< Rodzaju 21 >
1 A Pan nawiedził Sarę, jako był rzekł: i uczynił Pan Sarze, jako był powiedział.
Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
2 Bo poczęła i porodziła Sara Abrahamowi syna w starości jego, na tenże czas, który mu był Bóg przepowiedział.
Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
3 I nazwał Abraham imię syna swego, który mu się urodził, którego mu urodziła Sara, Izaak.
Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
4 I obrzezał Abraham Izaaka, syna swego, gdy był w ośmiu dniach, jako mu był rozkazał Bóg.
Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
5 A było Abrahamowi sto lat, gdy mu się urodził Izaak, syn jego.
Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
6 Tedy rzekła Sara: Śmiech mi uczynił Bóg; ktokolwiek usłyszy, śmiać się będzie ze mną.
Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
7 I rzekła: Któżby to był rzekł Abrahamowi, że Sara będzie karmiła piersiami syny? gdyżem urodziła syna w starości jego.
Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
8 Rosło tedy dziecię, i odstawione jest od piersi; i uczynił Abraham ucztę wielką w dzień odstawienia Izaaka.
Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
9 Potem ujrzała Sara syna Hagary, Egipczanki, przeszydzającego, którego urodziła Abrahamowi;
Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
10 I rzekła do Abrahama: Wyrzuć tę służebnicę, i syna jej; albowiem nie będzie dziedziczył syn tej służebnicy z synem mym Izaakiem.
ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
11 Ale się to bardzo nie podobało w oczach Abrahamowych, dla syna jego.
Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
12 Tedy rzekł Bóg do Abrahama: Niech to przykro nie będzie w oczach twoich z strony dziecięcia, i z strony służebnicy twojej; coćkolwiek rzecze Sara, usłuchaj głosu jej; boć w Izaaku nazwane będzie nasienie.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
13 Wszakże i syna służebnicy rozmnożę w naród, przeto iż nasieniem twojem jest.
Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
14 Wstał tedy Abraham bardzo rano, a wziąwszy chleb i łagiew wody, dał Hagarze; i włożywszy to na ramię jej, i z dziecięciem, odprawił ją; która poszedłszy błąkała się po puszczy Beerseba.
Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
15 A gdy nie stało wody w łagwi, porzuciła dziecię pod jednem drzewem;
Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
16 I odszedłszy usiadła przeciw niemu, tak daleko, jako na strzeleniu z łuku; bo mówiła: Nie będę patrzyła na śmierć dziecięcia; a siedząc przeciw niemu, podniosła głos swój, i płakała.
Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
17 Tedy usłyszał Bóg głos dziecięcy, i zawołał Anioł Boży na Hagarę z nieba, i rzekł jej: Cóżci Hagaro? nie bój się, boć usłyszał Bóg głos dziecięcy z miejsca, na którem jest.
Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
18 Wstań, weźmij dziecię, a ujmij je ręką swoją: bo w naród wielki rozmnożę je.
Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
19 Otworzył tedy Bóg oczy jej, że ujrzała źródło wody; a szedłszy napełniła łagiew wodą, i dała pić dziecięciu.
Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
20 I był Bóg z onem dziecięciem, Które urosło, i mieszkało na puszczy, był z niego strzelec dobry z łuku.
Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
21 A mieszkał na puszczy Faran; i wzięła mu matka jego żonę z ziemi Egipskiej.
Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
22 I stało się onegoż czasu, że rzekł Abimelech, i Fikol, hetman wojska jego, do Abrahama mówiąc: Bóg z tobą we wszystkiem, co ty czynisz.
Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
23 A tak teraz, przysiąż mi przez Boga, że mię w niczem podchodzić nie będziesz, ani syna mego, ani wnuka mego; ale według miłosierdzia, którem uczynił z tobą, uczynisz ze mną, i z ziemią, w którejś był przychodniem.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
24 Tedy odpowiedział Abraham: Ja przysięgnę.
Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
25 I przymawiał Abraham Abimelechowi o studnią wody, którą mu byli gwałtem odjęli słudzy Abimelechowi.
Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
26 I rzekł Abimelech: Nie wiem kto by to uczynił, nawet i tyś mi nie oznajmił, i jam nie słyszał o tem dopiero dziś.
Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
27 Nabrał tedy Abraham owiec i wołów, i dał Abimelechowi, i uczynili oba przymierze.
Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
28 I postawił Abraham siedmioro owiec z stada osobno.
Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
29 Tedy Abimelech rzekł do Abrahama: Na cóż to siedmioro owiec, któreś postawił osobno?
Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
30 A on odpowiedział: Iż te siedem owiec weźmiesz z rąk moich, aby mi były na świadectwo, żem wykopał tę studnię.
Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
31 Dlatego nazwano miejsce ono Beerseba; albowiem tam obaj przysięgli.
Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
32 A tak zawarli przymierze w Beerseba. Potem wstawszy Abimelech, i Fikol, hetman wojska jego, wrócili się do ziemi Filistyńskiej.
Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
33 I nasadził Abraham drzewa w Beerseba, i wzywał tam imienia Pana Boga wiecznego.
Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
34 I mieszkał Abraham w ziemi Filistyńskiej przez wiele dni.
Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.