< Rodzaju 18 >
1 Potem ukazał mu się Pan w równinie Mamre, a on siedział we drzwiach namiotu swego, gdy był najgorętszy dzień.
Olúwa sì farahan Abrahamu nítòsí àwọn igi ńlá Mamre, bí ó ti jókòó ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀, nígbà tí ọjọ́-kanrí tí oòrùn sì mú.
2 A podniósłszy oczy swe, obaczył, a oto trzej mężowie stanęli przeciw niemu; i ujrzawszy je, wybieżał przeciwko nim ze drzwi namiotu, i pokłonił się do ziemi.
Abrahamu gbójú sókè, ó sì rí àwọn ọkùnrin mẹ́ta tí wọn dúró nítòsí rẹ̀. Nígbà tí ó rí wọn, ó sáré láti lọ pàdé wọn, ó sì tẹríba bí ó ti ń kí wọn.
3 I rzekł: Panie mój, jeźlim teraz znalazł łaskę w oczach twoich, nie mijaj, proszę, sługi swego.
Ó wí pé, “Bí mo bá rí ojúrere yín Olúwa mi, ẹ má ṣe lọ láì yà sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ yín.
4 Przyniosą trochę wody, a umyjecie nogi wasze, i odpoczniecie pod drzewem.
Ẹ jẹ́ kí a bu omi díẹ̀ wá kí ẹ̀yin kí ó wẹ ẹsẹ̀ yín, kí ẹ sì sinmi lábẹ́ igi níhìn-ín.
5 I przyniosą kęs chleba, a posilicie serce wasze; potem odejdziecie, dla tegoście bowiem przyszli do mnie sługi swego. Tedy rzekli: Tak uczyń, jakoś powiedział.
Ẹ jẹ́ kí n wá oúnjẹ wá fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ, kí ara sì tù yín, kí ẹ si tẹ̀síwájú ní ọ̀nà yín, nígbà tí ẹ ti yà ní ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ yín.” Wọn sì wí pé “Ó dára.”
6 I pospieszył się Abraham do namiotu do Sary, i rzekł: Spiesz się: rozczyń trzy miarki mąki światłej, a uczyń podpłomyków.
Abrahamu sì yára tọ Sara aya rẹ̀ lọ nínú àgọ́, ó wí pé, “Tètè mú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dáradára mẹ́ta kí o sì pò ó pọ̀, kí o sì ṣe oúnjẹ.”
7 Abraham zaś szedł do trzody, i wziął cielę młode i wyborne, i dał je słudze, który się pospieszył, i nagotował je.
Abrahamu sì tún sáré lọ sí ibi agbo ẹran, ó sì mú ọmọ màlúù kan fún ìránṣẹ́ rẹ̀, ìránṣẹ́ náà sì tètè ṣè é.
8 Wziął też masła i mleka, i cielę, które był nagotował, i postawił przed nie, a sam stał przy nich pod drzewem; i jedli.
Ó sì mú wàrà àti mílíìkì àti màlúù tí ó ti pèsè, ó sì gbé síwájú wọn. Ó sì dúró nítòsí wọn lábẹ́ igi bí wọn ti ń jẹ ẹ́.
9 I rzekli do niego: Gdzie jest Sara, żona twoja? a on odpowiedział: Oto jest w namiocie.
Wọn béèrè pé, “Sara aya rẹ ń kọ́?” Ó dáhùn pé, “Ó wà nínú àgọ́.”
10 Tedy rzekł Pan: Wrócę się pewnie do ciebie o tymże czasie w rok, a oto, będzie miała syna Sara, żona twoja; a Sara słuchała u drzwi namiotu, które były za nim.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún un pé, “Èmi yóò sì tún padà tọ̀ ọ́ wá nítòótọ́ ní ìwòyí àmọ́dún; Sara aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.” Sara sì ń dẹtí gbọ́ láti ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tí ó wà lẹ́yìn ọkùnrin náà.
11 A Abraham i Sara byli starzy, i zeszli w leciech; i przestało bywać Sarze według zwyczaju niewiast.
Abrahamu àti Sara sì ti di arúgbó, Sara sì ti kọjá àsìkò ìbímọ.
