< Ezechiela 38 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie mówiąc:
Ọrọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Synu człowieczy! obróć twarz swoję przeciw Gogowi w ziemi Magog, książęciu głównemu w Mesech i Tubal, a prorokuj przeciw niemu.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
3 I rzecz: Tak mówi panujący Pan: Otom Ja przeciw tobie, o Gogu, księciu główny w Mesechu i w Tubalu!
kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
4 Bo cię zawrócę, i włożę wędzidło w czeluści twoje, i wywiodę cię, i wszystko wojsko twoje, konie i jezdnych wszystkich poubieranych w zupełny kirys, hufy wielkie z tarczami i z przyłbicami, wszystkich tych, którzy władają mieczem.
Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
5 Persów, Murzynów i Putejczyków z nimi, tych wszystkich z tarczami i z przyłbicami;
Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
6 Gomer i wszystkie hufy jego, dom Togormy mieszkającego w stronach północnych, i wszystkie poczty jego, narodów wiele z tobą.
Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
7 Gotuj się, a wypraw się, ty i wszystkie półki twoje, które się zebrały do ciebie, a bądź stróżem ich.
“‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
8 Po wielu dniach nawiedziony będziesz, a w ostatnie lata przyciągniesz na lud uwolniony od miecza, i zebrany z wielu narodów, na góry Izraelskie, które były pustynią ustawiczną, gdyż oni z narodów będąc wywiedzieni, wszyscy bezpiecznie mieszkać będą.
Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
9 W tem przyciągniesz i przyjdziesz jako burza, będziesz jako obłok okrywający ziemię, ty i wszystkie poczty twoje, i wiele narodów z tobą.
Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
10 Tak mówi panujący Pan: Dnia onego wstąpią dziwne rzeczy na serce twoje, a będziesz złe zamysły myślał,
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
11 I rzeczesz: Wtargnę do ziemi, w której są wsi; przypadnę na spokojnych i bezpiecznie mieszkających, na wszystkich, którzy mieszkają bez muru, a zawór i bram nie mają;
Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
12 Abym wziął łupy, a rozchwycił korzyści; abym obrócił rękę swoję na spustoszone miejsca już znowu osadzone, i na lud zgromadzony z narodów, którzy się bydłem i kupiectwem bawią, a mieszkają w pośrodku ziemi.
Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
13 Seba, i Dedan, i kupcy morscy, i wszystkie lwięta jego rzekną do ciebie: Izali ty na branie łupów idziesz? Izali na rozchwycenie korzyści zebrałeś półki twoje, abyś wybrał srebro i złoto, i zabrał dobytek i majętności, a żebyś zebrał łup wielki?
Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?”’”
14 Przetoż prorokuj, synu człowieczy! a mów do Goga: Tak mówi panujący Pan: Izali się w on dzień, gdy lud mój Izraelski bezpiecznie mieszkać będzie, nie dowiesz?
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
15 I przyjdziesz z miejsca swego z stron północnych, ty i narodów wiele z tobą, wszyscy wsiadający na konie, lud wielki i wojsko gwałtowne;
Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
16 I przypadniesz na lud mój Izraelski jako obłok, abyś okrył tę ziemię. W ostatnie dni przywiodę cię do ziemi mojej, aby mię poznały narody, gdy będę poświęcony w tobie, przed oczyma ich, o Gogu!
Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
17 Tak mówi panujący Pan: Azażeś ty nie jest on, o którymem powiedział za dni dawnych przez sług moich, proroków Izraelskich, którzy prorokowali za dni onych lat, żem cię miał przywieść na nich?
“‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
18 Wszakże w on dzień, w dzień, którego przyciągnie Gog na ziemię Izraelską, mówi panujący Pan, wzruszy się gniew mój w popędliwości mojej;
Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
19 A w gorliwości mojej, i w ogniu gniewu mego mówić będę, że dnia onego będzie wielki rozruch w ziemi Izraelskiej;
Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
20 I zadrżą od obliczności mojej ryby morskie, i ptastwo niebieskie, i zwierz polny, i wszelka gadzina płazająca się po ziemi, i wszyscy ludzie, którzy są na obliczu ziemi; i porozwalają się góry, i upadną wysokie wieże, i każdy mur obali się na zie mię.
Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
21 Bo przywołam przeciwko niemu po wszystkich górach moich miecz, mówi panujący Pan; miecz każdego obróci się na brata jego.
Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
22 I będę się z nim sądził morem i krwią, a deszcz gwałtowny i grad kamienny, ogień i siarkę spuszczę nań, i na wojska jego, i na wiele narodów, które z nim będą.
Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
23 I pokażę się wielmożnym, i poświęcę się, i znajomym się uczynię przed oczyma wielu narodów, i dowiedzą się, żem Ja Pan.
Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’

< Ezechiela 38 >