< Rodzaju 47 >

1 Tedy przyjechawszy Józef, oznajmił Faraonowi, i rzekł: Ojciec mój i bracia moi z owcami swemi, i z wołami swymi, i ze wszystkiem, co mają, przyjechali z ziemi Chananejskiej; a oto, są w ziemi Gosen.
Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.”
2 A z liczby braci swej wziął pięciu mężów, i postawił je przed Faraonem.
Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.
3 I rzekł Farao do braci jego: Czem się bawicie? A oni odpowiedzieli Faraonowi: Pasterzami owiec są słudzy twoi, i my i ojcowie nasi.
Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?” Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran.”
4 Rzekli jeszcze do Faraona: Abyśmy byli przychodniami w tej ziemi, przyszliśmy; bo nie masz paszy dla bydła, które mają słudzy twoi, gdyż ciężki głód jest w ziemi Chananejskiej; a teraz niech mieszkają, prosimy, słudzy twoi w ziemi Gosen.
Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”
5 Tedy rzekł Farao do Józefa mówiąc: Ojciec twój i bracia twoi przyjechali do ciebie;
Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá,
6 Ziemia Egipska przed tobą jest: w najlepszem miejscu tej ziemi daj mieszkanie ojcu twemu i braci twojej, niech mieszkają w ziemi Gosen; a zrozumieszli, że są między nimi mężowie godni, tedy je uczynisz przełożonymi nad trzodami memi.
ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ, mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”
7 I przywiódł Józef Jakóba, ojca swego, i postawił go przed Faraonem; a błogosławił Jakób Faraonowi.
Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán.
8 Tedy rzekł Farao do Jakóba: Wiele jest dni lat żywota twego?
Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”
9 I odpowiedział Jakób Faraonowi: Dni lat pielgrzymstwa mego jest sto i trzydzieści lat; krótkie i złe były dni lat żywota mego, i nie doszły dni lat żywota ojców moich, w których dniach oni pielgrzymowali.
Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje, ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.”
10 Zatem pobłogosławiwszy Jakób Faraonowi, wyszedł od oblicza Faraonowego.
Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.
11 Tedy dał mieszkanie Józef ojcu swemu i braci swej, i dał im osiadłość w ziemi Egipskiej, w najlepszem miejscu onej krainy, w ziemi Rameses, jako był rozkazał Farao.
Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ.
12 I żywił Józef ojca swego i bracią swoję, i wszystek dom ojca swego chlebem aż do najmniejszego.
Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.
13 A chleba nie było po wszystkiej ziemi; bo ciężki bardzo był głód, i utrapiona była ziemia Egipska, i ziemia Chananejska od głodu.
Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà.
14 Tedy zebrał Józef wszystkie pieniądze, które się znajdowały w ziemi Egipskiej i w ziemi Chananejskiej, za żywność, którą kupowano; i wniósł one pieniądze Józef do skarbu Faraonowego.
Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao.
15 A gdy nie stało pieniędzy w ziemi Egipskiej, i w ziemi Chananejskiej, tedy przyszli wszyscy Egipczanie do Józefa, mówiąc: Daj nam chleba, i czemuż mamy umierać przed tobą, gdyż nam już nie staje pieniędzy?
Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”
16 Na to odpowiedział Józef: Dawajcie bydła wasze, a dam wam żywności za bydła wasze, ponieważ wam nie stało pieniędzy.
Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.”
17 I przygnali bydła swe do Józefa; i dał im Józef chleba za konie, i za stada owiec, i za stada wołów, i za osły, i przechował je chlebem za wszystkie bydła ich, onego roku.
Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.
18 A gdy wyszedł rok on, przyszli do niego roku drugiego, mówiąc mu: Nie zatajemy przed panem naszym, że nam już pieniędzy nie stało, i stada bydeł są u pana naszego; nie zostawa nam przed panem naszym, tylko ciała nasze i role nasze.
Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa.
19 A czemuż umierać mamy przed oczyma twemi? i nas, i role nasze kupuj i ziemię naszę za chleb, a będziemy, my i ziemia nasza, w niewoli u Faraona; tylko nam daj nasienia, abyśmy żyli a nie pomarli, i ziemia nie spustoszała.
Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”
20 A tak kupił Józef wszystkę ziemię Egipską Faraonowi; bo sprzedali Egipczanie, każdy rolą swoję, gdyż się był wzmógł między nimi głód; i dostała się Faraonowi wszystka ziemia.
Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao,
21 I przeniósł lud do miast, od ostatnich granic Egiptu aż do końca jego.
Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì.
22 Tylko ziemi kapłańskiej nie kupił; bo kapłani mieli obrok postanowiony od Faraona, i żywili się obrokiem swym, który im dał Farao; dlategoż nie sprzedawali ziemi swej.
Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.
23 I rzekł Józef do ludu: Otom was teraz poskupował i ziemię waszę Faraonowi; otóż macie nasienie, posiejcież tedy role.
Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà.
24 A z urodzajów waszych będziecie dawali piątą część Faraonowi; cztery zasię części będą wam na zasianie roli, i na żywność waszę i tych, którzy są w domach waszych, i na żywność dziatek waszych.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”
25 Tedy odpowiedzieli: Zachowałeś żywot nasz; niechże znajdziemy łaskę w oczach pana swego, i będziemy niewolnikami Faraonowymi.
Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”
26 I postanowił to Józef za prawo aż do dnia dzisiejszego w ziemi Egipskiej, aby dawana była Faraonowi piąta część; tylko ziemia samych kapłanów nie dostała się Faraonowi.
Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.
27 I mieszkał Izrael w ziemi Egipskiej, w ziemi Gosen, i osadziwszy się w niej, rozrodzili się, i rozmnożyli się wielce.
Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.
28 I żył Jakób w ziemi Egipskiej siedemnaście lat; a było dni Jakóbowych, lat żywota jego, sto czterdzieści i siedem lat.
Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tàdínlógún iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹẹ́tàdínlàádọ́jọ.
29 I przybliżyły się dni Izraelowe, aby umarł; i wezwał syna swego Józefa i rzekł do niego: Jeźlim teraz znalazł łaskę w oczach twoich, połóż proszę rękę twoję pod biodro moje, a uczyń ze mną miłosierdzie i prawdę; proszę nie chowaj mię w Egipcie;
Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti.
30 Ale gdy zasnę z ojcy moimi, wyniesiesz mię z Egiptu, a pochowasz mię w grobie ich. A on rzekł: Uczynię według słowa twego.
Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.” Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”
31 A Jakób rzekł: Przysiążże mi: i przysiągł mu. Zatem nakłonił się Izrael ku głowom łoża.
Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.

< Rodzaju 47 >