< Rodzaju 14 >
1 I stało się za dni Amrafela, króla Senaarskiego, Aryjocha, króla Ellasarskiego, Chodorlahomera, króla Elamskiego i Tydala, króla Goimskiego:
Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
2 Że podnieśli wojnę przeciw Borowi królowi Sodomskiemu, i przeciw Bersie królowi Gomorskiemu, i Senaabowi królowi Adamackiemu, i Semeberowi królowi Seboimskiemu, i królowi Belamskiemu, to jest Zoarskiemu.
jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
3 Wszyscy ci zaciągnęli się w dolinę Syddym, ta jest teraz morzem słonem.
Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
4 Bo ci dwanaście lat służyli Chodorlahomerowi, a trzynastego roku odstąpili od niego.
Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
5 A tak roku czternastego wyciągnął Chodorlahomer z królmi, którzy z nim byli, i poraził Rafaimy w Astarot Karnaimie, i Zuzymy w Hamie, i Emimy w Sawie Karyjataim.
Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
6 Także Chorajczyki na górze ich Seir, aż do równiny Paran, która jest przy puszczy.
àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
7 Potem się wrócili, i przyciągnęli do En Myspat, która jest Kades, i wybili wszystkę krainę Amalekitów; także też Amorrejczyka mieszkającego w Hasesontamar.
Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
8 Tedy wyciągnął król Sodomski, i król Gomorski, i król Adamacki, i król Zeboimski, i król Belamski, to jest Zoarski, i uszykowali się ku bitwie przeciwko im w dolinie Syddym.
Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
9 Przeciwko Chodorlahomerowi królowi Elamskiemu, i Tydalowi królowi Goimskiemu, i Amrafelowi królowi Senaarskiemu, i Aryjochowi królowi Ellasarskiemu, czterech królów, przeciw pięciu.
láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
10 A w onej dolinie Syddym, było wiele studzien iłowatych; i uciekali król Sodomski i Gomorski, a polegli tam, a którzy zostali, na górę uciekli.
Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
11 A zabrawszy wszystkę majętność Sodomską, i Gomorską, i wszystkę żywność ich, odciągnęli.
Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
12 Zabrali też Lota synowca Abramowego, i majętność jego, i poszli; bo on mieszkał w Sodomie.
Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
13 I przyszedł jeden, który uszedł, i oznajmił to Abramowi Hebrejczykowi, który mieszkał w równinach Mamrego Amorrejczyka, brata Eschola, i brata Anera; ci bowiem uczynili byli przymierze z Abramem.
Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
14 A usłyszawszy Abram, iż był pojmany brat jego, wyprawił ćwiczonych sług swoich zrodzonych w domu swym, trzy sta i osiemnaście, i gonił je aż do Dan.
Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
15 I rozdzieliwszy się przypadł na nie w nocy, sam i słudzy jego, i poraził je; i gonił je aż do Hoby, która leży po lewej stronie Damaszku.
Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
16 I odebrał nazad wszystkę majętność, także i Lota brata swego z majętnością jego wrócił, także i niewiasty, i lud.
Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
17 Tedy wyszedł król Sodomski przeciw niemu, gdy się wracał od porażki Chodorlahomera, i królów, którzy z nim byli na dolinie Sawe, która jest doliną królewską.
Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
18 A Melchisedek, król Salemski, wyniósł chleb i wino; a ten był kapłanem Boga najwyższego.
Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
19 I błogosławił mu, a rzekł: Błogosławiony Abram od Boga najwyższego, dzierżawcy nieba i ziemi.
Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
20 I błogosławiony Bóg najwyższy, który podał nieprzyjacioły twe w rękę twoję; i dał mu Abram dziesięcinę ze wszystkiego.
Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
21 Zatem rzekł król Sodomski do Abrama: Daj mi ludzie, a majętność pobierz sobie.
Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
22 Tedy rzekł Abram królowi Sodomskiemu: Podniosłem rękę swą ku Panu Bogu najwyższemu, dzierżawcy nieba i ziemi;
Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
23 Że i najmniejszej nitki ani rzemyczka obuwia nie wezmę ze wszystkiego, co twego jest; żebyś nie rzekł: Jam zbogacił Abrama.
pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
24 Okrom tego, co strawili słudzy, i okrom działu mężów, którzy chodzili ze mną, Anera, Eschola, i Mamrego; ci niech wezmą dział swój.
Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”