< Rodzaju 26 >
1 Potem był głód na ziemi, po onym głodzie pierwszym, który był za dni Abrahamowych; I poszedł Izaak do Abimelecha, do króla Filistyńskiego do Gerar.
Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, yàtọ̀ fún èyí tí ó mú ní ìgbà ayé Abrahamu, Isaaki sì lọ sọ́dọ̀ Abimeleki ọba àwọn Filistini ni Gerari.
2 Bo mu się był ukazał Pan i mówił: Nie zstępuj do Egiptu, ale mieszkaj w ziemi, o której Ja powiem tobie.
Olúwa sì fi ara han Isaaki, ó sì wí pé, “Má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, jókòó ní ilẹ̀ tí èmi ó fún ọ.
3 Bądźże gościem w tej ziemi, a Ja będę z tobą, i będęć błogosławił; albowiem tobie i nasieniu twemu dam te wszystkie krainy, i utwierdzę przysięgę, którąm przysiągł Abrahamowi, ojcu twemu.
Máa ṣe àtìpó ní ilẹ̀ yìí fún ìgbà díẹ̀, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùkún fún ọ. Nítorí ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ni èmi yóò fi gbogbo àwọn ilẹ̀ wọ̀nyí fún, èmi yóò sì fi ìdí ìbúra tí mo ṣe fún Abrahamu baba rẹ múlẹ̀.
4 I rozmnożę nasienie twoje jako gwiazdy niebieskie, a dam nasieniu twemu wszystkie te krainy: A będą błogosławione w nasieniu twojem wszystkie narody ziemi.
Èmi yóò sọ ìran rẹ di púpọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, èmi yóò sì fi gbogbo ilẹ̀ yìí fún irú àwọn ọmọ rẹ, àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé,
5 Przeto, iż Abraham był posłuszny głosowi mojemu, a strzegł postanowienia mego, przykazań moich, ustaw moich i praw moich.
nítorí tí Abrahamu gba ohùn mi gbọ́, ó sì pa gbogbo ìkìlọ̀, àṣẹ, ìlànà àti òfin mi mọ́.”
6 Tedy Izaak mieszkał w Gerar.
Nítorí náà Isaaki jókòó ní Gerari.
7 I pytali się mężowie onego miejsca o żonie jego; a on powiedział: Siostra to moja; bo się bał mówić: Żona to moja; by go snać nie zabili mężowie miejsca tego dla Rebeki, iż była piękna na wejrzeniu.
Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà bi í léèrè ní ti aya rẹ̀, ó sì wí pé, “Arábìnrin mi ní í ṣe,” nítorí tí ó bẹ̀rù láti jẹ́wọ́ wí pé, “Aya mi ni.” Ó ń rò wí pé, “Kí àwọn ọkùnrin ibẹ̀ náà má ba à pa mí nítorí Rebeka, nítorí tí òun ní ẹwà púpọ̀.”
8 I stało się, gdy tam mieszkał przez nie mało dni, że wyglądał Abimelech, król Filistyński, oknem, i ujrzał, że Izaak żartował z Rebeką, żoną swą.
Nígbà tí Isaaki sì ti wà níbẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, Abimeleki ọba Filistini yọjú lójú fèrèsé, ó sì rí Isaaki ń bá Rebeka aya rẹ̀ tage.
9 Tedy przyzwał Abimelech do siebie Izaaka, i rzekł: Prawdziwieć to żona twoja; czemużeś powiadał, siostra to moja? I odpowiedział mu Izaak: Iżem u siebie mówił: Bym snać nie umarł dla niej.
Nígbà náà ni Abimeleki ránṣẹ́ pe Isaaki ó sì wí fun pé, “Nítòótọ́, aya rẹ ni obìnrin yìí í ṣe, èéṣe tí ìwọ fi wí fún wa pé arábìnrin mi ni?” Isaaki sì fèsì pé, “Nítorí mo rò pé mo le pàdánù ẹ̀mí mi nítorí rẹ̀.”
10 I rzekł Abimelech: Cóżeś nam to uczynił? bez mała ktokolwiek z ludu nie spał z żoną twoją: i przywiódłbyś był na nas grzech.
Nígbà náà ni Abimeleki dáhùn pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá ti bá a lòpọ̀ ń kọ́? Ìwọ ìbá wá mú ẹ̀bi wá sórí wa.”
11 Rozkazał tedy Abimelech wszystkiemu ludowi mówiąc: Kto by się dotknął męża tego, albo żony jego, śmiercią umrze.
Nígbà náà ni Abimeleki pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin yìí tàbí aya rẹ̀ yóò jẹ̀bi ikú.”
12 Tedy siał Izaak w onej ziemi, i zebrał roku onego sto korcy, albowiem błogosławił mu Pan.
Ní ọdún náà, Isaaki gbin ohun ọ̀gbìn sí ilẹ̀ náà, ó sì kórè rẹ̀ ní ìlọ́po ọgọ́rùn-ún ọdún ni ọdún kan náà, nítorí Olúwa bùkún un.
13 I zbogacił się on mąż, a im dalej, tem więcej wzmagał się, aż urósł wielce.
Ọkùnrin náà sì di ọlọ́rọ̀ púpọ̀, ọrọ̀ rẹ̀ sì ń pọ̀ si, títí ó fi di ènìyàn ńlá.
14 I miał stada owiec, i stada wołów, i czeladzi dosyć; przetoż mu zajrzeli Filistyńczycy.
Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran àti àwọn ìránṣẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Filistini ń ṣe ìlara rẹ̀.
