< Ezechiela 32 >
1 A dwunastego roku, miesiąca dwunastego, pierwszego dnia tegoż miesiąca, stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kejìlá, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Synu człowieczy! podnieś lament nad Faraonem, królem Egipskim, a powiedz mu: Podobnyś ty lwowi młodemu między narodami, tyś jest jako wieloryb w morzu, gdyż bujając po rzekach twoich mącisz wodę nogami twemi, i mięszasz rzeki jego.
“Ọmọ ènìyàn, ṣe ìpohùnréré ẹkún nítorí Farao ọba Ejibiti kí o sì wí fún un: “‘Ìwọ dàbí kìnnìún láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà; ìwọ dàbí ohun ẹ̀mí búburú inú àwọn omi okun to ń lọ káàkiri inú àwọn odò rẹ, ìwọ fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ omi láti mú kí àwọn odò ní ẹrẹ̀.
3 Tak mówi panujący Pan: Rozciągnę też na cię sieć moję przez zebranie wielu narodów, którzy cię wyciągną niewodem moim;
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìpéjọ ènìyàn èmi yóò da àwọ̀n mi bò ọ́ wọn yóò sì fà ọ́ sókè nínú àwọ̀n mi.
4 I zostawię cię na ziemi, na polu porzucę cię, i sprawię, że mieszkać będzie na tobie wszelkie ptastwo niebieskie, i nakarmię tobą zwierza wszystkiej ziemi;
Èmi yóò jù ọ́ sí orí ilẹ̀ èmi yóò sì fà ọ́ sókè sí orí pápá gbangba. Èmi yóò jẹ́ kí gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ní orí rẹ. Gbogbo àwọn ẹranko ayé yóò fi ìwọra gbé ara wọn lórí rẹ.
5 I rozrzucę mięso twoje po górach, i napełnię doliny wysokością twoją,
Èmi yóò tan ẹran-ara rẹ ká sórí àwọn òkè gíga ìyókù ara rẹ ní wọn yóò fi kún àwọn àárín àwọn òkè gíga.
6 I napoję ziemię twoję, w której pływasz, krwią twoją aż do gór, tak, że i rzeki będą napełnione tobą.
Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń sàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náà gbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga, àwọn àlàfo jíjìn ní wọn yóò kún fún ẹran-ara rẹ.
7 A gdy cię zgaszę, zakryję niebiosa, i ciemne uczynię gwiazdy ich, słońce obłokiem zasłonię, a księżyc nie da światła swego.
Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run dé àwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn; èmi yóò sì fi ìkùùkuu bo oòrùn òṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
8 Wszystkie światła jasne na niebiosach zaćmię dla ciebie, i przywiodę ciemność na ziemię twoję, mówi panujący Pan.
Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀run ni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ; èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ̀ rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Nadto zasmucę serce wielu narodów, gdy za sprawą moją przyjdzie wieść o starciu twojem między narody, do ziem, którycheś nie znał.
Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rú nígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wá ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò í tí ì mọ̀.
10 Uczynię, mówię, że się zdumieje nad tobą wiele narodów, a królowie ich zatrwożą się bardzo dla ciebie, gdy szermować będę mieczem swoim przed twarzą ich; będą się zaiste lękać co chwila każdy o duszę swoję w dzień upadku twego.
Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rùbà ọ́, àwọn ọba wọn yóò sì wárìrì fún ìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ, nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọn. Ní ọjọ́ ìṣubú rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrì ní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.
11 Bo tak mówi panujący Pan: Miecz króla Babilońskiego przyjdzie na cię.
“‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Idà ọba Babeli yóò wá sí orí rẹ,
12 Mieczami mocarzów porażę zgraję twoję; najokrutniejsi ze wszystkich narodów, ci skażą pychę Egipską, i będzie zgładzone wszystko mnóstwo jego.
Èmi yóò mú kí ìjọ ènìyàn rẹ kí ó tí ipa idà àwọn alágbára ènìyàn ṣubú àwọn orílẹ̀-èdè aláìláàánú jùlọ. Wọn yóò tú ìgbéraga Ejibiti ká, gbogbo ìjọ rẹ ní a yóò dá ojú wọn bolẹ̀.
13 Zagładzę i wszystko bydło jego, które jest przy wodach wielkich, tak, że ich więcej nie zmąci noga człowiecza, ani kopyta bydlęce mącić ich będą.
Gbogbo ẹran ọ̀sìn rẹ ni èmi yóò parun ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kì i ṣe ẹsẹ̀ ènìyàn ní yóò tẹ ibẹ̀ ẹsẹ̀ ẹran ọ̀sìn kì yóò sì mú kí ibẹ̀ ni ẹrọ̀fọ̀.
14 Tedy uczynię, że się wody ich ustoją, a rzeki ich jako oliwa pójdą, mówi panujący Pan.
Lẹ́yìn náà èmi yóò mú kí omi rẹ̀ tòrò kí àwọn odò rẹ̀ kí o sàn bí epo, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Gdyż obrócę ziemię Egipską w spustoszenie, a ziemia będzie wypróżniona z pełności swojej, gdy pobiję wszystkich mieszkających w niej; i dowiedzą się, żem Ja Pan.
Nígbà tí mo bá sọ Ejibiti di ahoro, tí mo sì kó gbogbo ohun tí ó wà ní orí ilẹ̀ náà kúrò. Nígbà tí mo bá gé àwọn olùgbé ibẹ̀ lulẹ̀, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
16 Toć jest lament, którym nad nią lamentować będą; córki narodów narzekać będą nad nią, nad Egiptem i nad wszystkiem mnóstwem jego narzekać będą, mówi panujący Pan.
“Èyí yìí ni ẹkún tí a yóò sun fún un. Àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè yóò sun ún; nítorí Ejibiti àti gbogbo ìjọ rẹ, wọn yóò sun ún, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
17 Potem dwunastego roku, piętnastego dnia tegoż miesiąca, stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc;
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mí wá:
18 Synu człowieczy! narzekaj nad mnóstwem Egipskiem, a zepchnij je, i córki tych narodów sławnych aż do najniższych miejsc ziemi, do tych, co zstępują do dołu,
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún lórí Ejibiti kí o sì ránṣẹ́ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ àti òun àti àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè alágbára, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ìsàlẹ̀, kòtò.
19 I mów: Nad kogożeś wdzięczniejszy? Zstąp, a połóż się z nieobrzezańcami.
Sọ fún wọn, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ní ojúrere jù àwọn tí o kù lọ? Lọ sí ìsàlẹ̀ kí a sì tẹ́ ọ sí àárín àwọn aláìkọlà náà.’
20 W pośród pobitych mieczem upadną; pod miecz podany jest, wywleczcież go ze wszystką zgrają jego.
Wọn yóò ṣubú láàrín àwọn tí a fi idà pa. A fa idà yọ; jẹ́ kí a wọ́ Ejibiti kúrò pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀.
21 Mówić do niego będą najmocniejsi z mocarzów z pośrodku grobu z pomocnikami jego, którzy tam zstąpiwszy, leżą z nieobrzezańcami pobitymi mieczem. (Sheol )
Láti inú isà òkú alágbára tí í ṣe aṣáájú yóò sọ nípa Ejibiti àti àwọn àlejò rẹ̀, ‘Wọn ti wá sí ìsàlẹ̀, wọn sì sùn pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.’ (Sheol )
22 Tam jest Assur, i wszystka zgraja jego, w około niego są groby jego; wszyscy ci pobici upadli od miecza.
“Asiria wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo jagunjagun rẹ̀; àwọn isà òkú àwọn tí a ti pa sì yí i ká, gbogbo àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú.
23 Którego groby położone są przy stronach dołu, aby była zgraja jego w około grobu jego; ci wszyscy pobici polegli od miecza, którzy puszczali strach w ziemi żyjacych.
Isà òkú wọn wà ní ibi tí ó jinlẹ̀ gan an nínú kòtò. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè ní a pa, tí ó ti ipa idà ṣubú.
24 Tam Elam i wszystka zgraja jego około grobu jego, ci wszyscy pobici upadli od miecza, którzy zstąpili w nieobrzezce do niskości ziemi, którzy puszczali strach swój w ziemi żyjących; jużci odnoszą hańbę swoją z tymi, którzy zstępują do dołu.
