< Rodzaju 27 >

1 I stało się, gdy się zestarzał Izaak, i zaćmiły się oczy jego, tak, iż widzieć nie mógł: tedy wezwał Ezawa, syna swego starszego, i rzekł mu: Synu mój! a on odpowiedział: Owom ja.
Nígbà ti Isaaki di arúgbó, ojú rẹ̀ sì ti di bàìbàì tó bẹ́ẹ̀ tí kò le ríran. Ó pe Esau àkọ́bí rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Ọmọ mi.” Esau sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
2 I rzekł Izaak: Otom się już zestarzał, a nie wiem dnia śmierci swej.
Isaaki sì wí pé, “Nísinsin yìí mo di arúgbó, èmi kò sì mọ ọjọ́ tí èmi yóò kú.
3 Przetoż teraz weźmij proszę naczynia twoje, sajdak twój, i łuk twój, a wynijdź w pole, i ułów mi zwierzynę.
Nítorí náà, mú ohun èlò ọdẹ rẹ, apó àti ọrún, nísinsin yìí kí o sì lọ pa ẹran wá fún mi nínú igbó.
4 I nagotuj mi potrawy smaczne, w jakich się kocham, i przynieś mi, a będę jadł, abyć błogosławiła dusza moja, pierwej, niż umrę.
Kí o sì ṣe ẹran àdídùn fún mi, irú èyí tí mo fẹ́ràn, kí o gbe wá fún mi kí n jẹ, kí n sì súre fún ọ kí n tó kú.”
5 Ale Rebeka słyszała, gdy to mówił Izaak do Ezawa, syna swego; tedy wyszedł Ezaw na pole, aby ułowił zwierzynę i przyniósł.
Ṣùgbọ́n Rebeka ń fetí léko gbọ́ nígbà tí Isaaki ń bá Esau ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nítorí náà, nígbà ti Esau ti ṣe ọdẹ lọ sínú igbó,
6 I rzekła Rebeka do Jakóba, syna swego, mówiąc: Otom słyszała, gdy ojciec twój mówił do Ezawa, brata twego, i rzekł:
Rebeka sọ fún Jakọbu ọmọ rẹ̀ pé, “Wò ó, mo gbọ́ tí baba rẹ ń wí fún Esau ẹ̀gbọ́n rẹ pé,
7 Przynieś mi co z obłowu, a nagotuj mi potrawy smaczne, abym jadł, i błogosławił ci przed obliczem Pańskiem, pierwej, niż umrę.
‘Pa ẹran fún mi wá, kí o sì ṣe oúnjẹ àdídùn fún mi láti jẹ, kí n ba à le súre fún ọ níwájú Olúwa kí èmi tó kú.’
8 A tak teraz synu mój, usłuchaj głosu mego w tem, co ja rozkazuję tobie.
Nísinsin yìí ọmọ mi, gbọ́ tèmi, kí o sì ṣe ohun tí èmi yóò wí fún ọ.
9 A szedłszy do trzody, przynieś mi stamtąd dwoje koźląt dobrych, a nagotuję z nich potrawy smaczne ojcu twemu, jako rad jada.
Lọ sínú agbo ẹran, kí o sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì, kí ó lè ṣe oúnjẹ àdídùn fún baba rẹ, irú èyí tí ó fẹ́ràn dáradára.
10 I zaniesiesz ojcu twemu, a będzie jadł; dlatego abyć błogosławił, pierwej niż umrze.
Ìwọ yóò sì gbé e tọ baba rẹ lọ, kí òun ba à lè jẹ ẹ́, kí ó sì súre fún ọ, kí ó tó kú.”
11 Tedy rzekł Jakób do Rebeki, matki swej: Oto, Ezaw brat mój, człowiek kosmaty, a jam człowiek gładki;
Jakọbu sì wí fún Rebeka ìyá rẹ̀ pé, “Ṣùgbọ́n Esau ẹ̀gbọ́n mi jẹ́ ènìyàn onírun lára, bẹ́ẹ̀ alára ọ̀bọ̀rọ́ sì ni èmi,
12 Jeźli mię pomaca ojciec mój, a będzie rozumiał, że z niego szydzę, przywiodę na się przeklęstwo, a nie błogosławieństwo.
bí baba mi bá fọwọ́ kàn mi ń kọ́? Èmi yóò jọ ẹlẹ́tàn lójú rẹ̀, dípò kí ó súre fún mi, èmi yóò sì mú ègún wá sórí ara mi.”
13 I rzekła mu matka jego: Na mię niech będzie przeklęstwo twoje, synu mój; tylko usłuchaj głosu mego, a szedłszy, przynieś mi.
