< Ezechiela 37 >

1 Była nademną ręka Pańska, i wywiódł mię Pan w duchu, i postawił mię w pośrodku pola, które było pełne kości;
Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
2 I przewiódł mię przez nie w około a w około, a oto było ich bardzo wiele na onem polu, a oto były bardzo suche.
Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
3 I rzekł do mnie: Synu człowieczy! ożyjąli te kości? I rzekłem: Panujący Panie! ty wiesz.
Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
4 W tem rzekł do mnie: Prorokuj o tych kościach, a mów do nich: Kości suche, słuchajcie słowa Pańskiego!
Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
5 Tak mówi panujący Pan o tych kościach: Oto ja wprowadzę w was ducha, a ożyjecie;
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
6 A włożę na was żyły, i uczynię, że porośnie na was mięso, i powlekę was skórą, a dam wam ducha, i ożyjecie, i poznacie, żem Ja Pan.
Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
7 Prorokowałem tedy, jako mi rozkazano; i stał się szum, gdym ja prorokował, a oto poruszenie; i przystąpiły kości, kość do kości swojej.
Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
8 I ujrzałem, a oto na nich żyły, i mięso porosło, i powleczone były skórą po wierzchu; ale ducha nie było w nich.
Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
9 I rzekł do mnie: Prorokuj do ducha, prorokuj, synu człowieczy! i rzecz do ducha: Tak mówi panujący Pan: Od czterech wiatrów przyjdź, duchu! i natchnij te pobite, a niech ożyją.
Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
10 Prorokowałem tedy jako mi był rozkazał, i wstąpił w nie duch, a ożyły, i stanęły na nogach swoich, wojsko nader bardzo wielkie.
Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
11 I rzekł do mnie: Synu człowieczy! te kości są wszystek dom Izraelski. Oto mówią: Wyschły kości nasze, i zginęła nadzieja nasza, wygładzeni jesteśmy.
Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
12 Dlategoż prorokuj, a mów do nich: Tak mówi panujący Pan: Oto Ja otworzę groby wasze, i wywiodę was z grobów waszych, ludu mój! i przywiodę was do ziemi Izraelskiej!
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
13 I dowiecie się, żem Ja Pan, gdy Ja otworzę groby wasze, a wywiodę was z grobów waszych, ludu mój!
Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
14 I dam w was ducha mego, a ożyjecie, i dam wam odpocząć w ziemi waszej; i dowiecie się, że Ja Pan mówię to i uczynię, mówi Pan.
Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
15 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
16 A ty, synu człowieczy! weźmij sobie jedno drewno, i napisz na niem: Judzie i synom Izraelskim, towarzyszom jego. Weźmij też i drugie drewno, a napisz na niem: Józefowi drewnu Efraimowemu, i wszystkiemu domowi Izraelskiemu, towarzyszom jego!
“Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
17 I złóż je sobie jedno do drugiego w jedno drewno, aby były jako jedno w ręce twojej.
So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
18 A gdy rzekną do ciebie synowie ludu twego, mówiąc: Izali nam nie oznajmisz, co przez to rozumiesz?
“Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
19 Rzeczesz im: Tak mówi panujący Pan: Oto Ja wezmę drewno Józefowe, które jest w ręce Efraimowej i pokolenia Izraelskie, towarzyszów jego, i przyłożę je z nim do drewna Judowego, i uczynię je jednem drewnem, a będą jednem w ręce mojej.
Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
20 A gdy będą one drewna, na których napiszesz, w ręce twojej przed oczyma ich,
Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
21 Tedy rzecz do nich: Tak mówi panujący Pan: Oto Ja wezmę synów Izraelskich z pośrodku tych narodów, do których byli zaszli, i zgromadzę ich zewsząd, a przywiodę ich do ziemi ich;
kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
22 I uczynię ich narodem jednym w ziemi, na górach Izraelskich, i będzie król jeden nad onymi wszystkimi za króla; a nie będą więcej dwa narody, nie rozdzielą się nigdy więcej na dwoje królestw;
Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
23 Nie splugwią się więcej plugawemi bałwanami swemi, i obrzydliwościami swemi, ani jakiemi przestępstwy swemi; i wybawię ich z każdego mieszkania ich, gdzie zgrzeszyli, i oczyszczę ich, i będą ludem moim, a Ja będę Bogiem ich.
Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
24 A sługa mój Dawid będzie królem nad nimi, i pasterza jednego wszyscy mieć będą, aby w sądach moich chodzili, i ustaw moich przestrzegali, i czynili je.
“‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
25 I będą mieszkać w onej ziemi, którąm był dał słudze memu Jakóbowi, w której mieszkali ojcowie wasi; będą, mówię, w niej mieszkali oni i synowie ich, i synowie synów ich aż na wieki, a Dawid, sługa mój, będzie książęciem ich na wieki.
Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
26 I uczynię też z nimi przymierze pokoju, a przymierze wieczne będzie z nimi; i osadzę ich i rozmnożę ich, i założę świątnicę moję w pośrodku ich na wieki.
Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
27 I będzie przybytek mój między nimi, i będę Bogiem ich, a oni będą ludem moim.
Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
28 I dowiedzą się narody, żem Ja Pan, który poświęcam Izraela, gdy będzie świątnica moja w pośrodku ich na wieki.
Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”

< Ezechiela 37 >