< Ozeasza 14 >

1 O Izraelu! nawróć się cale do Pana, Boga swego; albowiemeś upadł dla nieprawości swojej.
Yípadà ìwọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ló fa ìparun rẹ!
2 Weźmijcie z sobą słowa, i nawróćcie się do Pana, mówcie do niego: Odpuść wszystkę nieprawość, a daj to, co jest dobrego, tedyż oddamy cielce warg naszych.
Ẹ gba ọ̀rọ̀ Olúwa gbọ́, kí ẹ sì yípadà sí Olúwa. Ẹ sọ fún un pé, “Darí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá kí o sì fi oore-ọ̀fẹ́ gbà wá, kí àwa kí ó lè fi ètè wa sán an fún ọ
3 Assur nie wzybawi nas, na koniach jeździć nie będziemy, i nie rzeczemy więcej robocie rąk naszych: Wyście bogowie nasi; bo w tobie sierotka znajduje miłosierdzie.
Asiria kò le gbà wá là; a kò ní í gorí ẹṣin ogun. A kò sì ní tún sọ ọ́ mọ́ láé, ‘Àwọn ni òrìṣà wa’ sí àwọn ohun tí ó fi ọwọ́ wa ṣe; nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni àwọn aláìní baba tí ń rí àánú.”
4 Uzdrowię odwrócenie ich, a rozmiłuję się w nich dobrowolnie; bo się odwróci zapalczywość moja od nich.
“Èmi wo àgàbàgebè wọn sàn, Èmi ó sì fẹ́ràn wọn, lọ́fẹ̀ẹ́, nítorí ìbínú mi ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
5 Będę Izraelowi jako rosa, że się rozkwitnie jako lilija, a zapuści korzenie swe jako Liban.
Èmi o dàbí ìrì sí Israẹli, wọn o sì yọ ìtànná bi ewéko lílì. Bi kedari ti Lebanoni yóò si ta gbòǹgbò.
6 Rozrosną się gałęzie jego, a ozdoba jego będzie jako oliwne drzewo, a woń jego jako Libańska.
Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà, dídán ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi olifi. Òórùn rẹ yóò sì dàbí igi kedari ti Lebanoni.
7 Nawrócą się, aby siedzieli pod cieniem jego, ożyją jako zboże, i puszczą się jako winna macica, której pamiątka będzie jako wino Libańskie.
Àwọn ènìyàn yóò tún padà gbé lábẹ́ òjijì rẹ̀. Yóò rúwé bi ọkà. Yóò sì yọ ìtànná bi àjàrà, òórùn rẹ yóò dàbí ti wáìnì Lebanoni.
8 Efraimie! cóż mi już do bałwanów? Ja cię wysłucham, i wejrzę na cię; Jam jest jako jodła zielona, ze mnie się owoc twój znalazł.
Ìwọ Efraimu, kín ló tún kù tí mo ní ṣe pẹ̀lú ère òrìṣà? Èmi ó dá a lóhùn, èmi ó sì ṣe ìtọ́jú rẹ. Mo dàbí igi junifa tó ń fi gbogbo ìgbà tutù, èso tí ìwọ ń so si ń wá láti ọ̀dọ̀ mi.”
9 Kto mądry, niech to zrozumie, a kto roztropny, niech to pozna; bo drogi Pańskie są proste, a sprawiedliwi po nich chodzić będą, ale przestępcy na nich upadną.
Ta ni ọlọ́gbọ́n? Òun yóò mòye àwọn nǹkan wọ̀nyí. Ta a ní ó mọ̀? Òun yóò ní ìmọ̀ wọn. Títọ́ ni ọ̀nà Olúwa àwọn olódodo si ń rìn nínú wọn, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni yóò kọsẹ̀ nínú wọn.

< Ozeasza 14 >