< Habakuka 1 >

1 Brzemię, które widział prorok Abakuk.
Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.
2 Dokądże wołać będę, o Panie! a nie wysłuchasz? Dokądże do ciebie przed gwałtem krzyczeć będę, a nie wybawisz?
Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi? Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!” Ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?
3 Przeczże dopuszczasz, abym patrzył na nieprawość, i widział bezprawie, i zgubę, i gwałt przeciwko sobie? i przecz się znajduje ten, który swar i niezgodę roznieca?
Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé? Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà? Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi; ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.
4 Dlatego naruszony bywa zakon, a prawu się nigdy dosyć nie dzieje; albowiem niepobożny otacza sprawiedliwego, dlatego wychodzi sąd przewrotny.
Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí, ìdájọ́ òdodo kò sì borí. Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká, nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.
5 Spojrzyjcie na narody a obaczcie i dziwujcie się z zdumieniem, przeto, iż czynię nieco za dni waszych, o czem gdy wam powiadać będą, nie uwierzycie.
“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye, kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi. Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.
6 Albowiem oto Ja wzbudzę Chaldejczyków, naród srogi i prędki, który szeroko pójdzie przez ziemię, aby posiadł mieszkania cudze.
Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde, àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.
7 Straszny jest i ogromny; od niego samego wynijdzie sąd jego, i wywyższenie jego.
Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà, ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn, yóò máa ti inú wọn jáde.
8 Konie jego prędsze będą niż lamparty, a sroższe nad wilki wieczorne; szeroko rozciągną się jezdni jego, a jezdni jego z daleka przyjdą, przylecą jako orzeł spieszący się do żeru.
Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ, wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká; wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré, wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun,
9 Każdy z nich dla łupiestwa przyjdzie; obrócą twarze swoje na wschód słońca, a więźniów zgromadzą jako piasek.
gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú; wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.
10 Ten i z królów szydzić będzie, a książęta będą na pośmiech u niego; ten też z każdej twierdzy naśmiewać się będzie, a usypawszy wały weźmie ją.
Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé. Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín; nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á.
11 Tedy się odmieni duch jego, a wystąpi i przewini, myśląc, że ta moc jego jest boga jego.
Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà, yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”
12 Izaliś ty nie jest od wieku, Panie, Boże mój, święty mój? myć nie pomrzemy; o Panie! postawiłeś go na sąd; ty, o skało nasza! na karanieś go ugruntował.
Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà? Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́; Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí.
13 Czyste są oczy twoje, tak, że na złe patrzyć i bazprawia widzieć nie mogą; przeczżebyś miał patrzyć na czyniących przewrotność? Przeczżebyś miał milczeć, ponieważ niezbożnik pożera sprawiedliwszego niżeli sam?
Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi; ìwọ kò le gbà ìwà ìkà nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè? Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?
14 Miałżebyś zaniechać ludzi jako ryb morskich, jako płazu, który nie ma pana?
Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun, bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso.
15 Wszystkie wędą wyciąga, zagarnia je niewodem swoim, i zgromadza je do sieci swoich; dlategoż się weseli i raduje.
Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀; nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.
16 Przeto ofiaruje niewodowi swemu i kadzi sieci swojej; albowiem przez nie utył dział jego, a pożywienie jego hojniejsze.
Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀, ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀ nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.
17 Izali dlatego będzie zapuszczał niewód swój, a ustawicznie zabijał narody bez litości?
Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí, tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?

< Habakuka 1 >