< Rodzaju 11 >

1 A była wszystka ziemia jednego języka, i jednej mowy.
Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
2 I stało się, gdy wyszli od wschodu słońca, znaleźli równinę w ziemi Senaar, i mieszkali tam.
Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
3 I rzekł jeden do drugiego: Nuże naczyńmy cegły i wypalmy ją ogniem: i mieli cegłę miasto kamienia, a glinę iłowatą mieli miasto wapna.
Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
4 Potem rzekli: Nużeż, zbudujmy sobie miasto i wieżą, której by wierzch dosięgał do nieba, a uczyńmy sobie imię; byśmy się snać nie rozproszyli po obliczu wszystkiej ziemi.
Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
5 Tedy Pan zstąpił, aby oglądał miasto ono, i wieżą, którą budowali synowie ludzcy.
Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
6 I rzekł Pan: Oto lud jeden, i język jeden tych wszystkich; a toć jest zaczęcie dzieła ich, a teraz nie zabroni im nikt wszystkiego, co zamyślili uczynić.
Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
7 Przetoż zstąpmy, a pomieszajmy tam język ich, aby jeden drugiego języka nie zrozumiał.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
8 A tak rozproszył je Pan stamtąd po obliczu wszystkiej ziemi; i przestali budować miasta onego.
Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
9 Przetoż nazwał imię jego Babel; iż tam pomieszał Pan język wszystkiej ziemi; i stamtąd rozproszył je Pan po obliczu wszystkiej ziemi.
Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
10 Teć są rodzaje Semowe: Sem gdy miał sto lat, spłodził Arfachsada we dwa lata po potopie.
Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
11 I żył Sem po spłodzeniu Arfachsada pięć set lat, i spłodził syny i córki.
Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
12 Arfachsad też żył trzydzieści i pięć lat, i spłodził Selecha.
Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
13 I żył Arfachsad po spłodzeniu Selecha cztery sta lat, i trzy lata, i spłodził syny i córki.
Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
14 Selech zaś żył trzydzieści lat, i spłodził Hebera.
Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
15 I żył Selech po spłodzeniu Hebera cztery sta lat, i trzy lata, i spłodził syny i córki.
Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
16 I żył Heber trzydzieści lat i cztery, i spłodził Pelega.
Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
17 Żył też Heber po spłodzeniu Pelega, cztery sta lat, i trzydzieści lat, i spłodził syny i córki.
Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
18 Żył też Peleg trzydzieści lat, i spłodził Rehu.
Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.
19 I żył Peleg po spłodzeniu Rehu dwieście lat, i dziewięć lat, i spłodził syny i córki.
Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ọdún ó lé mẹ́sàn-án lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
20 Także Rehu żył trzydzieści lat, i dwa, i spłodził Saruga.
Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ni ó bí Serugu.
21 I żył Rehu po spłodzeniu Saruga dwieście lat, i siedem lat, i spłodził syny i córki.
Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.
22 Sarug zaś żył trzydzieści lat, i spłodził Nachora.
Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Nahori.
23 I żył Sarug po spłodzeniu Nachora dwieście lat, i spłodził syny i córki.
Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
24 Także Nachor żył dwadzieścia i dziewięć lat, i spłodził Tarego.
Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n, ó bí Tẹra.
25 I żył Nachor po spłodzeniu Tarego sto lat i dziewiętnaście lat, i spłodził syny i córki.
Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn dín lọ́gọ́fà lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
26 I żył Tare siedemdziesiąt lat, i spłodził Abrama, Nachora i Harana.
Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún ó bí Abramu, Nahori àti Harani.
27 A teć są rodzaje Tarego: Tare spłodził Abrama, Nachora i Harana. Haran zaś spłodził Lota.
Wọ̀nyí ni ìran Tẹra. Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani. Harani sì bí Lọti.
28 I umarł Haran przed obliczem Tarego ojca swego, w ziemi narodzenia swego, w Ur Chaldejskiem.
Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea.
29 I pojęli Abram i Nachor sobie żony: imię żony Abramowej było Saraj, a imię żony Nachorowej Melcha, córka Harana, ojca Melchy, i ojca Jeschy.
Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska.
30 A była Saraj niepłodna, i nie miała dziatek.
Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.
31 Wziął tedy Tare Abrama syna swego, i Lota syna Haranowego, wnuka swego, i Saraj niewiastę swoję, żonę Abrama syna swego; i wyszli społu z Ur Chaldejskiego, aby szli do ziemi Chananejskiej; a przyszli aż do Haranu, i mieszkali tam.
Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.
32 I było dni Tarego dwieście lat, i pięć lat; i umarł Tare w Haranie.
Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ọdún ó lé márùn-ún ni ó kú ní Harani.

< Rodzaju 11 >