< Ezechiela 8 >

1 I stało się roku szóstego, piątego dnia, szóstego miesiąca, gdym siedzał w domu swym, a starsi Judzcy siedzieli przedemną, tedy tam przypadła na mię ręka panującego Pana.
Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
2 I widzałem, a oto podobieństwo na wejrzeniu jako ogień; od biódr jego na dół jako ogień, a od biódr jego w górę na wejrzeniu jako blask, i niby prędka światłość.
Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
3 Tedy ściągnąwszy podobieństwo ręki, uchwycił mię za kędzierze głowy mojej, i podniósł mię duch między ziemią i między niebem, a przywiódł mię do Jeruzalemu w widzeniach Bożych, do wejścia bramy wewnętrznej, która patrzy ku północy, gdzie była stolica bałwana do gorliwości i zapalczywości pobudzająca.
Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
4 A oto tam była chwała Boga Izraelskiego na wejrzeniu jako ona, którąm widział na polu.
Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
5 I rzekł do mnie: Synu człowieczy! teraz podnieś oczy swe ku drodze na północy; a tak podniosłem oczy swe ku drodze na północy, a oto na północy był u bramy ołtarzowej on bałwan pobudzający do gorliwości w samem prawie wejściu.
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
6 Wtem mi rzekł: Synu człowieczy! widziszże ty, co ci czynią, obrzydliwości wielkie, które tu czyni dom Izraelski? tak, że się oddalić muszę od świątnicy mojej; ale obróciwszy się ujrzysz obrzydliwości jeszcze większe.
Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
7 I przywiódł mię do drzwi sieni, gdziem ujrzał, a oto dziura jedna była w ścianie.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
8 I rzekł do mnie: Synu człowieczy! przekop teraz tę ścianę: i przekopałem ścianę, a oto drzwi jedne.
Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
9 I rzekł do mnie: Wnijdź, a obacz te złe obrzydliwości, które tu oni czynią.
Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
10 Przetoż wszedłszy ujrzałem, a oto wszelakie podobieństwa płazu, i zwierząt obrzydłych, i wszelakich plugawych bałwanów domu Izraelskiego wyryte były na ścianie wszędy w około.
Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
11 A siedmdziesiąt mężów starszych z domu Izraelskiego, z Jazanijaszem, synem Safanowym, stojącym w pośród nich, stali przed nimi, mając każdy kadzielnicę swoję w ręcę swej, tak, że gęsty obłok kadzenia w górę wstępował.
Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
12 I rzekł do mnie: A widziałżeś, synu człowieczy! co starsi domu Izraelskiego w ciemności czynią, każdy w pokojach swoich malowanych? Bo mówią: Nie widzi nas Pan, opuścił Pan tę ziemię.
Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
13 Znowu rzekł do mnie: Jeszcze obróciwszy się ujrzysz obrzydliwości większe, które oni czynią.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
14 I przywiódł mię do wrót bramy domu Pańskiego, która jest na półnpcy, a oto tam niewiasty siedziały, płacząc Tammusa;
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
15 I rzekł mi: A widziałżeś, synu człowieczy? Ale obróciwszy się ujrzysz jeszcze większe obrzydliwości, niżeli te.
Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
16 Tedy mię wprowadził do wnętrznej sieni domu Pańskiego, a oto u drzwi kościoła Pańskiego między przysionkim i ołtarzem było dwadzieścia i pięć mężów, których tyły były obrócone ku kościołowi Pańskiemu, a twarze ich na wschód, którzy się kłaniali przeciwko wschodowi słońca.
Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
17 I rzekł mi: A widziałżeś, synu człowieczy? Izali to lekka rzecz jest domowi Judzkiemu, czynić takie obrzydliwości, jakie tu czynią? Bo napełniwszy ziemię nieprawością, obrócili się, aby mię draźnili, a oto przykładają latorośl winną do nosów swoich.
Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
18 Przetoż i Ja postąpię z nimi wedłu zapalczywości; oko moje nie sfolguje ani się zmiłuję; i będą wołać do uszów moich głosem wielkim, a nie wysłucham ich.
Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”

< Ezechiela 8 >