< Ezechiela 13 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Synu człowieczy! prorokuj przeciw prorokom Izraelskim, którzy prorokują, a rzecz prorokującym z serca swego: Słuchajcie słowa Pańskiego.
“Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
3 Tak mówi panujący Pan: Biada prorokom głupim, którzy idą za duchem swoim, choć nic nie widzieli!
Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
4 Izraelu! Prorocy twoi są jako liszki na puszczy.
Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
5 Nie wstępujcie na przerwane miejsca, ani grodzcie płotu około domu Izraelskiego, żeby się mógł ostać w bitwie w dzień Pański.
Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
6 Widzą marność i wieszczbę kłamliwą; powiadają: Pan mówi, choć ich Pan nie posłał; i cieszą lud, aby tylko utwierdzili słowo swe.
Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
7 Izali widzenia marnego nie widzicie, a wieszczby kłamliwej nie opowiadacie? I mówicie: Pan mówił, chociażem Ja nie mówił.
Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
8 Przetoż tak mówi panujący Pan: Ponieważ mówicie marność, a widzicie kłamstwo, przetoż oto Ja jestem przeciwko wam, mówi panujący Pan.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Bo ręka moja będzie przeciwko prorokom, którzy widzą marność, a opowiadają kłamstwo; w zgromadzeniu ludu mego nie będą, a w poczet domu Izraelskiego nie będą wpisani, i do ziemi Izraelskiej nie wnijdą; a dowiecie się, żem Ja panujący Pan.
Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
10 Przeto, przeto mówię, że w błąd wprowadzili lud mój, mówiąc: Pokój, choć nie było pokoju; jeden zaiste zbudował ścianę glinianą, drudzy ją tynkowali wapnem nieczynionem.
“‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
11 Mówże do tych, którzy ją tynkują wapnem nieczynionem: Upadnie to, przyjdzie deszcz gwałtowny, a wy, kamienie gradowe! spadniecie, i wiatr wichrowaty rozwali ją.
nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
12 A oto gdy upadnie ona ściana, izali wam nie rzeką: Gdzież jest ono tynkowanie, któremeście tynkowali?
Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
13 Prztoż tak mówi panujący Pan! Rozwalę ją, mówię, wiatrem wichrowatym w zapalczywości mojej, i deszcz gwałtowny w popędliwości mojej przyjdzie, a kamienie gradowe w rozgniewaniu mojem na zniszczenie jej.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
14 Bo obalę tę ścianę, którąście potynkowali wapnem nieczynionem, a zrównam ją z ziemią, tak, że odkryty będzie grunt jej, i upadnie, i skażeni będziecie w pośrodku jej, i dowiecie się, żem Ja Pan.
Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
15 A gdy wykonam popędliwość moję nad tą ścianą, i nad tymi, którzy ją tynkowali wapnem nieczynionem, rzekę do was: Niemasz już onej ściany, niemasz i tych, którzy ją tynkowali,
Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
16 To jest, proroków Izraelskich, którzy prorokują o Jeruzalemie, i ogłaszają mu widzenie pokoju, choć niemasz pokoju, mówi panujący Pan.
Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
17 Ale ty, synu człowieczy! obróć twarz twoję przeciwko córkom ludu swego, które prorokują z serca swego, a prorokuj przeciwko nim,
“Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
18 I rzecz: Tak mówi panujący Pan: Biada tym, które szyją wezgłówka pod wszelkie łokcie rąk ludu mojego, a czynią duchny na głowy wszelkiego wzrostu, aby łowiły dusze! izali łowić macie dusze ludu mego, abyście się żywić mogły?
wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
19 Bo mię podawacie w lekkość u ludu mego dla garści jęczmienia, i dla kęsa chleba, zabijając dusze, które nie umrą, a ożywiając dusze, które żywe nie będą, kłamiąc ludowi memu, którzy słuchają kłamstwa.
Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
20 Dlatego, tak mówi panujący Pan: Oto Ja będę przeciwko wezgłówkom waszym, któremi wy tam dusze łowicie, abyście je zwiodły; bo je stargnę z ramion waszych, a wypuszczę dusze, które wy łowicie, abyście je zwiodły;
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
21 I rozerwę duchny wasze, a wybawię lud mój z ręki waszej, abyście ich więcej nie mogły łowić ręką swoją; a dowiecie się, żem Ja Pan.
Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
22 Przeto, że zasmucacie serce sprawiedliwego kłamstwy, chociażem go Ja nie zasmucił, a zmacniacie ręce niezbożnego, aby się nie odwrócił od złej drogi swojej, ożywiając go;
Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
23 Przetoż nie będziecie więcej widywać marności, ani wieszczby więcej prorokować będziecie; bo wyrwę lud mój z ręki waszej, a dowiecie się, żem Ja Pan.
nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Ezechiela 13 >