< Rodzaju 6 >

1 I stało się, gdy się ludzie poczęli rozmnażać na ziemi, a córki się im zrodziły;
Nígbà tí ènìyàn bẹ̀rẹ̀ sí ní pọ̀ si ní orí ilẹ̀, wọ́n sí bí àwọn ọmọbìnrin.
2 Że, widząc synowie Boży córki ludzkie, iż były piękne, brali je sobie za żony, ze wszystkich, które sobie upodobali.
Àwọn ọmọ Ọlọ́run rí i wí pé àwọn ọmọbìnrin ènìyàn lẹ́wà, wọ́n sì fẹ́ èyíkéyìí tí ó wù wọ́n ṣe aya.
3 I rzekł Pan: Nie będzie się wadził duch mój z człowiekiem na wieki, gdyż jest ciałem; i będą dni jego sto i dwadzieścia lat.
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èémí ìyè tí mo mí sínú ènìyàn kò ní máa gbé inú ènìyàn títí láé, nítorí ẹran-ara sá à ni òun, ọgọ́fà ọdún ni ọjọ́ rẹ̀ yóò jẹ́.”
4 A byli olbrzymowie na ziemi w one dni; nawet i potem, gdy weszli synowie Boży do córek ludzkich, rodziły im syny. A cić są mocarze, którzy od wieku byli mężowie sławni.
Àwọn òmíràn wà láyé ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti lẹ́yìn ìgbà náà; nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run lọ bá àwọn ọmọbìnrin ènìyàn lòpọ̀ tí wọ́n sì bímọ fún wọn. Àwọn náà ni ó di akọni àti olókìkí ìgbà náà.
5 A widząc Pan, że wielka była złość ludzka na ziemi, a wszystko zmyślanie myśli serca ich tylko złe było po wszystkie dni;
Olúwa sì rí bí ìwà búburú ènìyàn ti ń gbilẹ̀ si, àti pé gbogbo èrò inú rẹ̀ kìkì ibi ni, ní ìgbà gbogbo.
6 Żałował Pan, że uczynił człowieka na ziemi, i bolał w sercu swem.
Inú Olúwa sì bàjẹ́ gidigidi nítorí pé ó dá ènìyàn sí ayé, ọkàn rẹ̀ sì gbọgbẹ́.
7 I rzekł Pan: Wygładzę człowieka, któregom stworzył, z oblicza ziemi, od człowieka aż do bydlęcia, aż do gadziny, i aż do ptastwa niebieskiego; bo mi żal, żem je uczynił.
Nítorí náà, Olúwa wí pé, “Èmi yóò pa ènìyàn tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀, ènìyàn àti ẹranko, àti ohun tí ń rákò, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, nítorí inú mi bàjẹ́ pé mo ti dá wọn.”
8 Ale Noe znalazł łaskę w oczach Pańskich.
Ṣùgbọ́n, Noa rí ojúrere Olúwa.
9 Teć są rodzaje Noego: Noe mąż sprawiedliwy, doskonałym był za wieku swego; z Bogiem chodził Noe.
Wọ̀nyí ni ìtàn Noa. Noa nìkan ni ó jẹ́ olóòótọ́ ènìyàn àti ẹni tí ó pé ní ìgbà ayé rẹ̀, ó sì fi òtítọ́ bá Ọlọ́run rìn.
10 I spłodził Noe trzech synów, Sema, Chama, i Jafeta.
Noa sì bí ọmọkùnrin mẹ́ta, Ṣemu, Hamu àti Jafeti.
11 Ale ziemia popsowała się była przed Bogiem; i napełniła się nieprawością.
Ayé sì kún fún ìbàjẹ́ gidigidi ní ojú Ọlọ́run, ó sì kún fún ìwà ipá pẹ̀lú.
12 Tedy wejrzał Bóg na ziemię, a oto popsowana była (albowiem zepsowało było wszelkie ciało drogę swoję na ziemi).
Ọlọ́run sì rí bí ayé ti bàjẹ́ tó, nítorí àwọn ènìyàn inú ayé ti bá ara wọn jẹ́ ní gbogbo ọ̀nà wọn.
