< Rodzaju 17 >
1 A gdy już było Abramowi dziewięćdziesiąt lat i dziewięć lat, ukazał się Pan Abramowi, i rzekł do niego: Jam jest Bóg Wszechmogący; chodź przed obliczem mojem, a bądź doskonały.
Ní ìgbà tí Abramu di ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùn-ún ọdún, Olúwa farahàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, máa rìn níwájú mi, kí o sì jẹ́ aláìlábùkù.
2 A uczynię przymierze moje, między mną i między tobą, i rozmnożą cię bardzo obficie.
Èmi yóò sì fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò sì sọ ọ́ di púpọ̀ gidigidi.”
3 Tedy upadł Abram na oblicze swoje, i rzekł do niego Bóg, mówiąc:
Abramu sì dojúbolẹ̀, Ọlọ́run sì wí fún un pé.
4 Jam jest, oto stanowię przymierze moje z tobą, i będziesz ojcem wielu narodów.
“Ní ti èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ nìyí. Ìwọ yóò di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.
5 I nie będzie zwane dalej imię twoje Abram; ale będzie imię twoje Abraham; albowiem ojcem wielu narodów postanowiłem cię.
A kì yóò pe orúkọ rẹ̀ ní Abramu mọ́, bí kò ṣe Abrahamu, nítorí, mo ti sọ ọ́ di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.
6 A rozmnożę cię bardzo, i rozkrzewię cię w narody, i królowie z ciebie wynijdą.
Èmi yóò mú ọ bí si lọ́pọ̀lọ́pọ̀, ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ni èmi yóò sì mú ti ara rẹ jáde wá, àwọn ọba pẹ̀lú yóò sì ti inú rẹ jáde.
7 I utwierdzę przymierze moje między mną, i między tobą, i między nasieniem twojem po tobie, w narodziech ich umową wieczną; żebym ci był Bogiem i nasieniu twemu po tobie.
Èmi yóò sì gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ láàrín tèmi tìrẹ, ní májẹ̀mú ayérayé àti láàrín irú-ọmọ rẹ ní ìran-ìran wọn, láti máa ṣe Ọlọ́run rẹ àti ti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ.
8 Dam też tobie, i nasieniu twemu po tobie ziemię, w której teraz jesteś gościem; wszystkę ziemię Chananejską w osiadłość wieczną, i będę Bogiem ich.
Gbogbo ilẹ̀ Kenaani níbi tí ìwọ ti ṣe àjèjì ni èmi yóò fi fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ láéláé. Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.”
9 Nad to rzekł Bóg Abrahamowi: Ty też przymierza mego przestrzegać będziesz, ty i nasienie twoje po tobie, w narodziech swoich.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Abrahamu pé, “Ìwọ máa pa májẹ̀mú mi mọ́, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ àti àwọn ìran tí ó ń bọ̀.
10 A toć jest przymierze moje, które zachowywać będziecie, między mną, i między wami, i między nasieniem twojem po tobie, aby był obrzezany między wami każdy mężczyzna.
Èyí ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ àti ìran rẹ lẹ́yìn rẹ, májẹ̀mú tí ẹ̀yin yóò máa pamọ́. Gbogbo ọkùnrin yín ni a gbọdọ̀ kọ ní ilà.
11 Obrzeżcie tedy ciało nieobrzezki waszej; a to będzie znakiem przymierza między mną, i między wami.
Ẹ̀yin yóò kọ ara yín ní ilà, èyí ni yóò jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín tèmi tiyín.
12 Syn ośmiu dni, będzie obrzezany między wami każdy mężczyzna w narodziech waszych, tak doma narodzony jako i kupiony za pieniądze, od jakiegożkolwiek cudzoziemca, któryby nie był z nasienia twego.
Ní gbogbo ìran tí ń bọ̀ lẹ́yìn, gbogbo ọkùnrin ni a gbọdọ̀ kọ ni ilà ní ọjọ́ kẹjọ tí a bí wọn, àti àwọn tí a bí ní ilé rẹ, tàbí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àwọn àjèjì, àwọn tí kì í ṣe ọmọ rẹ̀. Èyí yóò sì jẹ́ májẹ̀mú láéláé tí yóò wà láàrín Èmi àti irú-ọmọ rẹ.
13 Koniecznie obrzezany będzie, urodzony w domu twoim, i kupiony za pieniądze twoje; a będzie przymierze moje na ciele waszem, na przymierze wieczne.
Ìbá à ṣe ẹni tí a bí nínú ilé rẹ, tàbí ẹni tí o fi owó rà, a gbọdọ̀ kọ wọ́n ní ilà; májẹ̀mú mí lára yín yóò jẹ́ májẹ̀mú ayérayé.
14 A nie obrzezany mężczyzna, którego by nie było obrzezane ciało nieobrzezki jego, będzie wytracona dusza ona z ludu swego; albowiem zgwałcił przymierze moje.
