< Ezechiela 31 >

1 Potem jedenastego roku, trzeciego miesiąca, pierwszego dnia tegoż miesiąca, stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Synu człowieczy! mów do Faraona, króla Egipskiego, i do ludu jego: Komużeś podobnym w wielmożności twojej?
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
3 Oto Assur był jako cedr na Libanie, pięknych gałęzi i szeroko cień podawający i wysokiego wzrostu, a między gęstwiną gałęzi był wierzch jego.
Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
4 Wody mu wzrost dały, głębokość go wywyższyła, a rzekami jej otoczony był w około korzeń jego, a strumienie tylko swoje wypuszczała na wszystkie drzewa polne,
Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
5 Tak, że się wywyższył wzrost jego nad wszystkie drzewa polne, i rozkrzewiły się latorośle jego, a dla obfitości wód rozszerzyły się gałęzie jego, które wypuścił.
Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
6 Na gałęziach jego czyniło gniazda wszelakie ptastwo niebieskie, a pod latoroślami jego mnożyły się wszelkie zwierzęta polne, i pod cieniem jego siadały wszystkie narody zacne.
Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
7 I był piękny dla wielkości swojej, i dla długości gałęzi swoich; bo korzeń jego był przy wodach obfitych.
Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
8 Cedry go nie przewyższały w ogrodzie Bożym, jedliny nie były równe latoroślom jego, a kasztanowe drzewa nie były podobne gałęziom jego; żadne drzewo w ogrodzie Bożym nie było mu równe w piękności swojej.
Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
9 Jam go pięknym uczynił dla mnóstwa gałęzi jego, i zajrzały mu wszystkie drzewa w Eden, które były w ogrodzie Bożym.
Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
10 Przetoż tak mówi panujący Pan: Dlatego, że wysoko wzrósł, a wywyższył wierzch swój między gęstwiną gałęzi, i podniosło się serce jego dla wysokości jego:
“‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
11 Przetożen go podał w rękę najmocniejszego z narodów, aby się z nim srogo obchodził; dla niezbożności jego odrzuciłem go.
mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
12 A tak wygładzili go cudzoziemcy najsrożsi z narodów, i porzucili go; na górach i na wszystkich dolinach odpadły gałęzie jego, i połamane są latorośli jego przy wszystkich strumieniach tej ziemi; dlatego ustąpiły z cienia jego wszystkie narody zie mskie, i opuściły go.
àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
13 Na obaleniu jego mieszka wszelkie ptastwo niebieskie, a na gałęziach jego jest wszelki zwierz polny,
Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
14 Dlatego, aby się na potem nie wywyższało wzrostem swoim żadne drzewo przy wodach, i żeby nie wypuszczało wierzchów swoich, między gęstwiną gałęzi, i nie wspinało się nad inne wysokością swoją żadne drzewo wodami opojone. Albowiem ci wszyscy podan i są na śmierć, i wrzuceni w niskości ziemi w pośród synów ludzkich z tymi, którzy zstępują do dołu.
Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
15 Tak mówi panujący Pan: Dnia, którego on zstąpił do grobu, uczyniłem lament, zawarłem dla niego przepaść, i zahamowałem strumienie jej, aby się zastanowiły wody wielkie; i uczyniłaem, że się zaćmił dla niego Liban, a wszystkie drzewa polne dla nie go zemdlały. (Sheol h7585)
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
16 Od grzmotu upadku jego zatrwożyłem narody, gdym go wepchnął do grobu z tymi, co w dół zstępują, nad czem się ucieszyły na ziemi na dole wszystkie drzewa Eden, i co jest najwyborniejszego, i najlepszego na Libanie, i wszystko, co jest opojone wodą. (Sheol h7585)
Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
17 I ci z nim zstąpili do grobu, do pobitych mieczem, którzy byli ramieniem jego, i którzy siadali w cieniu jego w pośrodku narodów. (Sheol h7585)
Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
18 Komużeś podobny był sławą i wielkością między drzewami Eden? Oto zrzucony będziesz z drzewami Eden na dół na ziemię; w pośrodku nieobrzezańców polężesz między pobitymi mieczem. Toć jest Farao i wszystka zgraja jego, mówi panujący Pan.
“‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Ezechiela 31 >