12 I roześmiała się Sara sama w sobie, mówiąc: Gdym się zestarzała, rozkoszy zażywać będę; i pan mój zestarzał się.
Nítorí náà, Sara rẹ́rìn-ín nínú ara rẹ̀ bí ó ti ń rò ó lọ́kàn rẹ̀ pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo ti di arúgbó tán tí olúwa mi pẹ̀lú sì ti gbó jọ̀kújọ̀kú, èmi yóò ha tún lè bímọ?”
13 Zatem rzekł Pan do Abrahama: Czemu się rozśmiała Sara, mówiąc: Zaż prawdziwie porodzę, gdym się zestarzała? Izali jest co trudnego u Pana?
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abrahamu pé, “Kín ló dé tí Sara fi rẹ́rìn-ín tí ó sì wí pé, ‘Èmi yóò ha bímọ nítòótọ́, nígbà tí mo di ẹni ogbó tán?’
14 O tymże czasie wrócę do ciebie roku przyszłego, a Sara będzie miała syna.
Ǹjẹ́ ohunkóhun wà tí ó ṣòro jù fún Olúwa? Èmi ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìwòyí àmọ́dún, Sara yóò sì bí ọmọkùnrin.”
15 I zaprzała się Sara, mówiąc: Nie śmiałam się; bo się bała. A Pan rzekł: Nie mów tak; boś się śmiała.
Ẹ̀rù sì ba Sara, ó sì sẹ́ pé òun kò rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Dájúdájú ìwọ rẹ́rìn-ín.”
16 Potem wstali stamtąd mężowie oni, i obrócili się ku Sodomie; a Abraham szedł z nimi wyprowadzając je.
Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, wọn kọjú sí ọ̀nà Sodomu, Abrahamu sì sìn wọ́n dé ọ̀nà.
17 Tedy rzekł Pan: Izali ja zataję przed Abrahamem, co mam uczynić?
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ǹjẹ́ èmi yóò ha pa ohun tí mo fẹ́ ṣe mọ́ fún Abrahamu bí?
18 Ponieważ Abraham pewnie rozmnożon będzie w lud wielki i możny, a w nim będą ubłogosławione wszystkie narody ziemi.
Dájúdájú Abrahamu yóò sá à di orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára, àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni a ó bùkún fún nípasẹ̀ rẹ̀.
19 Znam go bowiem; przetoż przykaże synom swoim, i domowi swemu po sobie, aby strzegli drogi Pańskiej, i czynili sprawiedliwość i sąd; aby przywiódł Pan na Abrahama, co mu powiedział.
Nítorí tí èmi ti yàn án láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ará ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, láti máa pa ọ̀nà Olúwa mọ nípa ṣíṣe olóòtítọ́ àti olódodo: kí Olúwa le è mú ìlérí rẹ̀ fún Abrahamu ṣẹ.”
20 Rzekł tedy Pan: Krzyk Sodomy i Gomorry, iż się rozmnożył grzech ich, iż bardzo ociężał;
Olúwa sì wí pé, igbe Sodomu àti Gomorra pọ̀ púpọ̀ àti pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn burú jọjọ.
21 Zstąpię teraz, a obaczę, jeźli się według krzyku tego, który mię doszedł, do końca sprawują; a jeźliż nie, abym się wżdy dowiedział.
“Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ síbẹ̀ láti ṣe ìwádìí igbe tí ó dé sí etí ìgbọ́ mi nípa wọn, kí èmi sì mọ òtítọ́ tí ó wà níbẹ̀.”
22 I obrócili się stamtąd mężowie, i poszli do Sodomy; lecz Abraham jeszcze stał przed Panem.
Àwọn ọkùnrin náà yí padà, wọ́n sì ń lọ sí ìhà Sodomu. Ṣùgbọ́n Abrahamu dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
23 I przystąpił Abraham, i rzekł: Izali też zatracisz sprawiedliwego z niezbożnym?
Nígbà náà ni Abrahamu súnmọ́ ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì wí pé, “Ìwọ yóò ha pa olódodo ènìyàn àti ènìyàn búburú run papọ̀ bí?”
24 Jeźli snać będzie pięćdziesiąt sprawiedliwych w tem mieście, izali je wytracisz, a nie przepuścisz miejscu temu dla pięćdziesiąt sprawiedliwych, którzy w niem są?
“Bí ó bá ṣe pé ìwọ rí àádọ́ta olódodo nínú ìlú náà, ìwọ yóò ha run ún, ìwọ kì yóò ha dá ìlú náà sí nítorí àwọn àádọ́ta olódodo tí ó wà nínú rẹ̀ náà?
