< Izajasza 14 >
1 Albowiem zlituje się Pan nad Jakóbem, a obierze zasię Izraela, i da im odpocznąć w ziemi ich; a przyłączy się do nich cudzoziemiec, i przystaną do domu Jakóbowego.
Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
2 Bo wezmą z sobą narody, i przywiodą je do miejsca swego; i weźmie je sobie dom Izraelski w ziemi Pańskiej w dziedzictwo za sługi i za służebnice; i imać będą tych, którzy ich imali, a panować będą nad tymi, którzy ich ciemiężyli.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
3 A dnia onego, któregoć Pan da odpocznienie od pracy twojej i od strachu twego, i od niewoli ciężkiej, w którąś był podbity,
Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
4 Weźmiesz tę przypowieść przeciw królowi Babilońskiemu, i rzeczesz: O jako ustał poborca, ustał podatek złota!
ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
5 Pan złamał kij niezbożnych, i rózgę panujących;
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
6 Tego, który ludzi bijał w zapalczywości biciem ustawicznem, panował w gniewie nad narodami bez litości dręczonemi;
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
7 Teraz odpoczywa i jest w pokoju wszystka ziemia, wszyscy głośno śpiewają;
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
8 I jodły się weselą nad tobą, i cedry Libańskie, mówiąc: Od tego czasu, jakoś ty poległ, nie powstał, ktoby nas podcinał.
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
9 I piekło ze spodku wzruszyło się dla ciebie, aby tobie przychodzącemu zaszło; wzbudziło dla ciebie umarłych, wszystkich książąt ziemi; rozkazało powstać z stolic swoich i wszystkim królom narodów. (Sheol )
Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol )
10 Ci wszyscy odpowiadając mówią do ciebie: I tyś zemdlony jako i my, a stałeś się nam podobnym.
Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Strącona jest do piekła, pycha twoja i dźwięk muzyki twojej; podesłanoć mole, a robaki cię przykrywają. (Sheol )
Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol )
12 Jakoż to, żeś spadł z nieba, o jutrzenko! która wschodzisz rano? powalonyś aż na ziemię, któryś wątlił narody!
Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Wszakieś ty mawiał w sercu swem: Wstąpię na niebo, nad gwiazdy Boże wywyższę stolicę moję, a usiądę na górze zgromadzenia, na stronach północnych:
Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 Wstąpię na wysokość obłoków, będę równy Najwyższemu.
Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Wszakże strącon jesteś aż do piekła, w głębokość dołu. (Sheol )
Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol )
16 Którzy cię ujrzą, za tobą się oglądać, i przypatrywać ci się będą mówiąc: Onże to mąż, który trwożył ziemię? który trząsał królestwami?
Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 Który obrócił okrąg świata w pustynię, a miasta jego poburzył, a więźniom swoim nie otwarzał ciemnicy?
Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
18 Wszyscy królowie narodów, cokolwiek ich było, pochowani są w sławie, każdy w domu swoim.
Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Aleś ty odrzucony od grobu swego, jako latorośl obrzydła, jako szata zabitych, których poprzebijano mieczem, którzy zstępują do grobu kamienistego, jako ścierw podeptany.
Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 Nie będzisz miał uczęstnictwa z nimi w pogrzebie; boś ziemię twoję pokaził, i lud swój pomordował; albowiem nasienie złośników nie będzie wspominane na wieki.
a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 Gotujcie synów jego na zamordowanie dla nieprawości ojców ich, aby nie powstali, i nie odziedziczyli ziemi, nie napełnili miastami okręgu ziemskiego.
Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
22 Bo powstanę przeciwko nim, mówi Pan zastępów, a wykorzenię imię Babilonu, i ostatki jego, tak syna jako i wnuka, mówi Pan;
“Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
23 I uczynię je osiadłością bąków, i kałużami wód, i wymiotę go miotłą spustoszenia, mówi Pan zastępów.
Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
24 Przysiągł Pan zastępów, mówiąc: Zaiste, jakom umyślił, tak będzie, a jakom uradził, tak się stanie;
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
25 Iż potrę Assyryjczyka w ziemi mojej, a na górach moich podepczę go; a odejdzie od nich jarzmo jego, i brzemię jego z ramienia jego zdjęte będzie.
Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
26 Tać jest rada uradzona przeciw onej wszystkiej ziemi; a tać jest ręka wyciągniona przeciwko tym wszystkim narodom.
Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
27 A ponieważ Pan zastępów postanowił, któż to wzruszy? a rękę jego wyciągnioną któż odwróci?
Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
28 Roku, którego umarł król Achaz, stało się to proroctwo;
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
29 Nie raduj się, ty wszystka ziemio Filistyńska! iż złamana jest rózga tego, który cię bił; bo z korzenia wężowego wynijdzie bazyliszek, a płód jego będzie smok ognisty latający.
Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
30 I będą się paść pierworodni nędznych, a ubodzy bezpiecznie odpoczną; ale korzeń twój głodem wygubię a ostatki twoje wybiję.
Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
31 Kwilże bramo! krzycz miasto! jużeś się rozpłynęła wszystka ty ziemio Filistyńska; bo od północy ogień przyjdzie, a nie będzie, coby stronił od pocztów jego.
Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
32 A cóż odpowiedzą posłom narodu? To, że Pan ugruntował Syon, a do niego się uciekać będą ubodzy ludu jego.
Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”