< Izajasza 30 >
1 Biada synom odpornym, mówi Pan, którzy czynią radę, ale nie ze mnie, i nakrywają ją nakryciem, ale nie z ducha mojego, aby przyczyniali grzechu do grzechu.
“Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
2 Którzy chodzą a zstępują do Egiptu, nie radząc się ust moich, aby się zmocnili mocą Faraonową, i ukryli się w cieniu Egipskim.
tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
3 Bo moc Faraonowa będzie wam ku zawstydzeniu, a ucieczka do cieniu Egipskiego ku pohańbieniu.
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
4 Przeto, że byli w Soan książęta jego, a posłowie jego do Chanes chodzili.
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
5 Wszystkich do hańby przywiedzie przez lud, który im nie będzie ku dogodzie, ani ku pomocy, ani ku pożytkowi, ale tylko ku zelżywości i ku hańbie.
gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
6 Brzemię odniosą na bydlętach południowych do ziemi ucisku i utrapienia, (skąd pochodzi lew i szcznię lwie, żmija i smok ognisty latający; ) odniosą mówię na grzbietach bydlątek bogactwa swoje, i na garbie wielbłądów skarby swoje, do ludu, który im nic nie pomoże;
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
7 Bo Egipczanie daremno i próżno pomagać będą. Dlatego to ogłaszam, że ich moc jest, siedzieć w pokoju.
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
8 Terazże idź, napisz to na tablicy przed oczyma ich, a na księgach to wyrysuj, aby to trwało do dnia ostatniego, i aż na wieki wieków:
Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
9 Że ten lud jest odporny, synowie kłamliwi, synowie, którzy nie chcą słuchać zakonu Pańskiego.
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
10 Którzy mówią widzącym: Nie miewajcie widzenia; a prorokom: Nie prorokujcie nam, co prawego jest; mówcie nam rzeczy przyjemne, prorokujcie oszukanie;
Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 Ustąpcie z drogi, zejdźcie z ścieszki; niech będzie daleki od oblicza naszego Święty Izraelski.
Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
12 Przetoż tak mówi Święty Izraelski: Iż gardzicie tem słowem, a ufacie w potwarzy i w przewrotności, i spolegacie na niej:
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 Dlatego wam ta nieprawość będzie jako mur przerwany upadający, i jako wydęcie na murze wysokim, którego bywa nagłe i prędkie obalenie;
ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 I pokruszy ją, jako się kruszy stłuczone naczynie garncarskie; a tak mu nie sfolguje, iż się nie znajdzie po stłuczeniu jego i skorupa, którąby mógł nabrać ognia z ogniska, albo naczerpać wody z kałuży.
Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” ()
15 Albowiem tak mówi panujący Pan, Święty, Izraelski: Jeźli się nawrócicie i uspokoicie się, zachowani będziecie; w milczeniu i w nadziei będzie moc wasza. Ale nie chcecie;
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 Owszem mówicie: Nie tak, ale na koniach ucieczemy; przetoż uciekać będziecie. Na prędkich koniach ujedziemy; ale prędsi będą ci, którzy was gonić będą.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 Tysiąc ich uciecze przed okrzyknieniem jednego, a przed okrzyknieniem pięciu wszyscy ucieczecie, aż zostaniecie jako maszt na wierzchu góry, a jako chorągiew na pagórku.
Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
18 A dlategoć Pan czekać będzie, aby się zmiłował nad wami, i dlatego się wywyższy, aby się zlitował nad wami; albowiem Pan jest Bogie sądu; błogosławieni wszyscy, którzy nań oczekują.
Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
19 Bo lud na Syonie i w Jeruzalemie będzie mieszkać; płakać więcej nie będziesz. Zapewne zlituje się nad tobą na głos wołania twego (Pan), a skoro usłyszy, ozwieć się.
Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
20 A choć wam Pan da chleb utrapienia, i wodę ucisku, jednak nie odlecą więcej od ciebie nauczyciele twoi, ale oczy twoje patrzać będą na nauczycieli twoich;
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
21 I uszy twoje usłyszą słowo z tyłu do ciebie mówiącego: Tać jest droga, chodźcie po niej, lubbyście się w prawo albo w lewo udali.
Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
22 Tedy zarzucicie okrycie srebrnych swoich bałwanów rytych, i odzienie złotych swoich bałwanów odlewanych; rozproszysz je jako plugastwo niewiasty przyrodzoną niemoc cierpiącej, a rzeczesz im: Precz stąd.
Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
23 Da Bóg i deszcz na siewy twoje, któremibyś posiał ziemię, a chleb z urodzaju ziemi będzie syty i obfity; dnia onego paść się będą i bydła twoje na pastwisku szerokiem.
Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
24 Woły także i osły sprawujące ziemię, pastwę czystą jeść będą, która opałką i łopatą wywiana bywa.
Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
25 I będą na każdej górze wysokiej, i na każdym pagórku wyniosłym strumienie i potoki wód w dzień porażki wielkiej, gdy wieże upadną.
Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
26 Światłość też miesiąca będzie jako światłość słoneczna; a światłość słoneczna będzie w siedmiornasób, jako światłość siedmiu dni, dnia, którego zawiąże Pan złamanie ludu swego, a ranę zbicia jego uleczy.
Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
27 Oto imię Pańskie przychodzi z daleka, zapaliła się popędliwość jego, i ciężka jest ku znoszeniu; wargi jego pełne są gniewu, a język jego jako ogień pożerający.
Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 A duch jego jest jako rzeka wylewająca, która aż do gardła sięga, aby przewiewał narody, ażby się wniwecz obróciły, a wędzidłem kiełznał czeluści narodów.
Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 Tedy zaśpiewacie, jako gdy się w nocy obchodzi uroczyste święto, a rozweselicie się w sercu jako ten, który idzie z piszczałką, idąc na górę Pańską, do skały Izraelskiej;
Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
30 Gdy da usłyszeć Pan wielmożność głosu swego, i wyciągnione ramię swoje okaże w popędliwości gniewu swojego, i w płomieniu ognia pożerającego z rozproszeniem, z gwałtownym dżdżem, i z gradem kamiennym.
Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 Bo od głosu Pańskiego starty będzie Assyryjczyk, który innym kijem bijał.
Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 I stanie się, że na samym każde uderzenie kijowe, którem go Pan uderzy, znaczne będzie, gdy z bębnami i z lutniami, i z bitwą wesołą walczyć będzie przeciwko niemu.
Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 Albowiem dawno już jest nagotowane piekło, i dla samego króla nagotowane jest; które głębokie i szerokie uczynił, podniaty jego ognia i drew siła jest; poddymanie Pańskie jako rzeka siarczana zapala je. ()
A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.