13 I rzekł Bóg do Noego: Koniec wszelkiego ciała przyszedł przed oblicze moje, bo napełniona jest ziemia nieprawością od oblicza ich; przetoż je wytracę z ziemi.
Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èmi yóò pa gbogbo ènìyàn run, nítorí ilẹ̀ ayé kún fún ìwà ipá nípasẹ̀ wọn. Èmi yóò pa wọ́n run àti ayé pẹ̀lú.
14 Uczyń sobie korab z drzewa Gofer; przegrody poczynisz w korabiu, i oblejesz go wewnątrz i zewnątrz smołą.
Nítorí náà fi igi ọ̀mọ̀ kan ọkọ̀, kí o sì yọ yàrá sí inú rẹ̀, kí o sì fi ọ̀dà ilẹ̀ rẹ́ ẹ tinú-tẹ̀yìn.
15 A uczynisz go na ten kształt: Trzy sta łokci będzie długość korabia; pięćdziesiąt łokci szerokość jego, a trzydzieści łokci wysokość jego.
Báyìí ni ìwọ yóò ṣe kan ọkọ̀ náà: Gígùn rẹ̀ ní òró yóò jẹ́ ọ̀ọ́dúnrún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ yóò jẹ́ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́, nígbà tí gíga rẹ̀ yóò jẹ́ ọgbọ̀n ìgbọ̀nwọ́.
16 Okno uczynisz w korabiu; a na łokieć wywiedziesz je wzwyż, i drzwi korabiu w boku jego postawisz; piętra spodnie wtóre i trzecie uczynisz w nim.
Ṣe òrùlé sí orí ọkọ̀ náà ní ìgbọ̀nwọ́ kan, sì ṣe ọkọ̀ náà ní alájà mẹ́ta, ipá kan ní ìsàlẹ̀, ọ̀kan ní àárín àti ọ̀kan tí ó kù ní òkè, ẹ̀gbẹ́ ni kí ó ṣe ẹnu-ọ̀nà ọkọ̀ náà sí.
17 A Ja oto, Ja przywiodę potop wód na ziemię, ku wytraceniu wszelkiego ciała, w którem jest duch żywota pod niebem; wszystko, cokolwiek jest na ziemi, pozdycha.
Èmi yóò mú ìkún omi wá sí ayé láti pa gbogbo ohun ẹlẹ́mìí run lábẹ́ ọ̀run. Gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè ní inú. Gbogbo ohun tí ó wà nínú ayé yóò parun.
18 Ale z tobą postanowię przymierze moje; i wnijdziesz do korabia, ty i synowie twoi, i żona twoja, i żony synów twoich z tobą.
Ṣùgbọ́n èmi ó dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì wọ ọkọ̀, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú aya rẹ.
19 I ze wszech zwierząt wszelkiego ciała po dwojgu ze wszech, wprowadzisz do korabia, aby żywo zachowane były z tobą, samiec i samica będą.
Ìwọ yóò mú gbogbo ohun alààyè takọ tabo wá sí inú ọkọ̀, kí wọn le wà láààyè pẹ̀lú rẹ.
20 Z ptastwa według rodzaju jego, i z bydła według rodzaju jego, i z wszelkiej gadziny ziemskiej według rodzaju jej, po dwojgu z każdego rodzaju wnijdą z tobą, aby żywe zostały.
Mú onírúurú àwọn ẹyẹ, ẹranko àti àwọn ohun tí ń rákò ní méjì méjì, kí a bá lè pa wọ́n mọ́ láààyè.
21 A ty weźmiesz z sobą wszelkiego pokarmu, który się jeść godzi, a zbierzesz do siebie, i będzie tobie i onym na pokarm.
Mú onírúurú oúnjẹ wá sínú ọkọ̀, kí o pa wọ́n mọ́ fún jíjẹ gbogbo ẹ̀yin tí ẹ wà nínú ọkọ̀ àti ènìyàn àti ẹranko.”
22 I uczynił Noe według wszystkiego; jako mu rozkazał Bóg, tak uczynił.
Noa sì ṣe ohun gbogbo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.

< Rodzaju 6 >

The World is Destroyed by Water
The World is Destroyed by Water