Ìyá rẹ̀ wá wí fun un pé, “Ọmọ mi jẹ́ kí ègún náà wá sórí mi, sá à ṣe ohun tí mo wí, kí o sì mú wọn wá fún mi.”
14 Tedy on szedłszy wziął, i przyniósł matce swej; i nagotowała matka jego potrawy smaczne, jako rad jadał ojciec jego.
Jakọbu sì ṣe ohun gbogbo tí ìyá rẹ̀ wí fun un, Rebeka sì ṣe oúnjẹ àdídùn náà, irú èyí tí Isaaki fẹ́ràn.
15 I wziąwszy Rebeka szaty Ezawa, syna swego starszego, najkosztowniejsze, które miała u siebie w domu, oblokła w nie Jakóba, syna swego młodszego.
Nígbà náà ni Rebeka mú èyí tí ó dára jù nínú aṣọ Esau ọmọ rẹ̀ àgbà tí ó wà nínú ilé Rebeka, ó sì fi wọ Jakọbu ọmọ rẹ̀ àbúrò.
16 A skórkami koźlęcemi obwinęła ręce jego, i gładkość szyi jego.
Ó sì fi awọ ewúrẹ́ wọ̀n-ọn-nì bo ọwọ́ àti ibi tí ọ̀bọ̀rọ́ ọrùn.
17 I dała chleb i potrawy smaczne, które nagotowała, w ręce Jakóba syna swego.
Nígbà náà ni ó gbé ẹran dídùn náà àti oúnjẹ tí ó ti sè lé Jakọbu ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́.
18 A on wszedłszy do ojca swego mówił: Ojcze mój! a on rzekł: Owom ja! Ktoś ty jest, synu mój?
Jakọbu wọlé lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi.” Baba rẹ sì dáhùn pé, “Èmi nìyí, ìwọ ta ni, ọmọ mi?”
19 I rzekł Jakób do ojca swego: Jam jest Ezaw, pierworodny twój. Uczyniłem, jakoś mi rozkazał; wstań proszę, siądź, a jedz z obłowu mego, aby mi błogosławiła dusza twoja.
Jakọbu sì fèsì pé, “Èmi ni Esau àkọ́bí rẹ, èmi ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ fún mi, jọ̀wọ́ dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó mi tí mo ti sè, kí o ba à le súre fún mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.”
20 I rzekł Izaak do syna swego: Cóż to jest? Prędkoś to znalazł, synu mój? a on odpowiedział: Sposobił to Pan Bóg twój, że mi się nagodziło.
Isaaki tún béèrè pé, “Ọmọ mi, báwo ni ó ṣe tètè yá ọ bẹ́ẹ̀?” Jakọbu sì tún dáhùn pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ló fún mi pa.”
21 Zatem Izaak rzekł do Jakóba: Przystąp sam, abym cię pomacał, synu mój, jeźliś ty jest syn mój Ezaw, czyli nie.
Nígbà náà ni Isaaki wí fún Jakọbu pé, “Súnmọ́ mi, kí n le è fọwọ́ kàn ọ́, kí n lè mọ̀ bóyá Esau ọmọ mi ni nítòótọ́ tàbí òun kọ́.”
22 Tedy przystąpił Jakób do Izaaka, ojca swego, który pomacawszy go, rzekł: Głos jest głos Jakóbów, ale ręce Ezawowe.
Jakọbu sì súnmọ́ Isaaki baba rẹ̀. Isaaki sì fọwọ́ kàn án, ó sì wí pé, “Ohùn ni ohùn Jakọbu; ṣùgbọ́n ọwọ́ ni ọwọ́ Esau.”
23 I nie poznał go; albowiem były ręce jego jako ręce Ezawa, brata jego, kosmate; i błogosławił mu.
Kò sì dá Jakọbu mọ̀ nítorí ọwọ́ rẹ̀ ní irun bí i ti Esau arákùnrin rẹ, nítorí náà, ó súre fún un
24 I rzekł: Tyżeś jest syn mój Ezaw? a on odpowiedział: Ja.
ó sì bi í léèrè pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni Esau ọmọ mi ni tòótọ́?” Jakọbu sì dáhùn pé, “Èmi ni.”
25 Zatem rzekł: Podajże mi, żebym jadł z obłowu syna mego, abyć błogosławiła dusza moja. Tedy mu podał, i jadł. Przyniósł mu też wina, i pił.
Nígbà náà ni Isaaki wí pé, “Gbé ẹran igbó náà súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi, kí èmi kí ó jẹ ẹ́, kí èmi sì súre fún ọ láti inú ọkàn mi wá.” Jakọbu sì gbé e wá ó sì jẹ ẹ́, ó sì tún fún un ní wáìnì, ó sì mú un pẹ̀lú.
