< Ezdrasza 1 >
1 Roku pierwszego Cyrusa, króla Perskiego, aby się wypełniło słowo Pańskie powiedziane przez usta Jeremijaszowe, wzbudził Pan ducha Cyrusa, króla Perskiego, że kazał obwołać i rozpisać po wszystkiem królestwie swojem, mówiąc:
Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi, ọba Persia, kí a lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí Jeremiah sọ ṣẹ, Olúwa ru ọkàn Kirusi ọba Persia sókè láti ṣe ìkéde jákèjádò gbogbo agbègbè ìjọba rẹ̀, kí ó sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ pé,
2 Tak mówi Cyrus, król Perski: Wszystkie królestwa ziemi dał mi Pan, Bóg niebieski; i ten mi rozkazał, abym mu zbudował dom w Jeruzalemie, które jest w Judztwie.
“Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia wí pé: “‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mi ní gbogbo ìjọba ayé. Ó sì ti yàn mí láti kọ́ tẹmpili Olúwa fún un ní Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda.
3 Kto tedy jest między wami ze wszystkiego ludu jego, z tym niech będzie Bóg jego, a ten niech idzie do Jeruzalemu, które jest w Judztwie, a niech buduje dom Pana, Boga Izraelskiego; onci jest Bóg, który jest w Jeruzalemie.
Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín—kí Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda, láti kọ́ tẹmpili Olúwa Ọlọ́run Israẹli, Ọlọ́run tí ó wà ní Jerusalẹmu.
4 A ktoby został w któremkolwiek miejscu, gdzie jest przychodniem, niech go podpomogą mężowie miejsca onego srebrem i złotem, i majętnością, i bydłem, oprócz dobrowolnej ofiary na dom Boży, który jest w Jeruzalemie.
Kí àwọn ènìyàn ní ibikíbi tí ẹni náà bá ń gbé kí ó fi fàdákà àti wúrà pẹ̀lú ohun tí ó dára àti ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú ọrẹ àtinúwá ràn án lọ́wọ́ fún tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu.’”
5 Tedy powstali przedniejsi z domów ojcowskich, z Judy i z Benjamina, i kapłani, i Lewitowie; wszelki, którego ducha pobudził Bóg, aby szli, a budowali dom Pański, który jest w Jeruzalemie;
Nígbà náà àwọn olórí ìdílé Juda àti Benjamini àti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi—olúkúlùkù ẹni tí Ọlọ́run ti fọwọ́ tọ́ ọkàn rẹ̀—múra láti gòkè lọ láti kọ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu.
6 Których wszyscy mieszkający około nich wspomagali naczyniem srebrnem i złotem, majętnością, i bydłem, i rzeczami kosztownemi, oprócz wszystkiego, co dobrowolnie ofiarowano.
Gbogbo àwọn aládùúgbò wọn ràn wọ́n lọ́wọ́ pẹ̀lú ohun èlò ti fàdákà àti wúrà, pẹ̀lú onírúurú ohun ìní àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn iyebíye, ní àfikún si gbogbo àwọn ọrẹ àtinúwá.
7 Król też Cyrus wyniósł naczynia domu Pańskiego (które był zabrał Nabuchodonozor z Jeruzalemu, a oddał je był do domu Boga swego).
Ní àfikún, ọba Kirusi mú àwọn ohun èlò tí ó jẹ́ ti ilé Olúwa jáde wá, tí Nebukadnessari ti kó lọ láti Jerusalẹmu tí ó sì ti kó sí ilé òrìṣà rẹ̀.
8 A wyniósł je Cyrus, król Perski, przez ręce Mitrydatesa podskarbiego, który je pod liczbą oddał Sesbasarowi, książęciu Judzkiemu.
Kirusi ọba Persia pàṣẹ fún Mitredati olùṣọ́ ilé ìṣúra láti kó wọn jáde, ó sì kà wọ́n fún Ṣeṣbassari ìjòyè Juda.
9 A tak jest liczba ich: Miednic złotych trzydzieści, miednic srebrnych tysiąc, nożów dwadzieścia i dziwięć.
Èyí ni iye wọn. Ọgbọ̀n àwo wúrà 30 Ẹgbẹ̀rún àwo fàdákà 1,000 Àwo ìrúbọ fàdákà mọ́kàndínlọ́gbọ̀n 29
10 Kubków złotych trzydzieści, kubków srebrnych podlejszych cztery sta i dziesięć, a naczynia innego tysiącami.
Ọgbọ̀n àdému wúrà 30 Irinwó ó lé mẹ́wàá oríṣìí àdému fàdákà mìíràn 410 Ẹgbẹ̀rún kan àwọn ohun èlò mìíràn 1,000
11 Wszystkiego naczynia złotego i srebrnego pięć tysięcy i cztery sta; wszystko to wyniósł Sesbasar, gdy się prowadził lud z niewoli, z Babilonu do Jeruzalemu.
Gbogbo ohun èlò wúrà àti ti fàdákà ní àpapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ó lé irinwó. Ṣeṣbassari kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí wá pẹ̀lú àwọn ìgbèkùn tí ó gòkè wá láti Babeli sí Jerusalẹmu.