< Ezechiela 29 >

1 Roku dziesątego, dziesątego miesiąca, dwunastego dnia tegoż miesiąca stało się słowo Pańskie do mnie mówiąc:
Ní ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹwàá, ọdún kẹwàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Synu człowieczy! obróć twarz swoję przeciwko Faraonowi, królowi Egipskiemu, a prorokuj przeciw niemu i przeciwko wszystkiemu Egiptowi;
“Ọmọ ènìyàn, kọjú sí Farao ọba Ejibiti kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí i àti sí gbogbo Ejibiti.
3 Mów, a rzecz: Tak mówi panujący Pan: Otom Ja przeciwko tobie o Faraonie, królu Egipski, wielorybie wielki, który leżysz w pośrodku rzek twoich, i mówisz: Mojać jest rzeka, i jam ją sobie uczynił;
Sọ̀rọ̀, kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, Farao ọba Ejibiti ìwọ ẹ̀mí búburú ńlá inú òkun tí ó dùbúlẹ̀ sí àárín àwọn odò ṣíṣàn rẹ. Èyí tí ó sọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili; èmi ni ó sì ṣe é fún ara mi.”
4 Przetoż włożę wędę w czeluści twoje, i uczynię, że powięzną ryby rzek twoich na łuskach twych, i wywlekę cię z pośrodku rzek twoich i wszystkie ryby rzek twoich, które na łuskach twoich powięzną;
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìwọ̀ mú ẹnu rẹ èmi yóò sì mú ẹja inú odò rẹ gbogbo lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ. Èmi yóò fà ọ́ síta kúrò láàrín àwọn odò rẹ, àti gbogbo ẹja odò rẹ yóò lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ.
5 I zostawię cię na puszczy, ciebie i wszystkie ryby rzek twoich: polężesz na polu, i nie będziesz zebrany ani zgromadzony; dam cię bestyjom ziemskim i ptastwu niebieskiemu ku pożarciu;
Èmi yóò sọ ọ́ nù sí aginjù ìwọ àti gbogbo ẹja inú odò rẹ: ìwọ yóò ṣubú sí gbangba oko a kì yóò sì ṣà ọ́ jọ tàbí gbé ọ sókè. Èmi ti fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹranko igbó àti fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run láti jẹ.
6 I dowiedzą się wszyscy mieszkający w Egipcie, żem Ja Pan, przeto żeście laską trzcinianą domowi Izraelskiemu.
Nígbà náà gbogbo àwọn olùgbé ni Ejibiti yóò mọ pé, Èmi ni Olúwa. “‘Ìwọ ti jẹ́ ọ̀pá ìyè fún ilé Israẹli.
7 Gdy się ciebie ręką chwytają, łamiesz się i rozcinasz im wszystko ramię; a gdy się podpierają tobą, kruszysz się, choć im nadstawiasz wszystkich biódr.
Nígbà tí wọn fi ọwọ́ agbára wọn dì ọ́ mú. Ìwọ fọ́, ìwọ sì ya gbogbo èjìká wọn; nígbà tí wọn fi ara tì ọ́, ìwọ sẹ́, ìwọ sì mú gbogbo ẹ̀gbẹ́ wọn gbọ̀n.
8 Dlategoż tak mówi panujący Pan: Oto Ja przywiodę na cię miecz, i wygładzę z ciebie człowieka i bydlę;
“‘Nítorí náà, èyí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi, Èmi yóò mú idà kan wá sórí rẹ tí yóò sì gé ènìyàn àti ẹran kúrò nínú rẹ.
9 A ziemia Egipska będzie pustynią i spustoszeniem, i dowiedzą się, żem Ja Pan, dlatego, żeś mówił: Rzeka moja, i jam ją uczynił;
Ilẹ̀ Ejibiti yóò di aginjù àti ahoro, nígbà náà ní wọn yóò sì mọ̀ wí pé èmi ní Olúwa. “‘Nítorí tí ìwọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili, Èmi ni mo ṣe é,”
10 Przetoż oto Ja będę przeciwko tobie i przeciwko rzece twojej, i podam ziemię Egipską w spustoszenie, i we srogie poburzenie, od wieży Sewene aż do granic Murzyńskich.
nítorí náà, mo lòdì sí ọ àti sí àwọn odò rẹ, èmi yóò sì mú kí ilẹ̀ Ejibiti di píparun àti ahoro, pátápátá, láti Migdoli lọ dé Siene, dé ààlà ilẹ̀ Kuṣi.
11 Nie przejdzie przez nią noga człowiecza, i noga bydlęca nie przejdzie przez nią, ani w niej będą mieszkać przez czterdzieści lat.