26 I rzekł mu Izaak, ojciec jego: Przystąpże teraz a pocałuj mię, synu mój.
Nígbà náà ni Isaaki baba rẹ̀ wí fun un pé, “Súnmọ́ mi, ọmọ mi, kí o sì fẹnukò mí ní ẹnu.”
27 Tedy przystąpiwszy pocałował go, a skoro poczuł wonność szat jego, błogosławił mu, mówiąc: Oto wonność syna mego, jako wonność pola, któremu błogosławił Pan.
Ó sì súnmọ́ ọn, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. Nígbà tí Isaaki gbọ́ òórùn aṣọ rẹ̀, ó súre fún un ó wí pé, “Wò ó òórùn ọmọ mi dàbí òórùn oko tí Olúwa ti bùkún.
28 Niechajżeć da Bóg z rosy niebieskiej, i z tłustości ziemskiej, i obfitość zboża i wina.
Kí Ọlọ́run kí ó fún ọ nínú ìrì ọ̀run àti nínú ọ̀rá ilẹ̀ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà àti wáìnì tuntun.
29 Niechaj ci służą ludzie, a niech ci się kłaniają narodowie. Bądź panem braci twojej, a niech ci się kłaniają synowie matki twojej; którzy by cię przeklinali, niech będą przeklętymi, a którzy by cię błogosławili, niech będą błogosławionymi.
Kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó máa sìn ọ́, kí àwọn ènìyàn sì máa tẹríba fún ọ, máa ṣe olórí àwọn arákùnrin rẹ, kí àwọn iyèkan rẹ sì máa wólẹ̀ fún ọ Fífibú ni àwọn ẹni tó fi ọ́ bú, ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ó súre fún ọ.”
30 I stało się, gdy przestał Izaak błogosławić Jakóbowi, i ledwie Jakób odszedł od oblicza Izaaka, ojca swego, tedy Ezaw brat jego, przyszedł z łowu swego.
Bí Isaaki ti súre tán tí Jakọbu ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde kúrò ní ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ni Esau ti oko ọdẹ dé.
31 Który nagotowawszy potrawy smaczne, przyniósł je ojcu swemu, i mówił do ojca swego: Wstańże ojcze mój, a jedz z obłowu syna twego, aby mi błogosławiła dusza twoja.
Òun pẹ̀lú ṣe ẹran dídùn, ó sì gbé e tọ baba rẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Baba mi, dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó tí mo ti ṣè, kí o sì súre fún mi.”
32 Tedy mu rzekł Izaak, ojciec jego: Któżeś ty? A on rzekł: Jam jest syn twój, pierworodny twój, Ezaw.
Isaaki baba rẹ̀ sì bi í wí pé, “Ìwọ ta ni?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi Esau, àkọ́bí rẹ ni.”
33 I zląkł się Izaak zlęknieniem bardzo wielkiem, i rzekł: Któż to, a gdzie jest ten, co ułowił zwierzynę, i przyniósł mi? i jadłem ze wszystkiego, pierwej, niżeś ty przyszedł, i błogosławiłem mu, i będzie błogosławionym.
Nígbà náà ni Isaaki wárìrì gidigidi, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni náà, tí ó ti pa ẹran igbó tí ó sì ti gbe wá fún mi, tí mo sì ti jẹ ẹ́ kí ó tó dé? Mo sì ti súre fún un, sì wò ó dájúdájú a ó sì bùkún un!”
34 A usłyszawszy Ezaw słowa ojca swego, zawołał głosem wielkiem, i był żałością wielką zjęty, i rzekł ojcu swemu: Błogosławże też i mnie, ojcze mój.
Nígbà tí Esau gbọ́ ọ̀rọ̀ baba rẹ̀, ó ké, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún kíkorò, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Baba mi súre fún èmi náà, àní fún èmi náà pẹ̀lú.”
35 A on mu rzekł: Przyszedł brat twój chytrze, i wziął błogosławieństwo twoje.
Ṣùgbọ́n Isaaki wí pé, “Àbúrò rẹ ti fi ẹ̀tàn wá, ó sì ti gba ìbùkún rẹ lọ.”
36 Tedy Ezaw rzekł: Słusznieć nazwano imię jego Jakób, podszedł mię bowiem już dwa kroć; pierworodztwo moje wziął, a teraz oto odniósł błogosławieństwo moje. I rzekł: Toś mi nie zachował błogosławieństwa?
Esau sì wí pé, “Lásán ni a pe orúkọ rẹ̀ ní Jakọbu bí? Ní ìgbà méjì yìí ni ó ti tàn mí jẹ: ní àkọ́kọ́, ó gba ogún ìbí mi, nísinsin yìí, ó tún gba ìbùkún mi!” O sì béèrè pé, “Ṣe o kò wá fi ìre kankan sílẹ̀ fun mi ni?”
