< Rodzaju 39 >
1 Tedy Józef był zawiedzion do Egiptu; i kupił go Potyfar, dworzanin Faraonów, hetman żołnierstwa, mąż Egipczanin, z ręki Ismaelitów, którzy go tam byli zawiedli.
Nígbà tí wọ́n mú Josẹfu dé Ejibiti, Potifari, ará Ejibiti tí i ṣe ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao. Òun ni olórí àwọn ọmọ-ogun Farao. Ó ra Josẹfu lọ́wọ́ àwọn ará Iṣmaeli tí wọ́n mú un lọ síbẹ̀.
2 I był Pan z Józefem, który był mężem szczęśliwie postępującym, a mieszkał w domu pana swego Egipczanina.
Olúwa sì wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì bùkún un, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀gá rẹ̀ ará Ejibiti.
3 I baczył pan jego, że Pan był z nim, a iż wszystko co on czynił, Pan szczęścił w ręku jego.
Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ rí i pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀, àti pé Olúwa jẹ́ kí ó máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́ rẹ̀ lé.
4 I znalazł Józef łaskę w oczach jego, i służył mu; i przełożył go nad domem swym, a podał wszystko co miał, w ręce jego.
Josẹfu sì rí ojúrere Potifari, ó sì di aṣojú rẹ̀, Potifari fi Josẹfu ṣe olórí ilé rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
5 I stało się, gdy go przełożył nad domem swym, i nad wszystkiem, co miał, błogosławił Pan domowi Egipczanina dla Józefa; i było błogosławieństwo Pańskie nad wszystkiem, cokolwiek miał w domu i na polu.
Láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu jẹ olórí ilé rẹ̀ àti ohun ìní rẹ̀ gbogbo, ni Ọlọ́run ti bẹ̀rẹ̀ sí ní bùkún àwọn ará Ejibiti nítorí Josẹfu. Ìbùkún Olúwa wà lórí gbogbo ohun tí Potifari ní, nílé àti lóko.
6 Przetoż poruczył wszystko, co miał, w ręce Józefowe, i ni o czem u siebie nie wiedział, tylko o chlebie, którego pożywał. A był Józef pięknej twarzy, i wdzięczny na wejrzeniu.
Ó sì fi Josẹfu ṣe àkóso gbogbo ohun tí ó ní. Kò sì ṣe ìyọnu lórí ohunkóhun mọ àyàfi nípa oúnjẹ tí ó ń jẹ láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu ṣe àkóso ilé e rẹ̀. Josẹfu sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin ní ìdúró àti ìrísí rẹ̀,
7 I stało się potem, iż obróciła żona pana jego oczy swoje na Józefa, i rzekła: Śpij ze mną.
lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, aya rẹ̀ ṣe àkíyèsí Josẹfu, ó sì wí fún un pé, “Wá bá mi lòpọ̀!”
8 Ale nie chciał: i rzekł do żony pana swego: Oto, pan mój nie wie, tak jako ja, co jest w domu jego; bo wszystko, co miał, podał w ręce moje.
Ṣùgbọ́n Josẹfu kọ̀, ó sì wí fún aya ọ̀gá rẹ̀ pé, “Kíyèsi, Olúwa mi kò fi ohunkóhun dù mi nínú ilé yìí, gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni ó fi lé mi lọ́wọ́.
9 I nie masz nikogo w domu tym nad mię przedniejszego, i nie wyjął mi nic z mocy, prócz ciebie, przeto żeś ty jest żona jego; jakoż bym tedy miał uczynić tę wielką złość, i grzeszyć przeciwko Bogu?
Kò sí ẹni tí ó jù mi lọ nínú ilé yìí, ọ̀gá mi kò fi ohunkóhun dù mi àyàfi ìwọ, tí í ṣe aya rẹ̀. Báwo ni mo ṣe lè ṣe ohun búburú yìí, kí ń sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run?”
10 I stało się, gdy ona namawiała Józefa na każdy dzień, a on jej nie zezwalał, aby spał z nią, albo bywał z nią:
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ìgbà ni ó ń tẹnumọ́ èyí fún Josẹfu, Josẹfu kọ̀ láti bá a lòpọ̀. Ó tilẹ̀ kọ̀ láti máa dúró ni ibi tí ó bá wà.
11 Tedy dnia niektórego, gdy wszedł do domu, dla odprawowania pracy swej, a nie było tam z domowników nikogo w domu;
Ní ọjọ́ kan, Josẹfu lọ sínú ilé láti ṣe iṣẹ́, kò sì sí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ ní tòsí.