“Elamu wà níbẹ̀, o yí isà òkú rẹ̀ ká pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀. Gbogbo wọn ni a pa, àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè lọ sí ìsàlẹ̀ láìkọlà sí abẹ́ ilẹ̀. Wọ́n gba ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
25 W pośrodku pobitych postawili mu łoże, i wszystkiej zgrai jego, w około niego są groby jego; wszyscy ci nieobrzezańcy pobici są mieczem, przychodził strach ich na ziemię żyjących, jużci odnoszą hańbę swoję z tymi, którzy zstąpili do grobu, a w poś rodku pobitych położeni są.
A ṣe ibùsùn fún un láàrín àwọn tí a pa, pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀ tí ó yí isà òkú ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, tí a fi idà pa. Nítorí pé a tan ẹ̀rù wọn ká ilẹ̀ alààyè, wọn ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò; a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a pa.
26 Tam Mesech, Tubal i wszystka zgraja jego, i w około niego groby jego, ci wszyscy nieobrzezańcy pobici mieczem, choć puszczali strach swój w ziemi żyjących.
“Meṣeki àti Tubali wà níbẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ogun wọn yí isà òkú wọn ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, wọ́n fi idà pa wọ́n nítorí ẹ̀rù tiwọn tàn ká ilẹ̀ alààyè.
27 Aczkolwiekci jeszcze nie polegli z mocarzami, którzy upadli z nieobrzezańców, co zstąpili do grobu z wojennym orężem swoim, i położyli miecze swe pod głowy swe; a wszakże przyjdzie nieprawość ich na kości ich, chociaż strach tych mocarzów był w ziemi żyjących. (Sheol )
Wọn kì yóò sì dùbúlẹ̀ ti àwọn tí ó ṣubú nínú àwọn aláìkọlà, tí wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun wọn, wọ́n tí fi idà wọn rọ orí wọn. Ṣùgbọ́n àìṣedéédéé wọn yóò wà ní orí egungun wọn—bí wọ́n tilẹ̀ jẹ́ ẹ̀rù àwọn alágbára ní ilẹ̀ alààyè. (Sheol )
28 I ty w pośrodku nieobrzezańców starty będziesz, i będziesz leżał między pobitymi mieczem.
“Ìwọ náà, Farao, ní yóò ṣẹ, ti yóò dùbúlẹ̀ láàrín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.
29 Tam Edom, i królowie jego, i wszyscy książęta jego, którzy położeni są, z mocą swoją i z pobitymi mieczem; i ci z nieobrzezańcami leżeć będą, i z tymi, którzy zstępują do dołu.
“Edomu wà níbẹ̀, àwọn ọba rẹ̀ àti gbogbo ọmọbìnrin ọba; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní agbára, a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. Wọn dùbúlẹ̀ pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn ti o lọ sínú kòtò.
30 Tam wszyscy zgoła książęta północnej strony, i wszyscy Sydończycy, którzy zstępują do pobitych z strachem swoim, za moc swoję wstydzić się będą, i leżeć będą ci nieobrzezańcy z pobitymi mieczem, a odniosą hańbę swoję z tymi, którzy zstępują do dołu.
“Gbogbo àwọn ọmọ-aládé ilẹ̀ àríwá àti gbogbo àwọn ará Sidoni wà níbẹ̀; wọn lọ sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí a pa ní ìtìjú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ṣe okùnfà ẹ̀rù pẹ̀lú agbára wọn. Wọn sùn ní àìkọlà pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa, wọn sì ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
31 Tych ujrzawszy Farao ucieszy się nad wszystką zgrają swoją, która jest mieczem pobita, Farao i wszystko wojsko jego, mówi panujący Pan.
“Farao, òun àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ yóò rí wọn, a yóò sì tù ú nínú nítorí gbogbo ogun rẹ̀ tí a fi idà pa, ní Olúwa Olódùmarè wí.
32 Bo puszczę strach mój w ziemi żyjących, i położony będzie między nieobrzezańcami z pobitymi mieczem Farao i wszystka zgraja jego, mówi panujący Pan.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè, Farao àti gbogbo ogun rẹ̀ ni a yóò tẹ́ sí àárín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa ní Olúwa Olódùmarè wí.”