37 Odpowiedział Izaak, i rzekł do Ezawa: Otom go panem postanowił nad tobą, i wszystkich braci jego dałem mu za sługi, i zbożem, i winem opatrzyłem go; a tobie cóż teraz mam uczynić, synu mój?
Isaaki sì dá Esau lóhùn pé, “Mo ti fi ṣe olórí rẹ àti àwọn ìbátan rẹ ni mo fi ṣe ìránṣẹ́ fún un, àti ọkà àti wáìnì ni mo ti fi lé e lọ́wọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀, kí ni ó tún kù tí ǹ bá tún fún ọ báyìí ọmọ mi?”
38 I rzekł Ezaw do ojca swego: Izali tylko jedno błogosławieństwo masz, ojcze mój? Błogosławże i mnie; i jamci syn twój, ojcze mój. I podniósł Ezaw głos swój, a płakał.
Esau sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Ṣe ìre kan ṣoṣo ni ìwọ ní lẹ́nu ni baba mi? Súre fún èmi náà, baba mi.” Esau sì sọkún kíkankíkan.
39 I odpowiedział Izaak, ojciec jego, i rzekł mu: Oto w tłustości ziemi będzie mieszkanie twoje, i w rosie niebieskiej z góry.
Isaaki baba rẹ̀ sì dá a lóhùn pé, “Ibùjókòó rẹ yóò jìnnà sí ọ̀rá ilẹ̀, àti sí ibi ìrì ọ̀run láti òkè wá.
40 A z miecza twego żyć będziesz, i bratu twemu będziesz służył; ale stanie się, że i ty panować będziesz, i zrzucisz jarzmo jego z szyi twojej.
Nípa idà rẹ ni ìwọ yóò máa gbé, ìwọ yóò sì máa sin àbúrò rẹ, ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn, nígbà tí ìwọ bá di alágbára ìwọ yóò já àjàgà rẹ̀ kúrò lọ́rùn rẹ.”
41 Przetoż nienawidził Ezaw Jakóba dla błogosławieństwa, którem mu błogosławił ojciec jego; i mówił Ezaw w sercu swem: Przybliżają się dni żałoby ojca mego, a zabiję Jakóba, brata mego.
Esau sì kórìíra Jakọbu nítorí ìre tí baba rẹ̀ sú fún un, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “Baba mi sá à ti fẹ́rẹ kú, nígbà náà ni èmi ó pa Jakọbu, arákùnrin mi.”
42 I oznajmiono Rebece słowa Ezawa, syna jej starszego, która posławszy, wezwała Jakóba, syna swego młodszego, i rzekła do niego: Oto Ezaw, brat twój, cieszy się tem, iż cię zabije.
Nígbà tí Rebeka sì gbọ́ ohun tí Esau àkọ́bí rẹ̀ wí, ó sì ránṣẹ́ sí Jakọbu, ó sì wí fun un pé, “Esau ẹ̀gbọ́n rẹ ń tu ara rẹ̀ nínú pẹ̀lú èrò à ti pa ọ́.
43 Przetoż teraz, synu mój, usłuchaj głosu mego, a wstawszy, uciecz do Labana, brata mego, do Haranu,
Nítorí náà ọmọ mi, ṣe ohun tí èmi yóò sọ fún ọ, sálọ sọ́dọ̀ Labani ẹ̀gbọ́n mi ní Harani.
44 I pomieszkaj z nim przez jaki czas, aż ucichnie gniew brata twego,
Jókòó sí ibẹ̀ títí di ìgbà tí ìbínú ẹ̀gbọ́n rẹ yóò fi rọ̀.
45 Aż się odwróci zapalczywość brata twego od ciebie, i zapomni tego, coś mu uczynił; potem ja poślę, a wezmę stamtąd; bo czemuż mam was obydwóch postradać jednego dnia?
Nígbà tí ẹ̀gbọ́n rẹ kò bá bínú sí ọ mọ́, tí ó sì ti gbàgbé ohun tí ìwọ ṣe sí i, èmí ó ránṣẹ́ sí ọ láti padà wá. Èéṣe tí èmi ó fi pàdánù ẹ̀yin méjèèjì ní ọjọ́ kan náà?”
46 I rzekła Rebeka do Izaaka: Obmierzł mi żywot mój dla córek Hetejskich; jeźliże i Jakób weźmie sobie żonę z córek Hetejskich, jakie są córki ziemi tej, cóż mi po żywocie?
Nígbà náà ni Rebeka wí fún Isaaki pé, “Ayé sì sú mi nítorí àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí. Bí Jakọbu bá fẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí, ó kúkú sàn kí n má wà láààyè.”

< Rodzaju 27 >