< Rodzaju 46 >

1 A tak jechał Izrael ze wszystkiem, co miał, a przyjechawszy do Beerseby, ofiarował ofiary Bogu ojca swego Izaaka.
Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
2 I rzekł Bóg do Izraela w widzeniu nocnem, mówiąc: Jakóbie, Jakóbie; a on odpowiedział: Owom ja.
Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
3 I rzekł: Jam jest Bóg, Bóg ojca twojego; nie bój się zstąpić do Egiptu, bo cię tam w naród wielki rozmnożę.
Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
4 Ja zstąpię z tobą do Egiptu, i Ja cię stamtąd także zasię wywiodę, a Józef położy rękę swoję na oczy twoje.
Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
5 I powstał Jakób z Beerseby; i wzięli synowie Izraelowi Jakóba ojca swego, i dziatki swe, i żony swe na wozy, które był posłał Farao, aby go przywieziono.
Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
6 Pobrali też bydła swe, i majętność swoję, której byli nabyli w ziemi Chananejskiej, i przyjechali do Egiptu, Jakób i wszystka rodzina jego z nim;
Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
7 Syny swe, i syny synów swych, córki swe i córki synów swych, i wszystko nasienie swoje prowadził z sobą do Egiptu.
Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
8 A teć są imiona synów Izraelowych, którzy weszli do Egiptu: Jakób i synowie jego: pierworodny Jakóbów Ruben.
Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
9 A synowie Rubenowi: Henoch, i Fallu, i Hesron i Charmi.
Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
10 A synowie Symeonowi: Jemuel, i Jamyn, i Achod, i Jachyn, i Sochar, i Saul, syn niewiasty Chananejskiej.
Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
11 Synowie też Lewiego: Gerson, Kaat, i Merary.
Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
12 A synowie Judasowi: Her, i Onan, i Sela, i Fares, i Zara; ale umarł Her i Onan w ziemi Chananejskiej. A byli synowie Faresowi: Hesron i Hamuel.
Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
13 A synowie Isaszarowi: Tola, i Fua, i Job, i Simron.
Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
14 Synowie zaś Zabulonowi: Zared, i Elon, i Jaleel.
Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
15 A cić są synowie Lii, które urodziła Jakóbowi w Padanie Syryjskim, i Dyna córka jego; wszystkich dusz synów jego, i córek jego, trzydzieści i trzy.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
16 A synowie Gadowi: Sefon, i Aggi, Suny, i Esebon, Ery, i Arody, i Areli.
Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
17 A synowie Aser: Jemna, i Jesua, i Isui, i Beryja, i Sera, siostra ich. A synowie Beryjego: Heber, i Melchyjel.
Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
18 Cić są synowie Zelfy, którą był dał Laban Lii, córce swej, których ona urodziła Jakóbowi, szesnaście dusz.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
19 Synowie Racheli, żony Jakóbowej: Józef i Benjamin.
Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
20 Józefowi zaś urodzili się synowie w ziemi Egipskiej, które mu urodziła Asenat, córka Potyfara, książęcia Ońskiego: Manases i Efraim.
Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
21 A synowie Benjaminowi: Bela, i Bechor, i Asbel, Gera, i Naamann, Echy i Ros, Mupim, i Chupim, i Ared.
Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
22 Cić są synowie Racheli, którzy się urodzili Jakóbowi; wszystkich dusz czternaście.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
23 A synowie Danowi: Chusym.
Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
24 Synowie też Neftalimowi: Jachsyjel, i Gunny, i Jeser, i Selem.
Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
25 Ci są synowie Bali, którą był dał Laban Racheli, córce swej, która je urodziła Jakóbowi; wszystkich dusz siedem.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
26 Wszystkie dusze, które przyszły z Jakóbem do Egiptu, co wyszły z biódr jego, okrom żon synów Jakóbowych, wszystkich dusz było sześćdziesiąt i sześć.
Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
27 A synów Józefowych, którzy mu się urodzili w Egipcie, dusz dwie. A tak wszystkich dusz domu Jakóbowego, które weszły do Egiptu, było siedemdziesiąt.
Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
28 I posłał przed sobą Judasa do Józefa, aby mu oznajmił pierwej, niżby przyjechał do Gosen. I przyjechali do ziemi Gosen.
Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
29 A zaprzągłszy Józef wóz swój, wyjechał przeciw Izraelowi, ojcu swemu, do Gosen; a ujrzawszy go ( Jakób ) padł na szyję jego, i płakał na szyi jego chwilę.
Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
30 Tedy rzekł Izrael do Józefa: Niechże już umrę, gdym ujrzał oblicze twoje, ponieważeś ty jeszcze żyw.
Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
31 Zatem rzekł Józef do braci swej i do domu ojca swego: Pojadę, a opowiem Faraonowi, i rzekę mu: Bracia moi i dom ojca mego, którzy byli w ziemi Chananejskiej, przyjechali do mnie;
Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
32 A ci mężowie są pasterze trzód, bo się bawili chowaniem bydła; przeto owce swoje, i woły swoje, i wszystko, co mieli, przywiedli.
Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
33 A tak gdy was przyzowie Farao, i spyta: Czem się bawicie?
Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
34 Odpowiecie: Pasterze byli słudzy twoi od dzieciństwa naszego aż dotąd, i my i ojcowie nasi; a to dla tego abyście mogli mieszkać w ziemi Gosen, bo obrzydłością Egipczanom jest wszelki pasterz bydła.
ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”

< Rodzaju 46 >