Kò sí ẹsẹ̀ ènìyàn tàbí tí ẹranko tí yóò gba ibẹ̀ kọjá; ẹni kankan kò ní gbé ibẹ̀ fún ogójì ọdún.
12 A tak uczynię ziemię Egipską pustnią nad inne ziemie spustoszone, a miasta jej nad inne miasta spustoszone, będą spustoszone przez czterdzieści lat: gdyż rozproszę Egipczan między narody, i rozwieję ich po ziemiach.
Èmi yóò sọ ilẹ̀ Ejibiti di ọ̀kan ní àárín àwọn ìlú tí ó di ahoro, fún ogójì ọdún, Èmi yóò sì fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sáàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sáàárín gbogbo ilẹ̀.
13 A wszakże tak mówi panujący Pan: Gdy się skończy czterdzieści lat, zgromadzę Egipczan z narodów, do których rozproszeni będą.
“‘Ṣùgbọ́n báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Ní òpin ogójì ọdún, èmi yóò ṣa àwọn ará Ejibiti jọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn níbi tí a fọ́n wọn ká sí.
14 I przywrócę zasię więźniów Egipskich, i przywiodę ich do ziemi Patros, do ziemi mieszkania ich, i będą tam królestwem podłem.
Èmi yóò sì tún mú ìgbèkùn Ejibiti padà bọ̀, èmi yóò sì dá wọn padà sí ilẹ̀ Paturosi, ilẹ̀ àwọn baba ńlá wọn. Wọn yóò wà níbẹ̀ bí ìjọba tí a rẹ̀ sílẹ̀.
15 Między innemi królestwami będzie najpodlejszen, a nie wyniesie się więcej nad inne narody, i umniejszę ich, aby nie panowali nad narodami.
Ibẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba tí ó rẹlẹ̀ jùlọ nínú àwọn ìjọba, kì yóò sì gbé ara rẹ̀ ga mọ́ sórí àwọn orílẹ̀-èdè: nítorí èmi ni ó dín wọn kù, tiwọn kì yóò fi ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́.
16 I nie będzie więcej domowi Izraelskiemu ufnością, któraby mi na pamięć przywodziła nieprawość, gdyby się oglądali na nie; i dowiedzą się, żem Ja panujący Pan.
Ejibiti kí yóò sì jẹ orísun ìgbẹ́kẹ̀lé fún ilé Israẹli mọ́ ṣùgbọ́n, yóò jẹ́ ìrántí fún àìṣedéédéé wọn, nígbà tí yóò bá wò wọ́n fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’”
17 Potem stało się dwudziestego i siódmego roku, pierwszego miesiąca, pierwszego dnia tegoż miesiąca, stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní, ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
18 Synu człowieczy! Nabuchodonozor, król Babiloński, przyniewolił gwałtem wojsko swe do służby ciężkiej przeciwko Tyrowi; każda głowa obłysiała, i każde ramię obnażone, a przecie nie ma zapłaty on, ani wojsko jego z Tyru za onę służbę, którą podejmo wał, walcząc przeciwko jemu.
“Ọmọ ènìyàn, Nebukadnessari ọba Babeli mú kí ogun rẹ sin ìrú ńlá fún Tire. Gbogbo orí pá, àti gbogbo èjìká bó, síbẹ̀, òun àti àwọn ogun rẹ̀, kò rí owó ọ̀yà gbà láti Tire fún wa, fún ìrú ti a ti sìn.
19 Przetoż tak mówi panujący Pan: Oto Ja daję Nabuchodonozorowi, królowi Babilońskiemu, ziemię Egipską, aby zabrał dostatki jej, i rozszarpał łupy jej, i rozchwycił korzyści jej, aby miało zapłatę wojsko jego.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, Èmi yóò fi Ejibiti fún Nebukadnessari ọba Babeli, òun yóò sì kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ. Òun yóò bo ilé, yóò sì ṣe ìkógun ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ tí a san fún ológun rẹ̀.
20 Za pracę ich, którą dla mnie podjęli, dam im ziemię Egipską, przeto, że mnie pracowali, mówi panujący Pan.
Èmi ti fi Ejibiti fún un gẹ́gẹ́ bí èrè wàhálà rẹ̀ nítorí òun àti àwọn ológun rẹ ṣe é fún mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
21 Dnia onego uczynię, że wyrośnie róg domu Izraelskiego, tobie też usta twoje otworzę w pośrodku ich; i dowiedzą się, żem Ja Pan.
“Ní ọjọ́ náà, èmi yóò mú kí ìwo Israẹli ru jáde, èmi yóò sì fún ọ ní ẹnu ọ̀rọ̀ ní àárín wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”

< Ezechiela 29 >