12 Uchwyciła go za szatę jego, mówiąc: Śpij ze mną. Ale on zostawiwszy szatę swoję w ręku jej, uciekł, i wyszedł precz.
Ó sì di aṣọ Josẹfu mú, ó sì wí pé, “Wá bá mi lòpọ̀!” Ṣùgbọ́n Josẹfu fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí i lọ́wọ́, ó sì sá jáde.
13 A gdy ona obaczyła, iż zostawił szatę swoję w ręku jej, a uciekł precz;
Nígbà tí ó rí i pé ó ti fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí òun lọ́wọ́, ó sì ti sá jáde,
14 Tedy zawołała na czeladź domu swego, i rzekła do nich, mówiąc: Wejcie, wprowadził pan do nas męża Hebrejczyka, aby nas zelżył; albowiem wszedł do mnie, aby ze mną spał, ażem wołała głosem wielkim.
ó pe àwọn ìránṣẹ́ ilé náà, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ó, ọkọ ọ̀ mi mú Heberu kan wọlé tọ̀ wá wá láti fi wá ṣe ẹlẹ́yà. Ó wọlé tọ̀ mí wá, láti bá mi lòpọ̀, ṣùgbọ́n mo kígbe.
15 A gdy usłyszał, żem wyniosła głos mój, i zawołała, zostawiwszy szatę swoję u mnie, uciekł, i wyszedł precz.
Nígbà tí ó gbọ́ pé mo gbé ohùn mi sókè, tí mo sì kígbe, ó jọ̀wọ́ aṣọ rẹ̀ sọ́dọ̀ mi, ó sì sá, ó bọ́ sóde.”
16 I zatrzymała jego szatę u siebie, aż przyszedł pan jego do domu swego;
Ó sì fi aṣọ náà sọ́dọ̀ títí tí ọkọ rẹ̀ fi dé.
17 I rzekła do niego w te słowa, mówiąc: Wszedł do mnie sługa ten Hebrejczyk, któregoś przywiódł do nas, aby mię zelżył.
Ó rò fún un pé, “Ẹrú ará Heberu tí o rà wá ilé láti fi wá ṣẹlẹ́yà wá láti bá mi lòpọ̀.
18 A gdym podniosła głos swój, i zawołała, tedy zostawił szatę swą u mnie, i uciekł precz.
Ṣùgbọ́n bí mo ti kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ó sì sá kúrò nínú ilé.”
19 I stało się, gdy usłyszał pan jego słowa żony swojej, które rzekła do niego, mówiąc: Tak mi uczynił sługa twój, rozgniewał się bardzo.
Nígbà tí Potifari gbọ́ ọ̀rọ̀ aya rẹ̀ pé báyìí ni ẹrú rẹ̀ ṣe sí aya rẹ̀, ó bínú gidigidi.
20 I wziął pan Józefa, a dał go do domu więzienia, tam, gdzie więźnie królewskie sadzano, i był tam w domu więzienia.
Ó sì ju Josẹfu sí ẹ̀wọ̀n, níbi tí a ń ju àwọn ẹlẹ́wọ̀n ọba sí. Ṣùgbọ́n, nígbà tí Josẹfu wà nínú ẹ̀wọ̀n níbẹ̀,
21 A Pan był z Józefem, i skłoniwszy ku niemu miłosierdzie, dał mu łaskę w oczach przełożonego nad domem więzienia.
Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ṣàánú fún un, ó sì mú kí ó rí ojúrere àwọn alábojútó ọgbà ẹ̀wọ̀n.
22 Tedy przełożony nad domem więzienia, podał w moc Józefowi wszystkie więźnie, którzy byli w domu więzienia; a wszystko, co tam czynić mieli, to on sprawował.
Nítorí náà, alábojútó ọgbà ẹlẹ́wọ̀n fi Josẹfu ṣe alákòóso ohun gbogbo tí ó wà nínú ẹ̀wọ̀n, àti ohun tí wọn ń ṣe níbẹ̀.
23 A przełożony nad domem więzienia nie doglądał tego, czego mu się powierzył, dla tego iż Pan był z nim, a co on czynił, to Pan szczęścił.
Wọ́dà náà kò sì mikàn nípa gbogbo ohun tí ó fi sí abẹ́ àkóso Josẹfu, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì ń jẹ́ kí ó ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé.