< Ezechiela 35 >
1 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Synu człowieczy! obróć twarz swoję przeciwko górze Seir, a prorokuj przeciwko niej,
“Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
3 I mów do niej: Tak mówi panujący Pan: Otom Ja przeciwko tobie, góro Seir! a wyciągnę rękę moję na cię, i podam cię na wielkie spustoszenie.
kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
4 Miasta twoje w spustoszenie obrócę, że będziesz spustoszona, i dowiesz się, żem Ja Pan.
Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
5 Przeto, iż wieczną nieprzyjaźń wiedziesz, i rozpraszasz synów Izraelskich ostrzem miecza czasu utrapienia ich, czasu wykonywania kaźni ich;
“‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
6 Dlatego, jako żyję Ja, mówi panujący pan, że cię podam na zabicie, a krew cię ścigać będzie; ponieważ krwi rozlewania w nienawiści nie masz, przetoż cię krew ścigać będzie.
nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
7 I obrócę górę Seir w wielkie spustoszenie, a wygubię z niej przechodzącego, i wracającego się;
Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
8 I napełnię góry jej pobitymi jej; na pagórkach twoich, i na dolinach twoich, i przy wszystkich strumieniach twoich pobici mieczem polegną na nich;
Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
9 Na pustynie wieczne podam cię, i w miastach twoich mieszkać nie będą; a dowiecie się, żem Ja Pan.
Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
10 Przetoż iż mówisz: Te dwa narody, i te dwie ziemie moje będą a posiądziemy tę, w której Pan mieszkał;
“‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
11 Dlategoż, jako żyję Ja, mówi panujący Pan, że uczynię według gniewu twego i według zawiści twojej, którąś czyniła w nienawiści swej przeciwko nim; i będę poznany od nich, gdy cię sądzić będę;
nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
12 I dowiesz się, żem Ja Pan słyszał wszystkie urągania twoje, któreś wyrzekła przeciw górom Izraelskim, mówiąc: Spustoszone są, a nam podane są ku pożarciu.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
13 Boście się przeciwko mnie wynosili usty waszemi, a rozmnożyliście słowa swoje przeciwko mnie, com Ja słyszał.
Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
14 Tak mówi panujący Pan: Jako się ta wszystka ziemia weseli, tak cię obrócę w pustnię.
Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
15 Jako się ty weselisz nad dziedzictwem domu Izraelskiego, przeto, że jest spustoszone, tak uczynię i tobie; będziesz spustoszona, o góro Seir! a zgoła wszystka ziemia Edomska; i dowiedzą się żem Ja Pan.
Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”