25 Niech to nie będzie u ciebie, abyś uczynić miał rzecz takową, i zabił sprawiedliwego z niezbożnym, a żeby był sprawiedliwy, jako niezbożny. Niech to nie będzie u ciebie. Izali Sędzia wszystkiej ziemi nie uczyni sprawiedliwości?
Kò jẹ́ rí bẹ́ẹ̀! Dájúdájú ìwọ kì yóò ṣe ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀, láti pa olódodo pẹ̀lú àwọn ènìyàn rere àti àwọn ènìyàn búburú. Dájúdájú, ìwọ kì yóò ṣe èyí tí ó tọ́ bi?”
26 Tedy rzekł Pan: Jeźli znajdę w Sodomie pięćdziesiąt sprawiedliwych w samem mieście, odpuszczę wszystkiemu miejscu dla nich.
Olúwa wí pé, “Bí mo bá rí àádọ́ta olódodo ní ìlú Sodomu, èmi yóò dá ìlú náà sí nítorí tiwọn.”
27 A odpowiadając Abraham rzekł: Otom teraz zaczął mówić do Pana mego, aczem ja proch i popiół.
Abrahamu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Wò ó nísinsin yìí, níwọ̀n bí èmi ti ní ìgboyà láti bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa, èmi ẹni tí í ṣe erùpẹ̀ àti eérú,
28 A jeźliby nie stawało do pięćdziesięciu sprawiedliwych, pięciu, izali wytracisz dla tych pięciu wszystko miasto? I rzekł Pan: Nie wytracę, jeźli tam znajdę czterdziestu i pięciu.
bí ó bá ṣe pe olódodo márùndínláàádọ́ta ni ó wà nínú ìlú, ìwọ yóò ha pa ìlú náà run nítorí ènìyàn márùn-ún bí?” Olúwa dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo márùndínláàádọ́ta nínú rẹ̀.”
29 Na to jeszcze mówiąc do niego Abraham rzekł: A jeźliby się ich tam znalazło czterdzieści? i odpowiedział: Nie uczynię nic dla tych czterdziestu.
Òun sì tún wí lẹ́ẹ̀kan si pé, “Bí ó bá ṣe pé ogójì ni ń kọ́?” Olúwa sì tún wí pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo ogójì nínú rẹ̀.”
30 I rzekł Abraham: Proszę niech się nie gniewa Pan mój, że jeszcze mówić będę: A jeźliby się ich tam znalazło trzydzieści? odpowiedział: Nie uczynię, jeźliż tam znajdę trzydziestu.
Abrahamu sì tún bẹ Olúwa pé, “Kí Olúwa má ṣe bínú, ṣùgbọ́n èmi yóò sọ̀rọ̀. Bí ó bá ṣe pé ọgbọ̀n ni a rí níbẹ̀ ń kọ́?” Olúwa dáhùn pé, “Bí mó bá rí ọgbọ̀n, èmi kì yóò pa ìlú run.”
31 Tedy jeszcze rzekł Abraham: Otom teraz zaczął mówić do Pana mego: A jeźliby się ich tam snać znalazło dwadzieścia? odpowiedział Pan: Nie zatracę i dla tych dwudziestu.
Abrahamu wí pé, “Níwọ́n bí mo ti ní ìgboyà láti bá Olúwa sọ̀rọ̀ báyìí, jẹ́ kí n tẹ̀síwájú. Bí o bá ṣe pé olódodo ogún péré ni ó wà nínú ìlú náà ń kọ́?” Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa á run nítorí ogún ènìyàn náà.”
32 Nad to rzekł Abraham: Proszę niech się nie gniewa Pan mój, że jeszcze raz tylko przemówię: A jeźliby się ich tam znalazło dziesięć? Tedy rzekł Pan: Nie wytracę i dla tych dziesięciu.
Abrahamu sì wí pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú Olúwa. Jẹ́ kí ń béèrè lẹ́ẹ̀kan si. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn mẹ́wàá ni ó jẹ́ olódodo ń kọ́?” Olúwa wí pé, “Nítorí ènìyàn mẹ́wàá náà, èmi kì yóò pa á run.”
33 I poszedł Pan skończywszy rozmowę z Abrahamem; a Abraham wrócił się do miejsca swego.
Olúwa sì bá tirẹ̀ lọ, nígbà tí ó bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Abrahamu sì padà sílé.