< Rodzaju 30 >

1 A widząc Rachel, że nie rodziła Jakóbowi, zajrzała Rachel siostrze swej, rzekła do Jakóba: Daj mi syny, a jeźli nie dasz, umrę.
Nígbà tí Rakeli rí i pe òun kò bímọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara sí Lea, arábìnrin rẹ̀, ó sì wí fún Jakọbu pé, “Fún mi lọ́mọ, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó kú!”
2 Zapalił się tedy gniewem Jakób na Rachelę, i rzekł: Zażem ja Bóg, który zawściągnął płód żywota twego?
Inú sì bí Jakọbu sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
3 A ona rzekła: Oto służebnica moja Bala; wnijdźże do niej, i porodzi na kolanach moich, a będę też miała syny z niej.
Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Biliha ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
4 I dała mu Balę, służebnicę swoję, za żonę; i wszedł Jakób do niej.
Báyìí ni Rakeli fi Biliha fún Jakọbu ní aya, ó sì bá a lòpọ̀.
5 Tedy poczęła Bala, i urodziła Jakóbowi syna.
Biliha sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
6 I rzekła Rachel: Skazał za mną Bóg, i usłyszał głos mój, a dał mi syna; i dlatego nazwała imię jego Dan.
Rakeli sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dani.
7 Potem zaś począwszy porodziła Bala, służebnica Racheli, drugiego syna Jakóbowi.
Biliha, ọmọ ọ̀dọ̀ Rakeli sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
8 Tedy rzekła Rachel: Mężniem się biedziła z siostrą moją, a przemogłam; i nazwała imię jego Neftali.
Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Naftali.
9 A obaczywszy Lija, że przestała rodzić, wzięła też Zelfę, służebnicę swoję, i dała ją Jakóbowi za żonę.
Nígbà tí Lea sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Silipa fún Jakọbu bí aya.
10 I urodziła Zelfa, służebnica Lii, Jakóbowi syna.
Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
11 Zatem Lija rzekła: Przyszedł huf; i nazwała imię jego Gad.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Orí rere ni èyí!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gadi.
12 Porodziła też Zelfa, służebnica Lii, drugiego syna Jakóbowi.
Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì tún bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
13 I rzekła Lija: To na szczęście moje; bo mię szczęśliwą będą zwały niewiasty; i nazwała imię jego Aser.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Aṣeri.
14 I wyszedł Ruben czasu żniwa pszenicznego, i znalazł pokrzyki na polu, a przyniósł je do Lii, matki swej; i rzekła Rachel do Lii: Daj mi też proszę z pokrzyków syna twego.
Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Reubeni jáde lọ sí oko, ó sì rí èso mándrákì, ó sì mú un tọ Lea ìyá rẹ̀ wá. Rakeli sì wí fún Lea pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara èso mándrákì tí ọmọ rẹ mú wá.”
15 A ona jej odpowiedziała: A małoż na tem, żeś mi wzięła męża mego, iż też chcesz wziąć i pokrzyki syna mego? Tedy rzekła Rachel: Niechajże śpi z tobą tej nocy za pokrzyki syna twego.
Ṣùgbọ́n Lea dalóhùn pé, “Ọkọ mi tí o gbà kò tó kọ́? Ṣe ìwọ yóò tún gba èso mándrákì ọmọ mi pẹ̀lú?” Rakeli sì dáhùn pé, “Ó dára, yóò sùn tì ọ́ lálẹ́ yìí nítorí èso mándrákì ọmọ rẹ.”
16 A gdy się wracał Jakób z pola pod wieczór, wyszła Lija przeciwko jemu, i rzekła: Do mnie wnijdziesz, gdyżem cię pewną zapłatą najęła sobie pokrzykami syna mego; i spał z nią onej nocy.
Nítorí náà, nígbà tí Jakọbu ti oko dé ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, Lea jáde lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí pé, “O ní láti sun ọ̀dọ̀ mi ní alẹ́ yìí nítorí mo ti fi èso mándrákì tí ọmọ mi wá bẹ̀ ọ́ lọ́wẹ̀.” Nítorí náà ni Jakọbu sùn tì í ní alẹ́ ọjọ́ náà.
17 Tedy wysłuchał Bóg Liję; i poczęła, i porodziła Jakóbowi syna piątego.
Ọlọ́run sì gbọ́ ti Lea, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin karùn-ún fún Jakọbu.
18 I rzekła Lija: Oddał mi Bóg zapłatę moją, żem była dała służebnicę moję mężowi mojemu; i nazwała imię jego Isaszar.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Ọlọ́run ti sẹ̀san ọmọ ọ̀dọ̀ mi ti mo fi fún ọkọ mi fún mi,” ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isakari.
19 Potem począwszy jeszcze Lija, porodziła szóstego syna Jakóbowi.
Lea sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kẹfà fún Jakọbu.
20 I mówiła Lija: Obdarzył mnie Bóg zacnym upominkiem; już teraz będzie ze mną mieszkał mąż mój, bom mu urodziła sześciu synów; i nazwała imię jego Zabulon.
Nígbà náà ni Lea tún wí pé “Ọlọ́run ti fún mi ní ẹ̀bùn iyebíye, nígbà yìí ni ọkọ mi yóò máa bu ọlá fún mi.” Nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ni Sebuluni.
21 Potem porodziła córkę, i nazwała imię jej Dyna.
Lẹ́yìn èyí, ó sì bí ọmọbìnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dina.
