdują.
Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
5 Przyszły tedy słudzy króla Ezechyjasza do Izajasza;
Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 Którym odpowiedział Izajasz: Tak powiedzcie Panu waszemu, tak mówi Pan: Nie bój się tych słów, któreś słyszał, któremi mię lżyli słudzy króla Assyryjskiego.
Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Oto ja mu dam innego ducha, aby usłyszawszy wieść nawrócił się do ziemi swojej; i sprawię to, że polegnie od miecza w ziemi swojej.
Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 Ale Rabsaces wróciwszy się znalazł króla Assyryjskiego dobywającego Lebny; albowiem usłyszał, iż odciągnął był od Lachys.
Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
9 A usłyszawszy o Tyraku, królu Etyjopskim, że mówiono: Oto ciągnie, aby walczył przeciwko tobie; usłyszawszy to, mówię, przecie posłał posłów do Ezechyjasza z temi słowy:
Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
10 To powiedzcie Ezechyjaszowi, królowi Judzkiemu, mówiąc: Niech cię nie zwodzi Bóg twój, któremu ty ufasz, a mówisz: Nie będzie podane Jeruzalem w ręce króla Assyryjskiego.
“Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
11 Otoś słyszał, co poczynili królowie Assyryjscy wszystkim ziemiom, które wygładzili; a tybyś miał być wybawiony?
Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
12 Izali je wybawili bogowie tych narodów, które wygubili ojcowie moi: Gozan, i Haran, i Resef, i synów Eden, którzy byli w Telassar?
Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 Gdzież jest król Elmat, i król Arfad, i król miasta Sefarwaim, Ana, i Awa?
Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
14 Przetoż wziąwszy Ezechyjasz list z ręki posłów, przeczytał go, a wszedłszy do domu Pańskiego, rozciągnął go Ezechyjasz przed Panem.
Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
15 I modlił się Ezechyjasz Panu, mówiąc:
Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
16 Panie zastępów, Boże Izraelski, siedzący na Cherubinach! Ty, tyś sam jest Bóg wszystkich królestw ziemi, tyś stworzył niebo i ziemię.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
17 Nakłońże, Panie! ucha twego, a usłysz; otwórz, Panie! oczy twoje, a obacz; usłysz wszystkie słowa Sennacherybowe, który przysłał hańbić ciebie, Boga żywego.
Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
18 Prawdać jest, Panie! że sputoszyli królowie Assyryjscy wszystkie te krainy, i ziemię ich;
“Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
19 I powrzucali bogów ich w ogień; albowiem nie byli bogami, ale robotą rąk ludzkich, drewno i kamień; przetoż ich wygubili.
Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
20 A teraz, o Panie, Boże nasz! wybaw nas z ręki jego, aby poznały wszystkie królestwa ziemi, żeś ty, Panie! sam Bogiem.
Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
21 Tedy posłał Izajasz, syn Amosowy, do Ezechyjasza, mówiąc: Tak mówi Pan Bóg Izraelski: O coś mię prosił z strony Sennacheryba, króla Assyryjskiego,
Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
22 Tedy to jest słowo, które mówił Pan o nim: Panna, córka Syońska, wzgardziła cię, śmiała się z ciebie, kiwała głową za tobą córka Jeruzalemska.
èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
23 Kogożeś hańbił, i kogoś bluźnił? przeciwko komużeś podniósł głos, i wyniosłeś ku górze oczy swe? przeciwko Świętemu Izraelskiemu.
Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
24 Przez sługi twoje hańbiłeś Pana, i mówiłeś: W mnóstwie wozów moich wstąpiłem ja na wysokie góry, na strony Libańskie, i porąbię wysokie cedry jego, i wyborne jodły jego; i wnijdę na samę wysokość wierzchu jego, do lasów, i urodzajnych ról jego.
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
25 Jam wykopał źródła i piłem wody, a wysuszyłem stopami nóg moich wszystkie potoki miejsc oblężonych.
Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
26 Izażeś nie słyszał, żem to z dawna uczynił, i ode dni starodawnych to sprawił? A teraz do tego przywodzę, aby w pustynie i w kupy rumu miasta obronne obrócone były.
“Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
27 A obywatele ich ręce skurczone mając, przestraszeni są i zawstydzeni, stali się jako trawa polna, i jako ziele wschodzące, i trawy na dachach, a siewy rdzą zepsowane, pierwej niżeliby dorosły.
Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
28 Mieszkanie twoje, i wyjście twoje, i wejście twoje znam, i popędliwość twoję przeciwko sobie.
“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
29 Ponieważeś się przeciwko mnie zajuszył, a zapędy twoje przyszły do uszów moich, przetoż założę kolce moje za nozdrza twoje, a wędzidło moje wprawię w gębę twoję, i wrócę cię tą drogą, którąś przyszedł.
Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
30 A to miej za znak, Ezechyjaszu! Tego roku jeść będziesz samorodne zboże, także i drugiego roku samorodne zboże; ale roku trzeciego będziecie siać i żąć, i winnice sadzić, i pożywać owoce ich.
“Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
31 Ostatek bowiem domu Judy, który pozostał, wkorzeni się głęboko, i wyda owoc ku górze.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
32 Albowiem z Jeruzalemu wyjdą ostatki, i zachowani z góry Syońskiej. Gorliwość Pana zastępów to uczyni.
Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
33 Przetoż tak mówi Pan o królu Assyryjskim: Nie wnijdzie do miasta tego, ani tam strzały wystrzeli, ani go zaprzątnie tarcza, ani usypie około niego szańców.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
34 Drogą, którą przyszedł, zaś się wróci, a do miasta tego nie wnijdzie, mówi Pan.
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
35 Bo będę bronił miasta tego, i zachowam je sam dla siebie, i dla Dawida, sługi mego.
“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
36 Tedy wyszedł Anioł Pański, i pobił w obozie Assyryjskim sto ośmdziesiąt, i pięć tysięcy; a gdy wstali bardzo rano, oto wszędy pełno trupów.
Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
37 Przetoż ruszywszy się, odjechał, i wrócił się Sennacheryb, król Assyryjski, a mieszkał w Niniwie.
Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
38 A gdy chwalił Nesrocha, boga swego, w domu, tedy Adramelach i Sarasar, synowie jego, zabili go mieczem, a sami uciekli do ziemi Ararat; a królował Assarhaddon, syn jego, miasto niego.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< Izajasza 37 >