Gbogbo ọmọkùnrin tí kò bá kọ ilà, tí a kò kọ ní ilà abẹ́, ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀, nítorí pé ó da májẹ̀mú mi.”
15 Potem rzekł Bóg do Abrahama: Sarai, żony twojej, nie będziesz zwał imienia jej Saraj, ale Sara będzie imię jej.
Ọlọ́run wí fún Abrahamu pé, “Ní ti Sarai, aya rẹ̀, ìwọ kì yóò pè é ní Sarai mọ́, bí kò ṣe Sara.
16 I będę jej błogosławił, a dam ci z niej syna; będę jej błogosławił, i będzie rozmnożona w narody, a królowie narodów z niej wynijdą.
Èmi yóò bùkún fún un, èmi yóò sì fun ọ ní ọmọkùnrin kan nípasẹ̀ rẹ̀. Èmi yóò bùkún un, yóò sì di ìyá àwọn orílẹ̀-èdè, àwọn ọba àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì ti ara rẹ̀ jáde wá.”
17 Tedy Abraham padł na oblicze swoje, i roześmiał się, a mówił w sercu swem: Zaż człowiekowi stuletniemu urodzi się syn? i azaż Sara w dziewięćdziesięciu latach porodzi?
Abrahamu sì dojúbolẹ̀, ó rẹ́rìn-ín, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “A ó ha bí ọmọ fún ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún? Sara tí í ṣe ẹni àádọ́rùn-ún ọdún yóò ha bímọ bí?”
18 I rzekł Abraham do Boga: O by tylko Ismael żył przed obliczem twojem!
Abrahamu sì wí fún Ọlọ́run pé, “Sá à jẹ́ kí Iṣmaeli kí ó wà láààyè lábẹ́ ìbùkún rẹ.”
19 I rzekł Bóg: Zaiste, Sara, żona twoja, urodzi tobie syna, i nazowiesz imię jego Izaak; i utwierdzę przymierze moje z nim, umową wieczną, i z nasieniem jego po nim.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo gbọ́, ṣùgbọ́n Sara aya rẹ̀ yóò bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isaaki, èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀ ní májẹ̀mú ayérayé àti àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
20 O Ismaela też wysłuchałem cię: oto, błogosławiłem mu, i rozrodzę go, i rozmnożę go bardzo wielce. Dwanaście książąt spłodzi, i rozkrzewię go w naród wielki.
Ṣùgbọ́n ní ti Iṣmaeli, mo gbọ́ ohun tí ìwọ wí, èmi yóò bùkún fún un nítòótọ́, èmi ó sì mú un bí sí i, yóò sì pọ̀ sí i, òun yóò sì jẹ́ baba fún àwọn ọmọ ọba méjìlá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.
21 Ale przymierze moje utwierdzę z Izaakiem, którego tobie urodzi Sara, o tym czasie w roku drugim.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú Isaaki, ẹni tí Sara yóò bí fún ọ ni ìwòyí àmọ́dún.”
22 A przestawszy mówić z nim, odszedł Bóg od Abrahama.
Nígbà tí ó ti bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Ọlọ́run sì gòkè lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
23 Tedy wziął Abraham Ismaela, syna swego, i wszystkie urodzone w domu swym, i wszystkie kupione za pieniądze, każdego mężczyznę, z mężów domu Abrahamowego, i obrzezał ciało nieobrzeski ich, onegoż to dnia, jako mówił z nim Bóg.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Abrahamu mú Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ àti àwọn ẹrú tí a bí ní ilé rẹ̀ àti àwọn tí ó fi owó rà, ó sì kọ wọ́n ní ilà. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kọ gbogbo ọkùnrin tí ń bẹ ní ilé rẹ̀ ní ilà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Ọlọ́run.
24 A Abrahamowi było dziewięćdziesiąt lat i dziewięć, gdy obrzezane było ciało nieobrzeski jego.
Abrahamu jẹ́ ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùn-ún ọdún nígbà tí a kọ ọ́ ní ilà.
25 A Ismaelowi synowi jego było trzynaście lat, gdy obrzezane było ciało nieobrzeski jego.
Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlá.
26 Tegoż dnia obrzezany jest Abraham, i Ismael, syn jego.
Ní ọjọ́ náà gan an ni a kọ Abrahamu ní ilà pẹ̀lú Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ ọkùnrin.
27 I wszyscy mężowie domu jego, urodzeni w domu, i kupieni za pieniądze od cudzoziemców, obrzezani są z nim.
Àti gbogbo ọkùnrin tí ó wà ní ilé Abrahamu, ìbá à ṣe èyí tí a bí ní ilé rẹ̀ tàbí èyí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àlejò ni a kọ ní ilà pẹ̀lú rẹ̀.