< Ezechiela 14 >

1 Potem przyszedłszy do mnie mężowie z starszych Izraelskich, usiedli przedemną.
Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
2 I stało sie słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
3 Synu człowieczy! ci mężowie złożyli plugawe bałwany swoje do serca swego, a nieprawość, która im jest ku obrażeniu. położyli przed twarzą swoją; mniemaszże, iż mię uprzejmie pytają o radę?
“Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
4 Dlategoż powiedz im, i mów do nich: Tak mówi panujący Pan: Ktokolwiek z domu Izraelsiego położył plugawe bałwany swoje w sercu swojem, a nieprawość, która mu jest ku obrażeniu, położył przed twarzą swoją, a przyszedłby do proroka, Ja Pan odpowiem temu, który przyjdzie, o mnóstwie plugawych bałwanów jego.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
5 Abym ułapał dom Izraelski w sercu ich, że się odwrócili odemnie od plugawych bałwanów swoich wszyscy zgoła.
Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
6 Przetoż rzecz do domu Izraelskiego: Tak mówi panujący Pan: Nawróćcie się, a cofnijcie się od plugawych bałwanów waszych, i od wszystkich obrzydliwości waszych odwróćcie twarz swoję.
“Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
7 Bo ktobykolwiek z domu Izraelskiego i z przychodniów, którzy mieszkają w Izraelu, odwrócił się od naśladowania mnie, a położyłby plugawe bałwany swoje w sercu swem, i nieprawość, która mu jest ku obrażeniu, położyłby przed twarz swoją, i przyszedł by do proroka, aby mię przezeń pytał, Ja Pan odpowiem mu sam przez się,
“‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
8 I postawię oblicze moje przeciw temu mężowi, i dam go na znak, i na przysłowie, a wytracę go z pośrodku ludu mojego; i dowiecie się, żem Ja Pan.
Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
9 A gdyby się prorok dał zwieść, aby mówił słowo, Ja Pan zwiodłem proroka onego, i wyciągnę nań rękę swoję, i wygładzę go z pośrodku ludu mego Izraelskiego.
“‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
10 I tak poniosą nieprawość swoję; jaka jest kaźń na tego, któryby się pytał, taka też kaźń na proroka będzie,
Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 Aby więcej nie błądził dom Izraelski odemnie, a nie mazali się więcej żadnemi przestępstwami swojemi, aby byli ludem moim, a Ja abym był Bogiem ich, mówi panujący Pan.
Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
12 Znowu stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
13 Synu człowieczy! gdyby ziemia zgrzeszyła przeciwko mnie, dopuszczając się przestępstwa, tedy jeźlibym wyciągnął rękę moję na nią, a złamałbym jej łaskę chleba, i posłałbym na nią głód, i wytraciłbym z niej ludzi i zwierzęta;
“Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
14 Choćby byli w pośrodku niej ci trzej mężowie, Noe, Danijel i Ijob, oni w sprawiedliwości swojej wybawiliby dusze swe, mówi panujący Pan.
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
15 Także jeźlibym zły zwierz przepuścił na ziemię, a osierociłby ją, i byłaby spustoszona, żeby jej nikt przechodzić nie mógł dla zwierza,
“Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
16 Jako żyję Ja, mówi panujący Pan, że choćby ci trzej mężowie byli w pośrodku jej, żadną miarąby nie wybawili synów ani córek: oniby tylko sami wybawieni byli, leczby ziemia spustoszona była.
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
17 Albo jeźlibym przywiódł miecz na tę ziemię, a rzekłbym mieczowi: Przejdź przez tę ziemię, abym wytracił z niej ludzi i zwierzęta,
“Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
18 Jako żyję Ja, mówi panujący Pan, że choćby ci trzej mężowie byli w pośrodku jej, żadną miarąby nie wybawili synów ani córek, aleby oni tylko sami byli wybawieni.
Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
19 Albo posłałlibym mór na tę ziemię, i wylałbym popędliwość swoję na nią ku wytraceniu, aby z niej ludzie i zwierzęta byli wytraceni.
“Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
20 Że choćby Noe, Danijel i Ijob byli w pośrodku jej, jako żyję Ja, mówi panujący Pan, żadną miarąby ani syna ani córki nie wybawili, oniby tylko w sprawiedliwości swojej wybawili dusze swe.
bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
21 Owszem, tak mówi panujący Pan: Choćbym cztery kaźni moje ciężkie, miecz, i głód, i zły zwierz, i mór posłał na Jeruzalem, abym wytracił z niego ludzi i zwierzęta,
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
22 A oto jeźliby zostali w nim, którzyby tego uszli, a wywiedzeni byli synowie albo córki, oto i oni muszą iść do was; i oglądacie drogę ich, i sprawy ich, i ucieszycie się nad tem złem, które przywiodę na Jeruzalem, nad wszystkiem, co przywiodę na nie.
Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
23 A tak ucieszą was, gdy ujrzycie drogę ich i sprawy ich; i zrozumiecie, żem to wszystko nie darmo uczynił, com uczynił w nim, mówi panujący Pan.
Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ezechiela 14 >