22 Wspomniał też Bóg, na Rachelę, i wysłuchał ją Bóg, a otworzył żywot jej.
Nígbà náà ni Ọlọ́run rántí Rakeli, Ọlọ́run sì gbọ́ tirẹ̀, ó sì ṣí i ní inú.
23 Tedy począwszy porodziła syna, i rzekła: Odjął Bóg zelżywość moję.
Ó lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ó sì wí pé, “Ọlọ́run ti mú ẹ̀gàn mi kúrò.”
24 I nazwała imię jego Józef, mówiąc: Niech mi przyda Pan drugiego syna.
Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ni Josẹfu, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ kí Olúwa kí ó fi ọmọkùnrin mìíràn kún un fún mi.”
25 I stało się, gdy porodziła Rachel Józefa, mówił Jakób do Labana: Puść mię, abym się wrócił do miejsca mego, i do ziemi mojej.
Lẹ́yìn tí Rakeli ti bí Josẹfu, Jakọbu wí fún Labani pé, “Jẹ́ kí èmi máa lọ sí ilẹ̀ mi tí mo ti wá.
26 Daj mi żony moje, i dzieci moje, za którem ci służył, że odejdę; bo ty wiesz posługi moje, jakom ci służył.
Kó àwọn ọmọ àti ìyàwó mi fún mi, àwọn ẹni tí mo ti torí wọn sìn ọ́. Ki èmi lè máa bá ọ̀nà mi lọ. O sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ tó.”
27 I rzekł do niego Laban: Proszę, jeźlim znalazł łaskę w oczach twoich, zostań ze mną; bom doznał tego, że mi Pan dla ciebie błogosławił.
Ṣùgbọ́n Labani wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.
28 I rzekł: Mianuj mi zapłatę twoję, a dam ci ją.
Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”
29 Tedy mu odpowiedział Jakób: Ty wiesz, jakom ci służył, i jaki był dobytek twój przy mnie.
Jakọbu sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.
30 Bo ta trocha, którąś miał przede mną, rozmnożyła się wielce; i błogosławił ci Pan na przyjście moję, a teraz kiedyż ja się też starać będę o dom swój?
Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”
31 I rzekł: Cóżci mam dać? I odpowiedział Jakób: Nie dasz mi nic; ale jeźli to uczynisz coć powiem, tedy się wrócę, a będę pasł i strzegł bydła twego.
Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?” Jakọbu dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.
32 Przejdę dziś przez wszystkie trzody twoje, odłączając stamtąd każde bydlę pstre i nakrapiane, i każde bydlę płowe między owcami, a nakrapiane i pstre między kozami; to będzie zapłatą moją.
Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.
33 I da świadectwo o mnie sprawiedliwość moja na potem, gdy przyjdzie do zapłaty mojej przed tobą; wszystko co nie będzie pstre i nakrapiane między kozami, a płowe między owcami, niech będzie za kradzież poczytane przy mnie.
Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí gbé.”
34 Tedy rzekł Laban: Oby się stało według słowa twego!
Labani sì dáhùn pé, “Mo fi ara mọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí.”
35 I odłączył onegoż dnia kozły strokate, i nakrapiane, i wszystkie kozy pstre, i nakrapiane, i wszystkie, co jaką białą odmianę miały, także i płowe między owcami, i oddał je do rąk synów swych.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Labani kó gbogbo ewúrẹ́ tí ó ní àmì tàbí ilà (àti òbúkọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgùntàn dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
36 I odłączył się Laban od Jakóba, jakoby na trzy dni drogi; a Jakób pasł ostatek owiec Labanowych.
Ibi tí Labani àti Jakọbu sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jakọbu sì ń tọ́jú agbo ẹran Labani tí ó kù.
37 Nabrał tedy Jakób prętów zielonych topolowych, i laskowych, i kasztanowych, i obłupił miejscami skórę ich do białego, obnażając białość, która na prętach była.
Nígbà náà ni Jakọbu gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi Poplari, àti igi almondi àti igi Pileeni. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
38 I nakładł onych prętów, które był obłupił, do rynien i do koryt, gdzie lano wody ( gdy przychodziły owce, aby piły) nakładł ich przeciwko owcom, aby poczynały, gdyby pić przychodziły.
Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi.
39 I poczynały owce patrząc na one pręty, i rodziły jagnięta strokate, pstre i nakrapiane.
Tí àwọn ẹran bá sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
40 I odłączył Jakób jagnięta, a stawiał owce twarzą do jagniąt strokatych, i do wszystkich płowych w stadzie Labanowem, a swoje stada stawiał osobno, ani ich obracał ku stadu Labanowemu.
Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Labani, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jakọbu dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Labani.
41 A gdy wszystkich owiec co rańszych przypuszczanie bywało, kładł Jakób pręty przed oczy owiec w koryta, aby poczynały patrząc na pręty.
Nígbàkígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jakọbu yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mu omi.
42 Lecz gdy późniejszych owiec przypuszczanie było, nie kładł ich: i były późniejsze Labanowe, a rańsze Jakóbowe.
Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Labani, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jakọbu.
43 I tak zbogacił się on człowiek bardzo, i miał owiec wiele, i służebnic i sług, i wielbłądów, i osłów.
Nítorí ìdí èyí, Jakọbu di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́kùnrin, ìránṣẹ́bìnrin pẹ̀lú ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.

< Rodzaju 30 >