< Ozeasza 4 >

1 Słuchajcie słowa Pańskiego, o synowie Izraelscy! bo się Pan rozpiera z obywatelami tej ziemi, gdyż niemasz prawdy, ani żadnego miłosierdzia, ani znajomości Bożej w tej ziemi.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
2 Krzywoprzysięstwem, i kłamstwem, i mężobójstwem, i złodziejstwem, i cudzołóstwem wylewali z brzegów, a mężobójstwo mężobójstwa ścigało.
àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
3 Dlatego ziemia kwilić będzie, a zemdleje wszystko, co na niej mieszka; zwierz polny i ptastwo niebieskie, nawet i ryby morskie zginą.
Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
4 A wszakże niech się nikt z nimi nie spiera, ani ich kto strofuje; bo lud twój jest jako ci, którzy się z kapłanem wadzą.
“Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
5 Przetoż upadniesz we dnie, upadnie też i prorok z tobą w nocy; zagładzę i matkę twoję.
Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
6 Lud mój wygładzony będzie dla nieumiejętności; a ponieważeś ty odrzucił umiejętność, i Ja też ciebie odrzucę, abyś mi kapłańskiego urzędu nie odprawował; a iżeś zapomniał zakonu Boga twego, Ja też zapomnę na synów twoich.
àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
7 Czem się więcej rozmnożyli, tem więcej grzeszyli przeciwko mnie; dlatego sławę ich odmienię w hańbę.
Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
8 Ofiary za grzech ludu mego jedzą: przetoż do nieprawości ich podnoszą duszę swoję.
wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
9 Przetoż stanie się jako ludowie, tak i kapłanowi; bo nawiedzę na nim drogi jego, a uczynki jego oddam mu.
Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
10 I będą jeść, wszakże się nie nasycą, nierząd płodzić będą, ale się nie rozrodzą; bo nie chcą mieć względu na Pana.
“Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
11 Wszeteczństwo, i wino, i moszcz odejmuje serce.
fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
12 Lud mój drewna swego się pyta, a kij jego odpowiada mu; bo ich duch wszeteczeństwa w błąd prowadzi, aby nierząd płodzili, odstępując od Boga swego.
Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
13 Na wierzchach gór ofiarują, a na pagórkach kadzą pod dębiną i pod topoliną, i pod więziną, bo dobry jest cień ich; dlatego wszeteczeństwo płodzą córki wasze, a niewiasty wasze cudzołożą.
Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
14 Nie miałżebym nawiedzić córek waszych, gdy nierząd płodzą? i niewiast waszych, gdy cudzołożą? Albo gdy się i oni sami z nierządnicami odłączają, i z wszetecznicami ofiarują? Owszem, lud, który sobie tego w rozum nie bierze, upadnie.
“Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
15 Jeźli nierząd płodzisz, ty Izraelu! niechże wżdy nie występuje Juda; przetoż nie chodźcie do Galgal, ani wstępujcie do Bet Awen, ani przysięgajcie mówiąc: Jako żyje Pan!
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
16 Bo Izrael jest nieokrócony jako jałowica nieokrócona: zaprawdę Pan ich paść będzie, jako baranki na przestrzeństwie.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
17 Stowarzyszył się Efraim z bałwanami; zaniechaj go.
Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
18 Odpornymi ich czyni napój ich, nierząd ustawicznie płodzą; obrońcy jego z hańbą miłują dary.
Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
19 Zachwyci ich wiatr skrzydłami swemi, i będą zawstydzeni dla ofiar swoich.
Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.

< Ozeasza 4 >