15 I wszystkie studnie, które byli wykopali słudzy ojca jego, za dni Abrahama, ojca jego, zasypali Filistyńczycy, i napełnili je ziemią.
Nítorí náà àwọn ará Filistini ru erùpẹ̀ di gbogbo kànga tí àwọn ìránṣẹ́ Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́.
16 I rzekł Abimelech do Izaaka: Odejdź od nas, albowiemeś daleko możniejszy niż my.
Nígbà náà ni Abimeleki wí fún Isaaki pé, “Jáde kúrò ní ilẹ̀ wa, nítorí tí ìwọ ti di alágbára púpọ̀ jù wá lọ.”
17 I odszedł stamtąd Izaak, i rozbił namioty w dolinie Gerar, i mieszkał tam.
Isaaki sì ṣí kúrò níbẹ̀, ó sì pàgọ́ sí àfonífojì Gerari ó sì ń gbé ibẹ̀.
18 I kopał zasię Izaak studnie wód, które byli wykopali za dni Abrahama, ojca jego, co je byli zasypali Filistyni po śmierci Abrahamowej, i zwał je temiż imiony, któremi je był nazwał ojciec jego.
Isaaki sì ṣe àtúngbẹ́ àwọn kànga tí Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́ nígbà ayé rẹ̀, èyí tí àwọn Filistini ti dí lẹ́yìn ikú Abrahamu baba rẹ̀, ó sì fún wọn lórúkọ tí baba rẹ̀ ti sọ wọ́n tẹ́lẹ̀.
19 Tedy kopali słudzy Izaakowi w onej dolinie, i znaleźli tam studnią wód żywych.
Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki sì gbẹ́ kànga ní àfonífojì náà, wọ́n kan ìsun omi níbẹ̀.
20 Lecz poswarzyli się pasterze Gerarscy z pasterzami Izaakowymi, mówiąc: Nasza to woda; przeto nazwał imię studni onej, Hesek, iż się swarzyli z nim o nię.
Ṣùgbọ́n àwọn darandaran Gerari ń bá àwọn darandaran Isaaki jà sí kànga náà pé àwọn ni àwọn ni í. Nítorí náà ni ó fi pe orúkọ kànga náà ní Eseki, nítorí pé wọ́n bá a jà sí kànga náà.
21 Potem wykopali drugą studnią, i swarzyli się też o nię; dla tegoż nazwał imię jej Sydna.
Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki tún gbẹ́ kànga mìíràn, wọ́n sì tún jà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Sitna.
22 Zatem przeniósł się stamtąd, i wykopał drugą studnią o którą żadnego sporu nie było; i nazwał imię jej Rechobot, i mówił: Oto, teraz rozszerzył nas Pan, i urośliśmy na ziemi.
Ó sì tún kúrò níbẹ̀, ó sì gbẹ́ kànga mìíràn, wọn kò sì jásí èyí rárá, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Rehoboti, ó wí pé, “Nísinsin yìí, Olúwa ti fi ààyè gbà wá, a ó sì gbilẹ̀ si ní ilẹ̀ náà.”
23 I wstąpił stamtąd do Beerseby.
Láti ibẹ̀, ó kúrò lọ sí Beerṣeba.
24 I ukazał mu się Pan onejże nocy, mówiąc: Jam jest Bóg Abrahama, ojca twego, nie bój się, bom Ja jest z tobą; i będęć błogosławił, i rozmnożę nasienie twoje, dla Abrahama, sługi mego.
Ní òru ọjọ́ tí ó dé ibẹ̀, Olúwa sì fi ara hàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu baba rẹ. Má ṣe bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùsi fún ọ, èmi yóò sì sọ iye ìran rẹ di púpọ̀, nítorí Abrahamu ìránṣẹ́ mi.”
25 Tedy tam zbudował ołtarz, i wzywał imienia Pańskiego, i rozbił tam namiot swój, tamże też wykopali słudzy Izaakowi studnię.
Isaaki sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan níbẹ̀.
26 Abimelech potem przyjechał do niego z Gerar, i Achuzat przyjaciel jego, i Fikol, hetman wojska jego.
Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀.
27 Do których rzekł Izaak: Przeczżeście przyjechali do mnie, gdyż wy mnie macie w nienawiści, i wypędziliście mię od siebie?
Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”
28 A oni odpowiedzieli: Obaczyliśmy to dobrze, że Pan jest z tobą, i rzekliśmy: Uczyńmy teraz przysięgę między sobą, między nami i między tobą, i postanowimy przymierze z tobą;
Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn
29 Abyś nam nic złego nie czynił, jakośmy się też ciebie nie tykali; i jakośmyć tylko dobrze czynili, a puściliśmy cię w pokoju; a tyś teraz błogosławiony od Pana.
pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
30 Tedy im sprawił ucztę, a jedli i pili.
Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
31 Potem wstawszy bardzo rano przysięgli jeden drugiemu; i wyprowadził je Izaak, i odeszli od niego w pokoju.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.
32 I stało się onegoż dnia, przyszli słudzy Izaakowi, i powiedzieli mu o studni, którą wykopali, mówiąc mu: Znaleźliśmy wodę.
Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.
33 I nazwał ją Syba; dlategoż imię miasta onego jest nazwane Beerseba aż do dnia dzisiejszego.
Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba, títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.
34 Potem Ezaw mając czterdzieści lat, pojął sobie za żonę Judytę, córkę Beery Hetejczyka, i Basemat, córkę Elona, Hetejczyka.
Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti.
35 Które się bardzo naprzykrzały Izaakowi i Rebece.
Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.