< Ezechiela 19 >

1 A ty uczyń narzekanie nad książętami Izraelskimi,
“Kọ orin ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ-aládé Israẹli
2 A mów: Cóż była matka twoja? Lwica między lwami leżąca, która w pośrodku lwiąt wychowywała szczenięta swoje.
wí pé: “‘Èwo nínú abo kìnnìún ni ìyá rẹ̀ ní àárín àwọn kìnnìún yòókù? Ó sùn ní àárín àwọn ọ̀dọ́ kìnnìún ó sì ń tọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
3 A gdy odchowała jedno z szczeniąt swoich, stało się lwem, tak, że nauczywszy się chwytać łupu pożerał i ludzi.
Ó sì tọ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ dàgbà, ó sì di kìnnìún tó ní agbára, ó kọ́ ọ láti ṣọdẹ, ó sì ń pa àwọn ènìyàn jẹ.
4 To gdy usłyszały o nim narody, w jamie ich pojmany jest, a zawiedziony w łańcuchach do ziemi Egipskiej.
Àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì fi ẹ̀wọ̀n mú un nínú iho wọn. Wọn fi ẹ̀wọ̀n mu nu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
5 Co widząc lwica, że nadzieja jej, którą miała, zginęła, wziąwszy jedno z szczeniąt swoich, lwem je uczyniła;
“‘Nígbà tí abo kìnnìún yìí rí pé ìrètí rẹ̀ sì jásí asán, ó mú ọmọ rẹ̀ mìíràn ó sì tún tọ́ ọ dàgbà di kìnnìún tó ní agbára.
6 Który chodząc w pośrodku lwów stał się lwem, a nauczywszy się chwytać łupu pożerał i ludzi.
Ó sì ń rìn káàkiri láàrín àwọn kìnnìún nítorí pé ó ti lágbára, o kọ ọdẹ ṣíṣe, ó sì pa àwọn ènìyàn.
7 Poburzył też pałace ich, i miasta ich spustoszył, tak, iż i ziemia i pełność jej od głosu ryku jego spustoszała.
Ó sì wó odi wọn palẹ̀ ó sì sọ àwọn ìlú wọn di ahoro. Ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé ibẹ̀ sì wà ní ìpayà nítorí bíbú ramúramù rẹ̀.
8 I zeszły się przeciwko niemu narody z okolicznych krain, i zarzucili nań sieci swoje; a tak w jamie ich pojmany jest.
Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè dìde sí i, àwọn tó yìí ká láti ìgbèríko wá. Wọn dẹ àwọ̀n wọn fún un, wọn sì mú nínú ihò wọn.
9 I wsadzili go do klatki w łańcuchach, i przywiedli go do króla Babilońskiego, i wprowadzili go do więzienia ciężkiego, aby więcej nie był słyszany głos jego po górach Izraelskich.
Wọn fi ìwọ̀ gbé e sínú àgò, wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli, wọn fi sínú ìhámọ́, a kò sì gbọ́ bíbú rẹ̀ mọ́ lórí òkè Israẹli.
10 Matka twoja była czasu pokoju twego jako winna macica przy wodach szczepiona; płodną i gałęzistą była dla wód obfitych.
“‘Ìyá rẹ dàbí àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ̀; tí á gbìn sí etí odò ó, kún fún èso, ó sì kún fún ẹ̀ka nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
11 I miała rózgi mocne na sceptry panujących, a wywyższył się wzrost jej między gęstemi gałęziami, tak, że była okazała dla wysokości swojej, i dla mnóstwa latorośli swoich.
Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ lágbára tó láti fi ṣe ọ̀pá àṣẹ ìjòyè, ó ga sókè láàrín ewé rẹ̀, gíga rẹ̀ hàn jáde láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ka rẹ̀.
12 Ale w rozgniewaniu wyrwana będąc, na ziemię porzucona jest, a wiatr wschodni ususzył owoc jej; obłamane są i poschły rózgi mocy jej, ogień pożarł je.
Ṣùgbọ́n ó fà á tu ní ìrunú, á sì wọ́ ọ lulẹ̀, afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn sì gbé èso rẹ̀, ọ̀pá líle rẹ̀ ti ṣẹ́, ó sì rọ iná sì jó wọn run.
13 A teraz wszczepiona jest na puszczy w ziemi suchej i pragnącej.
Báyìí, a tún ún gbìn sínú aṣálẹ̀ ni ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tó ń pòǹgbẹ omi.
14 Nadto wyszedł ogień z rózgi latorośli jej, a pożarł owoc jej, tak, że niemasz na niej rózgi mocnej dla sceptru panującego. Toć jest narzekanie, i będzie narzekaniem.
Iná sì jáde láti ọ̀kan lára ẹ̀ka rẹ̀ ó sì pa ẹ̀ka àti èso rẹ̀ run, dé bi pé kò sí ẹ̀ka tó lágbára lórí rẹ̀ mọ́; èyí to ṣe fi ṣe ọ̀pá fún olórí mọ́.’ Èyí ni orin ọ̀fọ̀ a o sì máa lo bí orin ọ̀fọ̀.”

< Ezechiela 19 >