< Rodzaju 20 >

1 I ruszył się stamtąd Abraham do ziemi południowej, a mieszkał między Kades i między Sur, i był gościem w Gerar.
Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
2 Tam powiedział Abraham o Sarze, żonie swej: Siostra moja jest; przetoż posłał Abimelech, król Gerary, i wziął Sarę.
Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
3 Ale Bóg przyszedł do Abimelecha we śnie w nocy, i rzekł mu: Oto ty umrzesz dla niewiasty, którąś wziął, bo ona ma męża.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
4 Ale Abimelech nie przybliżył się był do niej, i rzekł: Panie, izali też lud sprawiedliwy zabijesz?
Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
5 Azaż mi on sam nie powiadał, siostra moja jest? a ona też sama nie mówiła, brat mój jest? w prostości serca mojego, i w niewinności rąk moich uczyniłem to.
Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
6 Tedy mu rzekł Bóg we śnie: Wiemci ja, żeś to w prostości serca swego uczynił; i dla tegom cię zawściągnął, abyś nie zgrzeszył przeciwko mnie, i nie dopuściłem ci, abyś się jej dotknął.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
7 Teraz tedy wróć żonę mężowi, bo prorokiem jest; i będzie się modlił za cię, a będziesz żył; a jeźliż jej nie wrócisz, wiedz, iż śmiercią umrzesz, ty, i wszystko, co twego jest.
Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
8 Tedy Abimelech wstawszy rano, zwołał wszystkich sług swoich, i opowiedział im to wszystko; co usłyszawszy, polękali się mężowie oni bardzo.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
9 Potem wezwał Abimelech Abrahama, i rzekł mu: Coś nam uczynił? a com zgrzeszył przeciwko tobie? iżeś przywiódł na mię i na królestwo moje grzech wielki? uczyniłeś mi, czegoś czynić nie miał.
Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
10 I rzekł po wtóre Abimelech do Abrahama: Cóżeś upatrywał, żeś tę rzecz uczynił?
Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
11 I odpowiedział Abraham: Myśliłem sobie: Podobno nie masz bojaźni Bożej na tem miejscu, i zabiją mię dla żony mojej.
Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
12 A wszakże prawdziwie siostra moja jest, córka ojca mego, choć nie córka matki mojej; pojąłem ją za żonę.
Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
13 I stało się, gdy mię wyprawił Bóg na pielgrzymowanie z domu ojca mego, żem rzekł do niej: To miłosierdzie twoje będzie, które uczynisz ze mną: Na każdem miejscu, do którego przyjdziemy, powiesz o mnie: Brat to mój jest.
Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
14 Tedy nabrawszy Abimelech owiec, i wołów, i sług, i służebnic, dał Abrahamowi, i wrócił mu Sarę, żonę jego.
Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
15 I rzekł Abimelech: Oto ziemia moja przed obliczem twojem; gdzieć się kolwiek podoba, mieszkaj.
Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
16 A do Sary rzekł: Otom dał tysiąc srebrników bratu twemu, onci jest zasłoną oczu twoich u wszystkich, którzy są z tobą; a tem wszystkiem Sara wyuczona była.
Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
17 I modlił się Abraham Bogu, a uzdrowił Bóg Abimelecha, i żonę jego, i służebnice jego, i rodziły.
Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
18 Zawarł bowiem był Pan cale każdy żywot domu Abimelechowego dla Sary, żony Abrahamowej.
nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.

< Rodzaju 20 >